Dámilọ́lá Anwo-Ade

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Damilola Anwo-Ade
Orílẹ̀-èdèNigerian
Orúkọ mírànDamilola Anwo-Ade
Iṣẹ́
  • IT Project Manager
  • Educational Planner
  • Managing Partner, Sprout
  • Founder of CodeIT

Dámilọ́lá Anwo-Ade tí í ṣe ọmọ bíbí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà jẹ́ olùṣàkóso Sprout Digital Development Limited tí ó ń bá ṣiṣẹ́ pọ̀. Òun sì ni olùdásílẹ̀ CodeIT.[1]

Ètò-ẹ̀kọ́ àti iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Babcock University ni Dámilọ́lá lọ tí ó sì kẹ́kọ̀ọ́ nípa Information Resources Management ní ọdún 2003 wọ ọdún 2007. Ó tẹ̀ síwájú láti gba oyè Master's degree nínú Education Planning and International Development ní The Institute of Education, U ní ìlú London lọ́dún 2012. Dámilọ́lá ni olùṣàkóso Sprout Digital Development Limited tí ó ń bá ṣiṣẹ́ pọ̀.[2] Sprout jẹ́ ọ̀kan lára àwọn irinṣẹ́ ayélujára tó máa ń pèsè ojútùú fún àwọn ilé-iṣẹ́ àti òwò lóríṣiríṣi.[3]

Bákan náà, CodeIT jẹ́ ọ̀kan lára àwọn irinṣẹ́ ayélujára tó máa ń pèsè àyè sílẹ̀ fún àwọn ọmọdé (ọmọ ọdún márùn-ún sí méjìdínlógún) láti nímọ̀ lórí àwọn irinṣẹ́ ayélujára. Dámilọ́lá ti ṣiṣẹ́ ribiribi lórí ICT. Ó máa ń pèsè iṣẹ́ lóríṣiríṣi tó dá lórí ayélujára láti mu lọ ìpele tó kàn. Ó ti ṣiṣẹ́ ní ilé-iṣẹ́ ICT lóríṣiríṣi níbi tó ti ń kọ́ àwọn èèyàn ní Intel àti UN Women Nigeria.[4]

Látipa ṣẹ̀ iṣẹ́ ribiribi rẹ̀, U.S. Department of State's Bureau of Educational and Cultural Affairs yàn-án gẹ́gẹ́ bíi ọ̀kan lára àwọn aṣojú orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní Silicon Valley lọ́dún 2017.[5]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Damilola Anwo-Ade – Medium". Medium. 2020-04-30. Retrieved 2020-05-01. 
  2. "Damilola Anwo-ade's schedule for Social Media Week Lagos 2019". Social Media Week Lagos 2019. 2013-12-17. Retrieved 2020-05-01. 
  3. "Damilola Anwo-Ade". F6S. Retrieved 2020-05-01. 
  4. . (2018-11-22). "How more women will access tech solutions to boost business". Anwo-Ade – Daily Trust. Retrieved 2020-05-01. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  5. "US honors 5 Nigerian women". Vanguard News. 2017-06-08. Retrieved 2020-05-01. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]