Emirate of Say

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Emirate of Say

1825
OlùìlúSay
Àwọn èdè tówọ́pọ̀Arabic, Fulani, Songhay, Zarma
Ẹ̀sìn
Islam
List of rulers of Say 
• 1825—1834
Alfa Mohamed Diobo
• 1834-1860
Boubacar Modibo
Ìtàn 
• Dídásílẹ̀
1825
Today part of

Emirate of Say jẹ́ ilẹ̀ Mùsùlùmí kan tí Alfa Mohamed Diobo, adarí Qadiriyya Sufi kan dá kalẹ̀ ní ọdún 1825, Mohamed wá sí Say àti Djenné ( ni Mali) ní ọdún 1810. Bí ó tilè jẹ́ pé Diobo kìí ṣe akọ́gun wọ̀lú, ó sì láṣẹ lórí Say nítorí pé ó jẹ́ Alfa àti pé ó wà lára àwọn tí ó dà àbò bo Sokoto Empire, tí àlùfáà Qadiriyya Sufi, Usman Dan Fodio kalẹ̀.

Nígbà tí ó sì gbajúmọ̀, emirate of Say jẹ́ ibi tí àwọn ènìyàn mọ̀ láti Gao dé Gaya gẹ́gẹ́ bi ibi tí wọn ti ń kó nípa ẹṣin Islam. Àwọn adarí ìlú Say láti ọdún mọ́dún jẹ́ àwọn ìran Diobo. Àwọn ni; Alfa Mohamed Diobo (1825—1834), Boubacar Modibo (1834–1860), Abdourahman (1860–1872), Moulaye (1872–1874), Abdoulwahidou (1874–1878), Saliha Alfa Baba (1878–1885), Amadou Satourou Modibo (1885—1893), Halirou Abdoulwahabi (1893—1894).[1][2]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Idrissa, Abdourahmane; Decalo, Samuel (2012), Historical Dictionary of Niger by Abdourahmane Idrissa, Samuel Decalo, Page 399, ISBN 9780810870901, retrieved 2021-03-18 
  2. Seeda (2014), Qui est Alpha Mahaman Diobbo ?, Niamey.com, retrieved 2021-03-18