Kẹ́mi Afọlábí

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Kẹ́mi Afọlábí (tí wọ́n bí ní ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n oṣù kẹrin ọdún 1978) jẹ́ gbajúmọ̀ òṣèrébìnrin, oǹkọ̀tàn àti olóòtú sinimá àgbéléwò ọmọ ìpínlẹ̀ Ògùn, ṣùgbọ́n tí àwọn òbí rẹ̀ bí sí ìpínlẹ̀ Èkó lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà. [1] [2]

Ìgbà èwe àti aáyan ìkẹ́kọ̀ọ́[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Kẹ́mi bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ ní ilé-ìwé A-Z International School àti ilé-ìwé Our Lady of Apostles School, ní ìpínlẹ̀ Èkó lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà fún ẹ̀kọ́ gírámà rẹ̀. Lẹ́yìn èyí, ó kàwé gboyè nípa ìmọ̀ òfin ni ifáfitì ìjọba àpapọ̀ ti ó kalẹ̀ sí ìlú Èkó, the University of Lagos. Lẹ́yìn tó dára pọ̀ mọ́ ìṣe sinimá àgbéléwò, Kẹ́mi tí gba àmìn ẹ̀yẹ tí ilé iṣẹ́ City People ṣe gẹ́gẹ́ bí òṣèrébìnrin tó dára jùlọ lọ́dún 2016, lọ́dún kan náà, ó gba àmìn ẹ̀yẹ gẹ́gẹ́ bí òṣèrébìnrin to gbajúmọ̀ jùlọ láti owó Odua Image Awards. Kẹ́mi Afolábí jẹ́ abilékọ, ó sìn tí bímọ kan péré.[3] [4]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. [/kemi-afolabi-biography-profile-fabwoman/ "Kemi Afolabi Biography - Profile"] Check |url= value (help). FabWoman | News, Style, Living Content For The Nigerian Woman. 2018-04-30. Retrieved 2019-12-07. 
  2. "Nollywood actress, Kemi Afolabi hospitalised in Saudi Arabia". P.M. News. 2019-07-30. Retrieved 2019-12-07. 
  3. Odozi, Amaka (2019-07-30). "41-Year-Old Nollywood Actress, Kemi Afolabi Hospitalized In Saudi Arabia (PHOTOS)". Information Nigeria. Retrieved 2019-12-07. 
  4. Published (2015-12-15). "I’m scared of my children’s future in Nigeria –Kemi Afolabi". Punch Newspapers. Retrieved 2019-12-07.