Ngozi Nwozor-Agbo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Ngozi Nwozor
Ọjọ́ìbíJune 21, 1974 (1974-06-21)
Onitsha, Anambra, Nigeria
AláìsíÀsìṣe ìgbéọ̀rọ̀sílẹ̀: Àìdámọ̀ àmì ìdádúró-ọ̀rọ̀ sókí "{"., May 28, 2012 (ọmọ ọdún Àsìṣe ìgbéọ̀rọ̀sílẹ̀: Àìdámọ̀ ọ̀rọ̀ "may".)
Lagos
Ẹ̀kọ́Yunifásítì ti Nàìjíríà
Yunifásitì ìlú Èkó
Iṣẹ́Journalist
OrganizationThe Nation (Nigeria) Newspapers
Gbajúmọ̀ fúnCampusLife

Ngozi Nwozor-Agbo /θj/ (ọjọ́ 21 oṣù kẹfà, ọdún 1974 sí ọjọ́ 28 oṣù karùn-ún, ọdún 2012) jẹ́ oníròyìn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà,[1] òǹkọ̀wé àti akéwì tí gbogbo ènìyàn ń pè ní ‘Lady Campus’. Ó jẹ́ ìlú mọ̀ọ́ká ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà gẹ́gẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tí ó dá ìwé-ìròyìn ọgbà Fáṣítì sílẹ̀ tí ó pè ní ìgbésí ayé ọgbà Fáṣítì (CampusLife), èyí tí ó jẹ jáde látinú àwọn ìwé-ìròyìn The Nation fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ láti inú ọgbà Fáṣítì jákèjádò orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó tún jẹ́ gbajúgbajà nípa kíkọ ọgọ́rùn-ún àwọn ọ̀dọ́ tí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti di àwọn òǹkọ̀ròyìn tí ó gbámúṣẹ́.[2][3]

Ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ayé àti iṣẹ́ àyànṣe[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Ngozi Agbo ní ìlú Onitsha, ní ìpínlẹ̀ Anambra, ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ó lọ sí Fáṣítì tí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, Nsukka (UNN), níbi tí ó ti kọ́ ẹ̀kọ́ ìmọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì. Ó jẹ́ ajàfẹ́tọ̀ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí ó múnádóko wọ́n sì yàn-án gẹ́gẹ́ bí igbákejì Ààrẹ ti ẹgbẹ́ akẹ́kọ̀ọ́ tí ìjọba ti UNN ní ọdún 1999. Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè Másítà nínú ìmọ̀-ẹ̀kọ́ ìtàn àti ẹ̀kọ́-ìmọ̀ ìbáṣepọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè ní Fáṣítì Èkó (UNILAG). Ngozi darapọ̀ mọ́ ìwé-ìròyìn The Nation ní ọdún 2007, pẹ̀lú pé ó ti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìwé-ìròyìn New Age àti àwọn àjọ tí kìí ṣe ti Ìjọba (NGO), Fate Foundation.

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "USA/Africa Dialogue, No 403: Nelson Mandela Institute". 
  2. "Ngozi Agbo: The unforgettable impact". 27 May 2015. 
  3. https://www.pmnewsnigeria.com/2010/05/21/all-hail-campus-life-spoils-students-at-writers%E2%80%99-workshop/