Jump to content

Ogedengbe of Ilesa

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Ogedengbe of Ilesa
ọmọnìyàn
ẹ̀yàakọ Àtúnṣe
ọjó ìbí1822 Àtúnṣe
ọjó ikú1910 Àtúnṣe

Ògèdèngbé ti ilẹ̀ Ìjẹ̀ṣà ( abi ní ọdún1822, ó sì papòdà ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n, Oṣù Agẹmọ, ọdún 1910), eni tí a tún mọ̀ sí Ògèdèngbé Agbógun Gbórò tàbí Sàráíbí Agbógungbọ́rọ̀, jẹ́ olóyè ní ilẹ̀ Yorùbá àti jagunjagun ní ilẹ̀ Yorùbá, tí ó jẹ́ apá kan orílẹ̀-èdè Nàìjíríà òde òní. Ó jẹ́ Séríkí nígbà Ogun Kíríjì (1877-1893) gẹ́gẹ́ bìi alátakò sí ìlú Ìbàdàn.

Ìgbé Ayé rẹ̀ ní Èwe

A bí Òrìṣàráyíbí Ògúndàmọ́lá sí ìdílé Apasan Borijiwa àti Fálùpò ní abúlé kékeré kan tí a ún pè ní Àtòrìn ní tòsí ìlú Iléshà, nìnù oṣù ògún tàbí ọwẹ́rẹ̀. Gẹ́gẹ́ bí ìse àwọn Yorùbá, babaláwo kan ní ọdún 1822 sọ àsọtẹ́lẹ̀ wípé aó bǐ ọmọkùnrin kan ní ọjọ́ ìsẹ́gun tí ó gba àwon ará Ìjẹṣà lọ̀wọ̀ òyìnbó aninilára. Ìyá rẹ̀ ṣe aláìsí nígbà tí óún rọbí lọ́wọ́. A bí Ògèdèngbé súmọ́ ìgbà ti ọdún Ogun ọlọ́dọdún máa ń wáyé, ọdún Ogun yǐ máa ń wáyé nínú oṣù ògún tàbí ọ̀wẹ̀rẹ̀. Ògèdèǹgbé nìkan ni ọmọkùnrin tí a bí ní ilé agbẹ̀bí ní ọjọ́ náà. Àwọn òbí rẹ̀ jẹ́ oníṣẹ̀ṣe. Ọrúkọ àkọ́kọ́ rẹ̀ tí óún jẹ́ Òrìṣàráyíbí Ògúndamọlá túnmo sí Òrìshà fúnbí. Òrìṣà nínú orúkọ rẹ̀ túnmọ̀ sí "Òrìsàńlá" orúkọ fún òrìsà Obàtálá, orúkọ náà tún lè túnmọ̀ sí "Ọbàtálá fúnbí". Ògúndàmọ́lá túnmọ̀ sí wípé Ògún fi kún ọlá. Ọmọ bíbí ìlú Àtòrìn ni ìyá Ògèdèǹgbé, bàbá rẹ̀ jẹ́ ọmọ bíbí ìlú Òkè-Òrìsà tí ó súnmọ́ ìlú Iléshà. Ní ìgbà kékeré rẹ̀, ànagijẹ rẹ̀ ni Ògèdèǹgbé, orúkọ Yorùbá tí ó jẹyọ nínú ọwá ara ìjàa rẹ̀. Nígbà tí ó ṣe di ẹ̀, a sọ́ ní Agbógungbọ́rọ̀ nígbà tí ó jagun tán. Agbógungbọ́rọ̀ túnmọ̀ sí ẹni tí ó nífẹ̌ sí Ogun jíjà bí ẹniwípé ènìyàn ń ṣe Ọdún ni.

Ìgbé ayé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Ológun

Ní ọdún 1864, ọwọ́ tẹ Ògèdèǹgbé nígbà tí óún gbèjà Ìlárá-Mọkin nínú ogun tí wọ́n ń jà pẹ̀lú ìlú Ìbàdàn. Ògèdèǹgbè sálọ kúrò nínú ìgbèkùn lẹ́yìn ìgbà tí ó kọ́ iṣẹ́ ogun jíjà lọ́wọ́ ọ̀gbẹ́ni jagunjagun kan tí a ń pè ní Badà Aki-Ìko. Ọwọ́ padà tẹ Ògédèǹgbé nígbà ogun Ìgbájọ ní ọdún 1867 ṣugbọ́n ó tún sálọ ní ìgbà ìkejì. Ìṣẹ̀lẹ̀ méjì yí kọ́ Ògèdèǹgbé ní bí a ṣe ń ja ogun. Ní ìgbà tí wọ́n fi ẹ̀sun kan olóyè Ìjẹ̀ṣà kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ọ̀dọlé Aríysǎsunlé wípé ó ń fún ìlu Ìbàdàn ní àsírí ìjagun àwọn ará Ìjẹ̀ṣà, Ògèdèǹgbè darí àwọn ọmọ ogun rẹ̀ làti lé olóyè náà kúrò ní ìlú Iléṣà, lẹ́yìn náà ó di akọni. Ní ọdún 1878, Ògèdèǹgbé kogun ja ìlú Ìdóàní, ó sì padà sí ìlú Ìtaògbolú ní Ìpínlẹ̀ Oǹdó, lẹ́yìn tí ó ti pàdánù ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ ogun rẹ̀ ní ojú ogun ní odún 1879.

Lẹ́yìn tí ogun Kíríjì bẹ̀rẹ̀, wọ́n kó àwọn jagun-jagun ti Èkìtì-Parapọ̀ jọ ní ọdún 1878 láti síwájú ogun lọ íi ìlú Ìbàdàn. Ní ọdún 1878, Ògèdèǹgbè ń gbé ní ìlú Ìgbàrà-òkè, bẹ́ẹ̀ sì ni pẹ̀lú ó ti pinu láti rin ìrìn-àjò lọ sí ìlu Benin. Ògèdèǹgbé fa igi lé ìrìn-àjà rẹ̀ lọ sí ìlú Benin kó lè darí àwọn ọmọ ogun rẹ̀ gẹ́gẹ́bí àwọn adarí ogun se béèrè fun. Nígbàtí Ògèdèǹgbé dé oju ogun, wọ́n fi ọ̀yàyà ki káàbọ̀, Ọmọ Ọba Fábùnmi sì finú fídọ̀ fi orí àpèrè sílẹ̀ fún Ògèdèǹgbé. Nígbà tí ogun ń lo lọ́wọ̀, Ògèdèǹgbé ṣe ìrànwẹ́ láti gba apá àríwá ìlà-oòrùn Yorùbá lọ́wọ́ Ìbàdàn. Lẹ́yìn àdéhùn 1886, Ògèdèǹgbé àti àwọn ọmọ-oogun rẹ̀ lọ sí ìlú Ìmẹ̀sí títí di ìgbà tí ìjà fi bẹ́ sílẹ̀ láàárin Ìbàdàn àti Ìlọrin ní ọdún 1893. Àwọn ọmọ ogun rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ń kó èrè oko àwọn ará ìlú, èyí tí ìkìlọ̀ wá làti ọwọ́ Captain Robert Lister Bower tí ó jẹ́ Ológun ti ìlẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì, tí ó ń ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bíi ọmọ ìlú Ìbàdàn àti olóṣèlú ti ìlú Èkó.

Ni[ ọdún 1894, Captain Bower fi kélé òfin gbé Ògèdèǹgbé, ó sì fi sí ẹ̀wọ̀n ní ìlú Ìbàdàn. Ní ìgbà tí àwọn adarí ìlú Iléṣà fi ẹ̀hónú hàn lórí ibi tí wọ́n fi Ògèdèǹgbé pamọ́ sí, wọ́n gbe lọ sí ìlú Ìwó. Lẹ́yìn ìtàkurọ̀sọ, gómìnà ológun ti ìlú Èkó, Gilbert Thomas Carter, dà Ògèdèǹgbé sílẹ̀ ní ìgbà tí Ọwá ìlú Iléṣà Fredrick Kumokun Adedeji Haastrup san owó ìtanràn tí ó jẹ ẹgbàata pọ́ùn.

Ìgbé Ayé Rẹ̀ Ní Àgbà

Ní ọdún 1898, lẹ́yìn tí Ògèdèǹgbé kọ̀ jálẹ̀ láti di Ọwá Obòkun, Ọba ìlú Iléṣà, fi Ògèdèǹgbé jẹ oyé Ọbańlá tàbí èyí tí a lè pè ní Ọbálá tí ó túnmọ̀ sí Alágbára Ọba làti yẹ́ẹ sí fún ipa ribi ribi tí ó kó nínú ogun Kíríjì. Ògèdèǹgbé ṣe aláìsí ní ọjọ́ kọ́kàndínlọ́gbọ̀n, oṣù Agẹmọ, ọdún 1910 ní ẹni ọdùn méjídínláàdọ́rùn ún. Ọmọ rẹ̀ ṣe ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì jẹ oyè Ọbańlá ti ìlú Iléṣà. Àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ sì ń jẹ oyè Ọbálá àti Alátòrìn (Ọba ìlú Àtòrìn) títí di òní. Ìjọba amúnisìn tí ó wà ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ṣe ère kan láti se ìrántí Ògèdèǹgbé ní ọdún 1934, ère náà wà ní ojúde ààfin Ọwá ti ìlú Iléṣà.