Jump to content

Tai Solarin University of Education

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Tai Solarin University of Education
Established2005
TypePublic
Vice-ChancellorAdekunle Olanrewaju Adeogun (Acting)
LocationIjebu-Ode, Ogun State, Nigeria
Websitehttps://tasued.edu.ng/

Unifasiti Ẹ̀kó Àgbà Tí Tai Solarin (TASUED) jẹ́ yunifásítì èkó ti ìjọba àpapọ̀ ní Nàìjíríà.  

Wọ́n dá a sílẹ̀ ní Odún 2005 gẹ́gẹ́ bí yunifásítì ìpínlẹ̀ ní Ìpínlẹ̀ Ogun[1]. Ní ọjọ́ Kèje Oṣù Kẹta Odún 2025, ìjọba àpapọ̀ gba ilé-ẹ̀kọ́ náà gẹ́gẹ́ bí yunifásítì ìjọba àpapọ̀.  Ìpinnu yìí, tí Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu fọwọ́ sí, jẹ́ àmì ìyípadà TASUED láti ilé-ẹ̀kọ́ tí ìpínlẹ̀ sí ti yunifásítì ìjọba àpapọ̀. Ó wà ní Ijagun, Ijebu-Ode, ní Ìpínlẹ̀ Ogun[2].

Wọn so Yunifásítì náà ni Orúkọ ni ìrántí lẹ́yìn Tai Solarin (1922–1994), olùṣèlú ètò ẹ̀kọ́ àti ajàfẹ́tọ́ ọmọnìyàn ará Nàìjíríà. Ó jẹ́ yunifásítì kẹrìndínlọ́gọ́rin (76th) tí National Universities Commission fọwọ́ sí ní Nàìjíríà[3]. Yunifásítì Ẹ̀kó Ti Tai Solarin (TASUED, tí a ń pè ní TARSUD), ni wọ́n kéde gẹ́gẹ́ bí yunifásítì tó péye gan-an (àti ìyípadà láti Tai Solarin College of Education tẹ́lẹ̀rí, tí wọ́n dá sílẹ̀ ní Oṣù Kínní ọdún 1978) ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ́n Oṣù Kínní ọdún 2005 láti ọwọ́ ìṣèlú Otunba Gbenga Daniel. Yunifásítì Ẹ̀kó Àkọ́kọ́ ti Orílẹ̀-Èdè Náà.

Wọ́n fọwọ́ sí TASUED ní ìfọwọ́sowọ́pọ̀ gẹ́gẹ́ bí yunifásítì láti ọwọ́ National Universities Commission (NUC) ní Ojó Iṣẹgun, ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n Oṣu Kọkànlá ọdún 2005. Láti ìgbà ìdásílẹ̀ rẹ̀, yunifásítì náà ti fi ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ iṣẹ́-ọwọ́ àti ìṣòwò fún ọdún mẹ́rin sínú ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ àwọn ètò rẹ̀ bí B.Ed., B.Sc. (Ed.), B.Sc., àti B.A. (Ed.) kí wọ́n lè fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ní ìwé ẹ̀rí méjì nígbà ìparí: ọ̀kan nínú ètò ìkẹ́kọ̀ọ́ tí wọ́n yàn, èyí kejì sì jẹ́ ìwé ẹ̀rí òye nínú ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ iṣẹ́-ọwọ́ àti ìṣòwò. Pẹ̀lú èyí, lẹ́yìn ìṣàyẹ̀wò ohun èlò NUC ní Oṣù Kerin Ọdún 2019, Ìgbìmọ̀ náà, ní àfikún sí àwọn ètò tó wà tẹ́lẹ̀ (undergraduate àti postgraduate), fún yunifásítì náà ní ìfọwọ́sowọ́pọ̀ láti dá àwọn ètò ìtèsíwájú ẹ̀kọ́ kan sílẹ̀ àti kí wọ́n ṣe àwọn ètò fún àwọn akẹkọ tí wọ́n sì wá lẹ́nu ẹ̀kọ́ kan ní ọ̀nà kíkọ́ lọ́jọ́ gbogbo. Ní ìgbẹ̀yìn, wọ́n fọwọ́ sí ètò mọ́kàndínlọ́gọ́ta (59) tuntun: ètò PhD mẹ́tàlélọ́gbọ̀n (33), ètò M.A. mẹ́tàlá (13), M.Sc., M.A.(Ed.), àti M.Sc.(Ed.), àti ètò B.A. àti B.Sc. mẹ́tàlá (13).


Àwọn Olùdarí Yunifásítì (Vice Chancellors) ti Yunifásítì Ẹ̀kó Ti Tai Solarin (TASUED) látìgbà ìdásílẹ̀ rẹ̀ ní ọdún 2005 ni wọ́nyí:[4][5]

  • Professor Olukayode Oyesiku: (Olùdarí Àkọ́kọ́/Pioneer Vice-Chancellor): ọjọ kínní oṣù kẹrin ọdún 2005 – ọjọ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kẹta ọdún 2010.
  • Professor Segun Awonusi: (Olùdarí Keji): ọjọ kínní oṣù kẹrin ọdún 2010 – ọjọ kẹ̀jọ oṣù kínní ọdún 2013.
  • Professor Oluyemisi Oluremi Obilade: ( Olùdarí Kẹta, àti Obìnrin Àkọ́kọ́): ọjọ kẹsán oṣù kínní ọdún 2013 – ọjọ kẹjọ oṣù kínní ọdún 2018.
  • Professor Abayomi Arigbabu: Olùdarí Kẹrin, àti Olùdarí Àkọ́kọ́ tó jẹ́ ọmọ ìbílẹ̀): ọjọ kọkàndínlógún oṣù kẹta ọdún 2018 – ọjọ kínní oṣù kọkànlá ọdún 2020.
  • Professor Oluwole Sikiru Banjo (ọdún 2023 - ọjọ Kejì oṣù kọkànlá ọdún 2025)[6]
  • Professor Adekunle Adeogun (ọjọ kẹta oṣù kọkànlá ọdún 2025 gẹ́gẹ́bí olùsebí Olùdarí (acting Vice chancellor)[7]

Yunifásítì náà ní kọ́lẹ̀jì mẹ́fà àti Kọ́lẹ̀jì Postgraduate.

- Kọ́lẹ̀jì Èkó Àkànṣe àti Ọjọ́gbọ́n (College of Specialised and Professional Education - COSPED)

- Kọ́lẹ̀jì Sáyẹ́nsì àti Ìmọ̀ Tẹ́knọ́lọ́jì Alámọ̀ràn (College of Science and Information Technology - COSIT)

- Kọ́lẹ̀jì Èdè àti Ìmọ̀ Ènìyàn (College of Humanities - COHUM)

- Kọ́lẹ̀jì Àwùjọ àti Ìmọ̀ Ìṣèlú (College of Social and Management Sciences - COSMAS)

- Kọ́lẹ̀jì Èkó Iṣẹ́-Ọwọ́ àti Tẹ́knọ́lọ́jì (College of Vocational and Technology Education - COVTED)

- Kọ́lẹ̀jì Ogbin àti Ìṣètò Àlejò (College of Agriculture and Hospitality Management - COAHM)

- Kọ́lẹ̀jì Postgraduate (The Postgraduate College - TPC)

Ọgbà Ilé-ìwé àti Àwọn Họ́stẹ́lì

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Yúnifásítì náà ní àwọn gbọngàn àti ilé-ìkànsí gẹ́gẹ́ bí Otunba Gbenga Daniel Auditorium, Ilé Ẹ̀kọ́ Ayelujara (e-learning) ti Yúnifásítì, Alex O. Onabanjo Complex, ilé CEPEP, Science Complex, àti Lecture Theatre. Ó tún ní àwọn ilé ìgbé (họ́stẹ́lì) fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́.[8] Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tún ń gbé nínú àwọn họ́stẹ́lì tí àwọn ará àgbègbè ìlú tó yí yúnifásítì ká kọ́, gẹ́gẹ́ bí Ijagun, Ijele, Imaweje, Ososa àti Ijẹbu-Ode. Mosun Filani àti Tobi Oyinlola jẹ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àtijọ́ (alumni) olókìkí ti yúnifásítì náà.

Ìjọba tuntun kan dé sípò ní Ìpínlẹ̀ Ogun ní ọdún 2011 lábẹ́ ìṣàkóso Sénétọ̀ Ibikunle Amosun, tí ó sì gbìyànjú láti fagi lé TASUED. Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé-ẹ̀kọ́ náà dìde láti lòdì sí ìpinnu yìí, wọ́n sì dá ìpolongo #OccupyTASUED sílẹ̀.

Ní ọjọ́ kẹrìnlá Oṣù Kejìlá ọdún 2012, ní ọ̀kan lára àwọn ìrìnàjò wọn sí Ilé Ìjọba Ìpínlẹ̀ ní Oke-Mosan, Abeokuta, táyà mọ́tò-bọ́ọ̀sì tí ń gbe àwọn alátìlẹ́yìn TASUED fọ́, mọ́tò náà sì tàkìtì lẹ́ẹ̀mejì. Ìjàmbá náà fa ìfarapa sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, ó sì mú ẹ̀mí Olatunji Fashina lọ, tí a tún mọ̀ sí Humble TeeJay. Layemi, Azeez Agboola (Olofin), Ishola Adebayo Crown, Owoblow, Tola Ben, àti díẹ̀ míì tún wà nínú mọ́tò náà nígbà ìjàmbá.

Lónìí, wọn bọlá fún Tunji Fashina gẹ́gẹ́ bí akíkanjú fún àṣeyọrí yẹn, nítorí pé ó san ǹkan ńlá jùlọ tín ṣe ẹ̀mí rẹ̀. Ilé ìṣèjọba àwọn akẹ́kòó (Students Union Government) (SUG) ni wọ́n sọ ní orúkọ rẹ̀.[9]

Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Àtijọ́ Olókìkí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]