Tanimowo Ogunlesi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Tanimowo Ogunlesi
Fáìlì:Photo of Tanimowo Ogunlesi (cropped).png
Ọjọ́ìbí1908
Aláìsí2002
Orílẹ̀-èdèNigeria
Ẹ̀kọ́London University
Iléẹ̀kọ́ gígaKudeti Girls School Ibadan
United Missionary College (UMC)
Iṣẹ́Women's rights activist
Gbajúmọ̀ fúnLeader of the Women's Improvement League

Tanimowo Ogunlesi (1908-2002[1]) jẹ́ ajàfẹ́ẹ̀tọ́ àwọn obìnrin ilẹ̀ Nàìjíríà ó tún jẹ́ adarí Women's Improvement League[2][3]. Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn adarí tó ń já à fún ẹ̀tọ́ àwọn obìnrin àti ọ̀kan lára àwọn olùdásílẹ̀ National Council of Women Societies, tí ń ṣe aṣáájú iléeṣẹ́ ajàfẹ́ẹ̀tọ́ àwọn obìnrin ti Nàìjíríà.

Ìgbésí ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Tanimowo Ogunlesi lọ iléèkọ́ Kudeti Girls School Ibandan. Ó tún kàwé ní iléèkọ́ United Missionary College (UMC) fún ìkàwágboyè ìkẹ́ẹ̀kọ́ gẹ́gẹ́ bí i olùkọ́. Ó jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ láti ṣe ìdásílẹ̀ ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ oníléégbèé ní ìlú Ìbádàn (Children Home School).

Ó jẹ́ ààrẹ àkọ́kọ́ ti National Council of Women Societies ní ọdún1959[4]. Ó ṣiṣẹ́ ribiribi lórí ẹ̀tọ́ àwọn obìnrin láti ma dìbò àti láti ní àǹfààní sí àwọn ohun-èlò ẹ̀kọ́, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí i ọ̀pọ̀ àwọn adarí obìnrin ìgbà ayé rẹ̀, Kò ní ẹjọ́ tó tako sí àwọn ọkùnrin gẹ́gẹ́ olórí àwọn ìdílé oríléèdè ilẹ̀ Nàìjíríà.[5][6]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "OGUNLESI Gladys Tanimowo Titilola (Née Okunsanya)". 3 September 2020. 
  2. "Foreign Data". Jet : 2004 (Jet Magazine (Johnson Publishing Company)): 40. December 16, 1961. ISSN 0021-5996. https://books.google.com/books?id=MrMDAAAAMBAJ&pg=PA40. 
  3. Banji Oyeniran Adediji (2013). DEEPER INSIGHT INTO NIGERIA'S PUBLIC ADMINISTRATION. AuthorHouse. ISBN 978-1-491-8347-25. https://books.google.com/books?id=5qFkAgAAQBAJ&q=Tanimowo+Ogunlesi&pg=PA476. 
  4. http://news.biafranigeriaworld.com/archive/ngguardian/2003/feb/19/article18.html - 16k
  5. Karen Tranberg Hansen; African Encounters with Domesticity. Rutgers University Press, 1992. p. 131–133.
  6. Hajo Sani (2001). Women and national development: the way forward. Spectrum Books. p. 32. ISBN 978-9-780-2928-29. https://books.google.com/books?id=wFW1AAAAIAAJ&q=Tanimowo+Ogunlesi.