Abd al-Rab Mansur al-Hadi
Ìrísí
A bí Abd Al - Rab Mansur al- Hadi ni ọjọ́ ìkíní, oṣù kẹsàn-án ní ọdún 1945, ní agbègbè Abyan ní apá Gúúsù ilẹ̀ Yemen. Ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ gíga ológun ní Yemen àti ní òkè òkun kó tó gbá ipò ọ̀gá, kó sì tó darapọ̀ mọ́ òsèlú ìjọba àpapọ̀.
Ní ọdún 2011, ààrẹ Saleh gbà láti gbé agbára kalẹ̀, lẹ́yìn èyí ni Hadi di adelé. Ní àkókò ìgbágbárá kalẹ̀ tí àjọ̀ Gulf tì lẹ́yìn, wọ́n yàn án bí i ààrẹ orílẹ̀-èdè ní ọdún 2012. Ààrẹ Hadi jẹ́ ààrẹ orílẹ̀-èdè ìkejì tí yóò jẹ láti ọdún 2012 - 2022. Kí ó tó di ààrẹ orílẹ̀-èdè, ó fi ìgbà tó pẹ́ díẹ̀ ṣe igbákejì ààrẹ lábẹ́ ààrẹ orílẹ̀-èdè Ali Abdulahi Saleh, fún odidi ọdún mẹ́tàdínlógún.