Jump to content

Aláàfin Ọdarawu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Ọdarawu fìgbà kan jẹ́ Aláàfin Ìlú Ọ̀yọ́, ní sẹ́ńtúrì kẹtàdínlógún.[1] Òun ni Aláàfin àkọ́kọ́ tí àwọn Ọ̀yọ́ Mèsì ò tẹ́wọ́gbà.[1]

Ọdarawu jẹ́ ọmọ Aláàfin Àjàgbó. Kò pẹ́ rárá lórí oyè. Ó jẹ́ onínú fùfù, tó máa ń tètè bínú. Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ṣe sọ, ìbínú rẹ̀ ló sun dé bí wọ́n ṣe le kúrò lórí oyè, tí ó sì dúró gẹ́gẹ́ bí ẹ̀kọ́ fún àwọn ọba tó jẹ lẹ́yìn rẹ̀. Ogun tí Ọdarawu kópa nínú rẹ̀ ni èyí tó ṣe kẹ́yìn. Lásìkò ìjọba rẹ̀, ó pàṣẹ kí wọ́n ba ọjà kan jẹ́. Orúkọ ọjà yìí ni Ojo-segi, nítorí ọkàn lára àwọn tó ń tajà níbẹ̀ ṣèṣì gbá Aláàfin yìí létí láìmọ̀ pé òun ni Aláàfin, tí ó sì tún pè é ní olè.[2] Lẹ́yìn gbogbo awuyewuye yìí, àwọn ará Ọ̀yọ́ ní kó ṣígbá wò, nítorí kò yẹ láti ṣèjọba ìlú Ọ̀yọ́.

Lẹ́yìn tó wàjà, Aláàfin Kánran jẹ oyè Aláàfin.

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. 1.0 1.1 Law, R. C. C. (1971). "The constitutional troubles of Ọyọ in the eighteenth century". The Journal of African History 12 (1): 25–44. doi:10.1017/s0021853700000050. ISSN 0021-8537. 
  2. Johnson, Samuel (2010), "Origin and Early History", The History of the Yorubas, Cambridge University Press, pp. 3–14, ISBN 9780511702617, doi:10.1017/cbo9780511702617.006