Jump to content

Aláàfin Àjàgbó

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Ajagbo
Iṣẹ́Alaafin

Àjàgbó fìgbà kan jẹ́ Aláàfin Ìlú Ọ̀yọ́, tí ìjọba rẹ̀ wáyé ní sẹ́ńtúrì kẹtàdínlógún.[1]

Ajagbo jẹ oyè yìí, lẹ́yìn tí bàbá-bàbá rẹ̀ wàjà, ìyẹn Aláàfin Ọbalokùn.[1] Ìtàn àtẹnudẹ́nu fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé ó jọba fún ogóje ọdún.[2] Àti pé ó jẹ́ ìbejì.[2]

Ó gbajúmọ̀ fún oyè Ààrẹ Ọ̀nà Kakanfò tó ṣẹ̀dá (èyí tí a lè fi wé oyè ológuna) ní ìlú Ọ̀yọ́. Yàtọ̀ sí èyí, àwọn ìgbèríko tó yí Ọ̀yọ́ ká mọ̀ ọ́n fún ìwà ogun rẹ̀, nítorí ó rán àwọn jagunjagun láti kọjú ogun sí àwọn ará Pópó, Ilé Ọlọ́pàá àti ìlú ìyá rẹ̀, ìyẹn Ikereku-were.

Ọmọ rẹ̀ Aláàfin Ọdarawu ló jẹ oyè Aláàfin lẹ́yìn tó wàjà.

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. 1.0 1.1 Law, R. C. C. (1971). "The constitutional troubles of Ọyọ in the eighteenth century". The Journal of African History 12 (1): 25–44. doi:10.1017/s0021853700000050. ISSN 0021-8537. 
  2. 2.0 2.1 Johnson, Samuel (August 2011). The history of the Yorubas : from the earliest times to the beginning of the British Protectorate. ISBN 0948390891. OCLC 989713421.