Catherine Obianuju Acholonu

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Catherine Obianuju Acholonu
Fáìlì:Catherine Obianuju Acholonu.jpg
Ọjọ́ìbí(1951-10-26)26 Oṣù Kẹ̀wá 1951
Aláìsí18 March 2014(2014-03-18) (ọmọ ọdún 62)
Iléẹ̀kọ́ gígaUniversity of Düsseldorf

Catherine Obianuju Acholonu (tí a bí ní ọjọ́ kẹrindínlógún oṣù Kẹ̀wá ọdun 1951 – ọjọ́ méjìdínlógún oṣù kẹta ọdun 2014) jẹ́ Olùkọ̀wé, olóṣèlú àti ajàfẹ́to ẹni ọmọ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1]

Òun ni Senior Special Adviser (SSA) sí ààrẹ Olusegun Obasanjo lórí ọ̀rọ̀ àwòrán àti àsà, ó sì tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Association of Nigerian Authors (ANA).[2][3]

Ìpìlẹ̀ àti Ẹ̀kọ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Catherine sínú ìdílé Chief Lazarus Emejuru Olumba àti Josephine Olumba, ní Umuokwara Village, ti ìlú Orlu.[4][5] Òun ni àkọ́bí nínú àwọn ọmọ mẹ́rin.[6]

Ó parí ẹ̀kọ́ Primari àti Sẹ́kọ́ndìrì rẹ̀ ní ilé-ìwé Holy Rosary School, kí wón tó fe fún Brendan Douglas Acholonu nígbà tí ,ó jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́tadínlógún, Douglas jẹ́ onísẹ́ abẹ, Orílẹ̀-èdè Jẹ́mánì sì ló kalẹ̀ sí nígbà náà.[4][5]

Ní ọdun 1974, Catherine tẹ ẹ̀kọ́ rẹ̀ síwájú ní Yunifásítì ti Düsseldorf, ó sì kékọ̀ọ́ gboyè ní ilé-ìwé náà lodun 1977.[4] Ní ọdun 1982, ó gba àmì-èye PhD nínú ìmò èdè Igbo.

Ikú rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Acholonu fi ayé sílè ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kẹta 2014, ó jẹ́ ọmọ ọdún méjìlélógota nígbà náà, ó kú látàrí àìsàn Kíndìnrín.[7]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Umeh, Marie (2011). "Acholonu, Catherine Obianuju". Oxford African American Studies Center (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). ISBN 9780195301731. doi:10.1093/acref/9780195301731.013.48143. Retrieved 2021-05-19. 
  2. "Prof Catherine Obianuju Acholonu". faculty.ucr.edu. Retrieved 2020-05-30. 
  3. Uduma, Kalu (29 May 2020). "Celebrated scholar, Acholonu dies at 63". Vanguard Media Limited. https://www.vanguardngr.com/2014/03/celebrated-scholar-acholonu-dies-63/. 
  4. 4.0 4.1 4.2 Akyeampong, Emmanuel Kwaku; Gates, Henry Louis (2012-02-02) (in en). Dictionary of African Biography. OUP USA. pp. 85–86. ISBN 978-0-19-538207-5. https://books.google.com/books?id=39JMAgAAQBAJ. 
  5. 5.0 5.1 Owomoyela, Oyekan (2008). The Columbia Guide to West African Literature in English Since 1945. Columbia University Press. pp. 56–57. doi:10.7312/owom12686. ISBN 9780231126861. JSTOR 10.7312/owom12686. 
  6. Otiono, Nduka (29 May 2020). "Catherine Acholonu (1951-2014) The Female Writer as a Goddess". Nokoko 4: 67–89. https://carleton.ca/africanstudies/wp-content/uploads/Nokoko-4-Otiono.pdf. 
  7. "Nigeria: Celebrated Scholar, Acholonu Dies At 63". allAfrica.com. 19 March 2014. Retrieved 19 March 2014.