Charlotte Ọlájùmọ̀kẹ́ Ọbasá

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Oloori
Charlotte Ọlájùmọ̀kẹ́ Ọbasá
Ọjọ́ìbíỌjọ́ keje oṣù kìíní ọdún 1874
Èkó
AláìsíDecember 23, 1953(1953-12-23) (ọmọ ọdún 79)
Èkó
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Orúkọ mírànCharlotte Blaize
Iṣẹ́Afowóṣàánú
Gbajúmọ̀ fúnOlùdásílẹ̀ ilé-iṣẹ́ awakọ̀, Anfani Bus Service
Olólùfẹ́Ọmọba Òrìṣàdípẹ̀ Ọbasá
Àwọn ọmọ5
Àwọn olùbátanKòfowórọlá Adémọ́lá

Charlotte Ọlájùmọ̀kẹ́ Ọbasá tí orúkọ abilékọ rẹ̀ ń jẹ́ Blaize, ní wọ́n bí ní Ọjọ́ keje oṣù kìíní ọdún 1874, tí ó sìn kú lọ́jọ́ kẹtàlélógún ọdún 1953 jẹ́ gbajúmọ̀ Afowóṣàánú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó jẹ́ ọmọ bíbí pàràkòyí oníṣòwò R.B. Blaize àti ìyàwó rẹ̀ tí ó jẹ́ oníwòsàn Òrìṣàdípẹ̀ Ọbasá.

Ìgbé-ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Charlotte Ọlájùmọ̀kẹ́ Ọbasá jẹ́ ọmọ Saro tí wọ́n bí sí ìdílé gbajúmọ̀ òṣèlú àti ọlọ́rọ̀, Richard Beale Blaize, àti aya rẹ̀, Emily Cole Blaize. O lo ìgbà èwe rẹ̀ ni ìlú Èkó, níbi tí bàbá rẹ̀ ti jẹ́ olùdásílẹ̀ ìwé-ìròyìn tí wọ́n pè ní The Lagos Times and Gold Coast Colony Advertiser àti The Lagos Weekly Times.[1] Ó kàwé gidi gan-an. Ó kọ́kọ́ kàwé ní ilé-ìwé Anglican Girls' School ní Èkó,lẹ́yìn náà, ó sọdá lọ kàwé sí i lókè òkun lórílẹ̀-èdè England [2]

Lọ́dún 1902, ó fẹ́ Ọmọba Sàró, Ọmọba Òrìṣàdípẹ̀ Obasá. Odidi ilé tuntun ni bàbá rẹ̀ fi fún wọn ní ẹ̀bùn ìgbéyàwó. Ọmọ márùn-ún ni wọ́n bí fún ara wọn. [3]

Ó jẹ́ ìbátan Kòfowórọlá Adémọ́lá [4] Ọlájùmọ̀kẹ́ jẹ́ oníṣòwò àti pàràkòyí afowóṣàánú tó ṣáájú ìjà fún ẹ̀tọ́ àti ìkàwé ọmọ obìnrin. Nítorí akitiyan rẹ̀ ni wọ́n fi dá ilé-ìwé àwọn obìnrin tí wọ́n pè ní Lagos School for Girls tí ó wà di Wesleyan Girls' High School silẹ lọ́dún 1907, lórí ilẹ̀ tí ó yá wọn. Lọ́dún 1913, ó ṣe ìdásílẹ̀ ilé-iṣẹ́ awakọ̀ àkọ́kọ́ sílẹ̀ ní ìlú Èkó tí ó pè ní Anfani Bus Service, nígbà náà, ó ní ọkọ̀ Àjàgbé mẹ́ta, ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ taasí mẹ́ta àti ọkọ̀ èrò, bọ́ọ̀sì mẹ́fà kí ó tó di ọdún 1915.[5]

Lọ́dún 1914,ó wà lára àwọn tí wọ́n dá ẹgbẹ́ Ògbóni ìgbàlódé Reformed Ogboni Fraternity sílẹ̀. Òun ni ó kọ́kọ́ joyè Ìyá Àbíyè nínú ẹgbẹ́ náà lọ́dún kan náà.[6]

Ó tà téru nípàá lọ́dún 1953.[7]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Olajumoke Obasa: The Selfless Social-Worker who established first bus service in Lagos to ease pain of commuters". Neusroom.com. Retrieved October 28, 2020. 
  2. Akintola 1992, p. 86.
  3. Akintola 1992, p. 82.
  4. George 2014, p. 1898.
  5. Schoonmaker 2003, p. 13.
  6. Akintola, Akinbowale (1992), The Reformed Ogboni Fraternity (R.O.F.): The Origins and Interpretation of Its Doctrines and Symbolism, pp. 9 and 10
  7. Akintola 1992, pp. 85 and 86.