David Abioye
| David Abioye | |
|---|---|
| Ọjọ́ìbí | David Olatunji Abioye 11 Oṣù Kẹta 1961 |
| Orílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Ẹ̀kọ́ | University of Ilorin |
| Olólùfẹ́ | Mary Abioye (m. 1988) |
| Àwọn ọmọ | 3 |
| Website | davidabioye.org.ng |
David Olatunji Abioye jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Naijiria ti a bí ní ọjọ kọkànlá oṣù kẹta ọdún 1961 jẹ́ onígbàgbọ, ònkọ̀wé àti oníwàásù; òun ni igbákejì adari ijọ fún ìjọ olorun ìgbàgbọ ayé káàkiri àgbáyé ìyẹn Living Faith Church. [1] O jẹ́ bisoobu ati oníwàásù àgbà ni ìjọ tó wà ní Abuja èyí tí a n pè ní ìlú Goseni tí o ní ìwọn ọmọ ìjọ ọ̀kẹ́ méjì àti àbọ̀ ti o n jọsin níbè, títí di ìgbà tí ó fẹ̀yìntì ní ọjọ́ kejìdínlógún Oṣù Kẹwàá ọdún 2024.[2][3][4]
Ìgbésí ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Nípasẹ̀ àyànfẹ́ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run, ni o fi pe David Olatunji Abioye láti gbé àpẹẹrẹ ìtọ́jú ojúṣe (stewardship) ga nínú Ara Kristi.
Ó kẹ́kọ̀ọ́ Ẹ̀rọ Ayọ́kẹ́lẹ́ (Automobile Engineering), lẹ́yìn tí ó parí iṣẹ́ àgùnbánirọ̀ (NYSC) rẹ̀ ní ọdún 1984, ó ṣiṣẹ́ ní ilé iṣẹ́ onímọ́ ayọ́kẹ́lẹ́ kan, lẹ́yìn náà ó tún kọ́ni ní Polytechnic kan fún ìgbà díẹ̀, kí ó tó dáhùn ìpè iṣẹ́ ìjọsìn yán yán ní Oṣù Kẹwàá ọdún 1986. Ìgbésí-ayé rẹ̀ yí padà ní ọdún 1980 nígbà tí ó pàdé Bíṣọ́ọ̀bù David Oyedepo ní ìpàdé Ẹgbẹ́ Akẹ́kọ̀ọ́ Kristẹni kan. Ìpàdé yìí ló padà di ìbẹ̀rẹ̀ ọdún mẹ́rìnlélógún (40) ti ìṣẹ́-ìránṣẹ́ àti ìtọ́jú labẹ́ rẹ̀. Gẹ́gẹ́ bí onkọ̀wé tó ní ipa, ó ti tẹ̀ ọ̀pọ̀ ìwé tó bo oríṣìíríṣìí apakan ìgbé-ayé jáde.
A bi Abioye sí inú ìdílé kan ni ìpínlẹ̀ Kwara.[5] Abioye se ìgbéyàwó pẹ̀lú arábìnrin Mary Abioye; wọn sì bí ọmọ mẹtaàti vid Jr, Ruth ati Daniel.[6][7] O lọ sí ilé ẹ̀kọ́ gíga yunifásítì ti ilu ilorin láti lọ kọ́ ẹkọ nípa ìmọ ẹrọ ìyẹn (mechanical engineering).O sise olumo ni Ilé ẹkọ gbogbo nise ni Auchi ìyẹn (open cast polytechnic,Auchi) ni ọdún 1985 fún ọdún kan
Iṣẹ́ Ìjọsìn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Nígbà tí ó ṣi ń kọ́mọ ní Polytechnic, ó ní èrò láti dá ilé-iṣẹ́ imọ̀-ẹ̀rọ kan sílẹ̀ láti mú ìṣúná rẹ̀ lágbára. Ṣùgbọ́n lẹ́yìn tí ó pàdé David Oyedepo ní ìpàdé Ẹgbẹ́ Akẹ́kọ̀ọ́ Kristẹni ní ọdún 1980s, ó pinnu láti tẹ̀síwájú sínú ìṣẹ́ ìjọsìn ní àdáyanrí[8]. Lẹ́yìn tí Oyedepo kúrò lọ sí Èkó, Abioye di Olùsọ́-àgùntàn olùgbé (Resident Pastor) ti Garden of Faith, Kaduna, tí ó jẹ́ ilé-iṣẹ́ àgbà ti ìjọ náà nígbà yẹn.[9] Ní ọdún 1993, wọn yan an sípò Bíṣọ́ọ̀bù nínú ìjọ náà[10]. Láti ìgbà yẹn lọ, ó kó ọ̀pọ̀ ipa, lára rẹ̀ ní gẹ́gẹ́bí Olùsọ́-àgùntàn Olùgbé/Àgbà ní Living Faith Churches ní Kaduna, Durumi, àti nígbà míì Goshen lẹ́bàá Abuja, níbi tí ó ti sàmojútó àwọn ìjọ tó ń dàgbà lọ́pọlọpọ̀.
Ní ọjọ́ kejìdínlógún Oṣù Kẹwàá, ọdún 2024, wọn ṣe ìjọsìn ìkíni ìkẹyìn (valedictory service) fún un lẹ́yìn ìfeyinti rẹ̀ kúrò nínú iṣẹ́ ìjọsìn labẹ́ Olùdásílẹ̀ àti Ààrẹ Living Faith Church Worldwide, Bíṣọ́ọ̀bù David Oyedepo.
Lẹ́yìn náà, ó gba àṣẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run láti ṣètò Wákàtí Ìyè ti àgbáyé (Inter-denominational Hour of Revival), pẹ̀lú àwọn olórí àgbáyé àti adarí ìjọ (International Leaders and Ministers Conference). Ó tún jẹ́ Olùsọ́-àgùntàn Àgbáyé (Global Lead Pastor) ti ìjọ ilé (home-based church) kan, Living Word Conquerors Global Assembly.
Ní Oṣù Kínní ọdún 2014, Ààrẹ Nàìjíríà, Goodluck Jonathan, lọ sí ìjọsìn kan ní ìjọ rẹ̀ ní Abuja.[11] Ní Oṣù Karùn-ún ọdún 2015, Agbẹnusọ Ilé Aṣòfin Aṣojú Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Yakubu Dogara, tún lọ sí ìjọsìn Ìdupẹ́ kan ní ìjọ rẹ̀ lẹ́yìn yíyàn rẹ̀ sípò.[12]
Ìtẹ̀jáde ìwé
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Abioye ti tẹ̀ ìwé Kristẹni tí o ju mẹ́ẹ̀dógún (15) lọ, pẹ̀lú àwọn ìwé ìmísí, ìtóni ìgbésí-ayé, ìwé kékeré, ìwé ìròyìn, àti àwọn orísun míì. Àwọn ni wọ̀nyí:
- Making the Most of Opportunity
- Productive Thinking
- The Lifestyle of Faith
- Wisdom From Above
- Releasing The Creative Power of The Mind
- Overcoming Stagnation
- Courage for Conquest
- Creating a New Beginning
- Experiencing God in Prayer
- Stewardship the Pathway to Honour
- Spiritual apprenticeship
- Strategies for Success
Àwọn ì́tọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Adekunle. "Love, Forgiveness panaceas to broken marriages, says Abioye".
- ↑ "2019: Bishop David Abioye lists ways Nigeria is being islamized by Buhari, tells members who to vote".
- ↑ "Interview with Bishop David Abioye, Senior Pastor Of Living Faith Church, Goshen City". Archived from the original on 2018-12-15. Retrieved 2023-12-07.
- ↑ "Serving God is not for clerics alone, says Bishop Abioye".
- ↑ Kolesnik, Kay (28 December 2017). "Life story of Bishop David Abioye". Legit.ng – Nigeria news. (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-02-16.
- ↑ "About Bishop Abioye". Archived from the original on 2020-11-24. Retrieved 2023-12-07.
- ↑ "About Bishop Abioye – David Abioye" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2022-02-16. Retrieved 2022-02-16.
- ↑ https://www.legit.ng/1142770-bishop-david-abioyes-biography.html
- ↑ https://www.legit.ng/1142770-bishop-david-abioyes-biography.html
- ↑ https://www.legit.ng/1142770-bishop-david-abioyes-biography.html
- ↑ http://encomium.ng/president-goodluck-in-living-faith-church-keffi-nasarawa-state/
- ↑ "Ẹda pamosi". Archived from the original on 2020-02-03. Retrieved 2025-12-24.