EkoEXCEL

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

EkoEXCEL jẹ́ ìlànà ètò Ìkẹ́kọ̀ọ́ tuntun tí Ìjọba Ìpínlẹ̀ Èkó ṣẹ̀ṣẹ̀ dá sílẹ̀ lọ́dún 2020 nípa lílo ẹ̀rọ Ìléwọ́ kọ̀m̀pútà fún ìlànà ìkẹ́kọ̀ọ́ ní àwọn ilé ìwé àkóbẹ̀rẹ̀. [1]. Ó jẹ́ ètò ìlànà ìkẹ́kọ̀ọ́ tí ìṣèjọba Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó, Babájídé Olúṣọlá Sanwó-Olú ṣẹ̀ṣẹ̀ dá sílẹ̀ lọ́dún 2020. Nínú ìlànà Ekoexcel yìí, gbogbo àwọn olùkọ́ ni ilé ìwé àkóbẹ̀rẹ̀ ni Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó tí pín ẹ̀rọ Ìléwọ́ kọ̀m̀pútà fún láti kómọ lẹ́kọ̀ó.[2] Nínú ẹ̀rọ yìí, gbogbo àwọn ẹ̀kọ́ tí wọ́n máa kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àti ìlànà bí wọn yóò ti kọ́ wọn ti wà nínú rẹ̀.[3]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Ekoexcel: We’ll continue massive investments in education sector – Sanwo-Olu". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. 2020-01-26. Retrieved 2020-01-27. 
  2. "The A,B,C of EkoEXCEL - The Nation Newspaper". The Nation Newspaper (in Èdè Latini). 2019-12-12. Retrieved 2020-01-27. 
  3. "EKO EXCEL: Lagos begins training of 2,400 primary school teachers". P.M. News. 2019-12-09. Retrieved 2020-01-27.