Georgina Onuoha

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Georgina Onuoha
Ọjọ́ìbíSeptember 29 [1]
Ọmọ orílẹ̀-èdèNaijiria
Iṣẹ́Actress
Ìgbà iṣẹ́1990- di sin

Georgina Onuoha jẹ́ òṣèré Nollywood, afẹwàṣiṣẹ́, olóòtú ètò tẹlifíṣọ̀nù àti afowóṣàánú.[2] Ó wá láti Ìpínlẹ̀ Anámbra ní gúúsù ìla-òòrùn Nàìjíríà.. Ó darapọ̀ mọ́ iṣẹ́ fíìmù ti Nàìjíríà ní ọdún 1990 nígbà tó wà lọ́mọ ọdún mẹ́wàá. Ṣùgbọ́n ó di gbajúmọ̀ ní ọdún 1992 lẹ́hìn kíkópa rẹ̀ nínu eré "Living in Bondage." Wọ́n yàán fún òṣèrè amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ tó dára jùlọ níbi ayẹyẹ Africa Movie Academy Awards. Ní Ọdún 2016, ó fẹ̀họ́nú rẹ̀ hàn gbangba gbàngbà lóri ìgbésẹ̀ Ìjọba Nàìjíríà láti fi owó kuń owó epo pẹtiró.[3] Nínu ìfìwéránṣẹ́ Ínstágràmù rẹ̀ ní Oṣù Kẹẹ̀ta Ọdún 2016, ó jẹ́ kó di mímọ̀ wípé òun ti n bá àìsàn kan fàá láti bí ọdún mẹ́jọ sẹ́yìn.[4]


Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Photos From Georgina Onuoha’s Birthday Party". iyodatv.com. Archived from the original on 22 August 2016. Retrieved 31 July 2016. 
  2. "Nollywood Actress, Georgina Onuoha Shares Stunning Photos". informationng.com. Retrieved 31 July 2016. 
  3. "Actress blasts President Buhari". pulse.ng. Retrieved 31 July 2016. 
  4. "For eight years I have battled illness – Georgina Onuoha [PHOTO]". dailypost.ng. Retrieved 31 July 2016.