Ijo Kristiẹni ti a rà pada

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

 

Redeemed Christian Church of God ( RCCG ) jẹ́ ìjọ pẹ́ńtíkọ́sítì ńlá kan ní Ìpínlẹ̀ Èkó, ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

Enoch Adébóyè ti jẹ́ alábòójútó ìjọ náà láti ọdún 1981. Ìjọ náà tó wà ní Èkó ní àwọn olùjọ́sìn tó ń lọ bíi 50,000 ní ọdún 2022. [1]

Ìtàn[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Rev. Josiah Olufemi Akindayomi (tí wọ́n bí ní ọdún 1909, tó sì kú ní ọdún 1980) dá ìjọ RCCG sílẹ̀ ní ọdún 1952.[2] [3] Reverend Akindayomi yan Enoch Adébóyè gẹ́gẹ́ bíi alábòójútó ìjọ náà. Adeboye jẹ́ olùkọ́ ẹ̀kọ́ mathematics ní University of Lagos, ó sì dara pọ̀ mọ́ ìjọ ní ọdún 1973. Wọ́n kọ́kọ́ gba Adeboye gẹ́gẹ́ bíi ògbufọ̀ láti máa tú àwọn ìwásù Akindayomi láti èdè Gẹ̀ẹ́sì sí èdè Yoruba. Wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bíi olùṣọ́-àgùntàn láti mójútó ìjọ náà ní ọdún 1975. Yíyàn tí wọ́n yàn án sípò yìí tẹ̀lé ìfilehlẹ̀ tí Akindayomi fi lélẹ̀. Ní ọdún 1990, ilé-ìwé fún ẹ̀kọ́ Bíbélì fún ìjọ Redeemed Christian Church of God jẹ́ dídá sílẹ̀. [4]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Warren Bird, World megachurches Archived 2014-11-02 at Archive.is, Leadership Network, USA, retrieved August 21, 2016
  2. Ruth Marshall, Political Spiritualities: The Pentecostal Revolution in Nigeria, University of Chicago Press, USA, 2009, page 74
  3. Nimi Wariboko, Nigerian Pentecostalism, Boydell & Brewer, USA, 2014, page 57
  4. Laurent Fourchard, André Mary et René Otayek, Entreprises religieuses transnationales en Afrique de l'Ouest, Karthala Editions, France, 2005, page 343