Jésù
Jésù ti Násárẹ́tì | |
---|---|
![]() orundun-6th mosaic ti Jesus ni Basilica ti Sant'Apollinare Nuovo ni Ravenna. Nipase awon apejuwe ti Jesus wa se pataki ni asa , ko si iwe iranti nipa aworan Jesu laisi ariyanjiyan ti awa mo pé wa ninu agbaye. | |
Ọjọ́ìbí | c. 4 BC/BCE[1] Bethlehem, Judea, Ilẹ̀ọbalúayé Rómù (traditional); Nazareth, Galilee (historical Jesus)[2] |
Aláìsí | c. 30 AD/CE[1] Calvary, Judea, Ilẹ̀ọbalúayé Rómù (According to the New Testament, he rose on the third day after his death.) |
Cause of death | igi agbelebu (Awa gbagbo itan-akọọlẹ, O se pataki gidigan ni igbagbo Kristeni) Ko si idi/ O wa ariyanjiyan fun iku re (Igbagbo Isilamu) |
Resting place | Traditionally and temporarily, a garden tomb located in what is now the Ile ijosin ti Holy Sepulchre, Jerúsálẹ́mù.[3] |
Tani je Jesu ti Nasareti? (Omo Olorun)
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Jésù ará Násárẹ́tì (c. 5 BC/BCE – c. 30 AD/CE[1]), tàbí Jésù Kírísítì tabi Jésù, jẹ́ ẹni tó ṣe kókó jùlọ, yàtọ̀ sí Ọlọ́run nínú Ẹ̀sìn Kírísítì, tí àwọn ẹlẹ́sìn náà gbà gẹ́gẹ́ bí Olùgbàlà Aráyé, èyí tí ó jẹ́ àsọtẹ́lẹ̀ ni Májẹ̀mú Láéláé nínú Bíbélì, tí gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣin Kíristi tàbí irú wọn gbà pé òun ni Ọmọ Ọlọ́run àti àwòrán Ọlọ́run tí ó jí dìde nínú ipò òkú.[4] Islamu gba Jesu gege bi woli ati Messiah.[5] Ọ̀pọ̀ àwọn ẹ̀sìn mìíràn ni wọ́n tún tẹrí ba fún un lóríṣi ọ̀nà. Jésù jẹ́ ẹnìkan tó ṣe pàtàkì nínú ìtàn ọmọ ènìyàn.
Kini Jesu ti Nasareti ti se
Jesu ti Nasareti ti fi ku fun ese wa, o ti wa si ayé lati se èsè ayé lo.[6]
Ko si eni ti o ri Olorun ri, sugbon eniyan ti o wa lati Olorun, o ti o fihan. Jesu Kristi a mu opolopo eniyan larada, o ti fun wa ireti ati, o ti kọ wa.
Johanu 3:16 « “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. »[Bibeli Mimo 1]
Awon Oruko miiran fun Jesu Kristi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Jesu Kristi ni awon orisirisi oruko, nitori, won je orisirisi ohun fun wa, awa n pe o:
- Imolè Arayé
- Oluso-Aguntan Dara
- Ounje Iyè
- Odo-Aguntant Olorun
- Onise Iyanu
- O yigiyigi
- Alagbawi Eda
- Alakoso Orun
- Eleda ti a ti da gbogbo wa
- Olorun ti ogbon
- Aròmoniṣe Faiyàsì
- Olugbala Aràyé
- Oba Igbala
- Oba Nla
- Oba to ga
- Edumare
- Ibere ati ipari
- Oba Mimo
- Oba awon Oba
- Kabiyesi
- Oluwa Olorun
- Orò (Orò Olorun)
- Alade Ogo
- Kiniun ti eya ti Judah
- Olorun Agbayé
- Alagbada ina
Se Jesu ma pada akoko keji?
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Bee ni, Jesu ma pada akoko keji, fun idajo.
Johanu 5: 24-29
24 “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó bá sì gba ẹni tí ó rán mi gbọ́, ó ní ìyè tí kò nípẹ̀kun, òun kì yóò sì wá sí ìdájọ́; ṣùgbọ́n ó ti ré ikú kọjá bọ́ sí ìyè. 25 Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, wákàtí náà ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn òkú yóò gbọ́ ohùn ọmọ Ọlọ́run: àwọn tí ó bá gbọ́ yóò sì yè. 26Nítorí pé gẹ́gẹ́ bí Baba ti ní ìyè nínú ara rẹ̀; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ó sì fi fún ọmọ láti ní ìyè nínú ara rẹ̀; 27Ó sì fún un ní àṣẹ láti máa ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú, nítorí tí òun jẹ́ ọmọ ènìyàn.[7]
28 “Kí èyí má ṣe yà yín lẹ́nu; nítorí pé wákàtí ń bọ̀, nínú èyí tí gbogbo àwọn tí ó wà ní ibojì yóò gbọ́ ohun rẹ̀. 29 Wọn ó sì jáde wá; àwọn tí ó ṣe rere, sí àjíǹde ìyè; àwọn tí ó sì ṣe búburú sí àjíǹde ìdájọ́. 30 Èmi kò le ṣe ohun kan fún ara mi: bí mo ti ń gbọ́ ni, mo ń dájọ́: òdodo sì ni ìdájọ́ mi; nítorí èmi kò wá ìfẹ́ ti èmi fúnra mi, bí kò ṣe ìfẹ́ ti ẹni tí ó rán mi.[8]
Mati 24: 36- 42
36 “Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan ti ó mọ ọjọ́ àti wákàtí tí òpin náà yóò dé, àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀ ọ́n. Àní, ọmọ kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe Baba mi nìkan ṣoṣo ló mọ̀ ọ́n. 37Bí ó ṣe rí ní ìgbà ayé Noa, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí. 38Nítorí bí àwọn ọjọ́ náà ti wà ṣáájú ìkún omi, tí wọ́n ń jẹ́ tí wọ́n ń mu, tí wọ́n ń gbéyàwó, tí wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí tí ó fi di ọjọ́ tí Noa fi bọ́ sínú ọkọ̀. 39Ènìyàn kò gbàgbọ́ nípa ohun tí o ṣẹlẹ̀ títí tí ìkún omi fi dé nítòótọ́, tí ó sì kó wọn lọ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn. 40Àwọn ọkùnrin méjì yóò máa ṣiṣẹ́ nínú oko, a o mú ẹnìkan, a ó sì fi ẹni kejì sílẹ̀. 41Àwọn obìnrin méjì yóò jùmọ̀ máa lọ ọlọ pọ̀, a yóò mú ọ̀kan, a ó fi ẹni kejì sílẹ̀.[9]
42 “Nítorí náà, ẹ múra sílẹ̀, nítorí ẹ kò mọ ọjọ́ tí Olúwa yín yóò dé.[10]
Awon Òrò-Olorun
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Isaiah 42:5 «5 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí
Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde,
tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn,
Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí
àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:»
Olorun tobi gan ati awa nilo lati sin òun.
![]() |
Àyọkà yìí tàbí apá rẹ̀ únfẹ́ àtúnṣe sí. Ẹ le fẹ̀ jù báyìí lọ tàbí kí ẹ ṣàtúnṣe rẹ̀ lọ́nà tí yíò mu kúnrẹ́rẹ́. Ẹ ran Wikipedia lọ́wọ́ láti fẹ̀ẹ́ jù báyìí lọ. |
Ẹ tún le ka
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ 1.0 1.1 1.2 Sanders (1993).p.11, p 249.
- ↑ "Awa gbagbo pe Jesu wa lati Nasareti." Theissen, Gerd; and Merz, Annette. itan-akọọlẹ Jesu: ìtọ́sọ́nà asoye. Minneapolis: Fortress Press. 1998. Tr lati Jẹmánì (1996 àtúnse). p. 165. ISBN 978-0-8006-3123-9
- ↑ Eusebius, (trans. Cameron, Averil; Hall, Stuart G.). Life of Constantine. Oxford: Clarendon Press; New York : Oxford University Press, 1999. ISBN 978-0-19-814917-0
- ↑ Theologian and bishop Lesslie Newbigin says "the whole of Christian teaching would fall to the ground if it were the case that the life, death, and resurrection of Jesus were not events in real history but stories told to illustrate truths which are valid apart from these happenings." Newbigin, J. E. L. (1989). "The Gospel In a Pluralist Society". London: SPCK. p. 66.
- ↑ Abdulsalam, M. (19 February 2008). "Jesus in Islam". IslamReligion.com.
- ↑ https://www.bible.com/bible/911/JHN.3.YCB
- ↑ https://www.bible.com/bible/911/JHN.5.YCB
- ↑ https://www.bible.com/bible/911/JHN.5.YCB
- ↑ https://www.bible.com/bible/911/MAT.24.YCB
- ↑ https://www.bible.com/bible/911/MAT.24.YCB
Àṣìṣe ìtọ́kasí: <ref>
tags exist for a group named "Bibeli Mimo", but no corresponding <references group="Bibeli Mimo"/>
tag was found