Kùránì

| Ìkan nínú àwọn àyọkà lórí |
| Ìmàle |
| Ìgbàgbọ́ |
|---|
|
Allah · Ọ̀kanlọ̀kan Ọlọ́run · Àwọn Ànábì · Revealed books · Àwọn Mọ̀láíkà |
| Àwọn ojúṣe |
| Àwẹ̀ · Ìṣọrẹ · Ìrìnàjò |
| Ìwé àti òfin |
| Fiqh · Sharia · Kalam · Sufism |
| Ìtàn àti olórí |
|
Timeline · Spread of Islam Imamate |
| Àṣà àti àwùjọ |
|
Academics · Animals · Art Mọ́ṣálásí · Ìmòye Sáyẹ́nsì · Àwọn obìnrin Ìṣèlú · Dawah |
| Ẹ̀sìn ìmàle àti àwọn ẹ̀sìn yìókù |
| Hinduism · Sikhism · Jainism · Mormonism |
| Ẹ tún wo |
| Glossary of Islamic terms |
|
Èbúté Ìmàle |
Kùrání jẹ́ ìwé mímọ́ ẹ̀sìn Islam, èyí tí àwọn Mùsùlùmí jákèjádò orílẹ̀ àgbáyé gbà pé ó jẹ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ọba tí ó fi rán Ànọ́bì Mùhámọ́dù (kí ìkẹ́ àti àlàáfíà Ọlọ́run ó lọ máa bá a) wá sí ilé ayé. Ìgbàgbọ́ àwọn Mùsùlùmí ni pé Ọlọ́run Ọba sọ kùránì kalẹ̀ fún òjíṣẹ́ rẹ̀ ẹni tí í ṣe Ànọ́bì Mùhámọ́dù (kí ìkẹ́ àti àlàáfíà Ọlọ́run ó lọ máa bá a) láti fi tọ́ àwọn ènìyàn sí ojú ọ̀nà Ọlọ́run Ọba. Ọlọ́run Ọba fi kùránì ránṣẹ́ sí Ànọ́bì Mùhámọ́dù (kí ìkẹ́ àti àlàáfíà Ọlọ́run ó lọ máa bá a) ní ẹni ogójì ọdún nígbà tí ó wà nínú ihò àpáta Hira. Áńgẹ́lì tí Ọlọ́run rán sí ànọ́bì Mùhàmọ́dù (kí ìkẹ́ àti àlàáfíà Ọlọ́run ó lọ máa bá a) ni ó ń jẹ́ Jibril (angel Gabriel). Kùránì jẹ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ọba tí ànọ́bì fi máa ń kọ́ àwọn Mùsùlùmí, èyí tí ó sì jẹ́ àtẹnudẹ́nu. Kùránì ní orí mẹ́rìnléláàdọ́fà, èyí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní onírúurú ẹsẹ.
Kùránì jẹ́ ìwé Ọlọ́run Ọba èyí tí ó ti wà láti bí àìmọye ọdún tí ó sì wà ní kíkọ sílẹ̀ ní èdè Lárúbáwá. Èyí tí ó mún un jẹ́ ìwé tí ó péye jùlọ tí ó wà ní àkọsílẹ̀ ní èdè Lárúbáwá. [1][2][3]
Kùránì kì í ṣe ìwé ẹ̀sìn lásán; ó jẹ́ ìwé ìtọnisọ́nà tí ó péye jùlọ fún gbogbo àwọn Mùsùlùmí káàkiri àgbáyé. Ó ń kọ́ ni nípa ìgbàgbọ́ nínú Ọlọ́run Ọba ọ̀kan ṣoṣo (Tawhíd), ó ń kọ́ ni nípa ìwà rere, ó ń kọ́ ní ìfaradà, ìfẹ́, ìdájọ́ òdodo, àti bí ènìyàn ṣe yẹ kí ó bá ara rẹ̀ àti awùjọ gbé. Ó tún máa ń sọ nípa ìtàn àwọn òjíṣẹ́ tí wọ́n ti lọ. Bẹ́ẹ̀ ni ó ń kọ́ni bí a ṣe ń ṣètò àwùjọ pẹ̀lú àlàáfíà.
Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ṣe sọ, ọ̀pọ̀ nínú àwọn sọ̀hábà Ànábì Muhammad (kí ìkẹ́ àti àlàáfíà Ọlọ́run ó máa bá a) ni wọ́n ṣiṣẹ́ takuntakun nípa ṣíṣe àkọsílẹ̀ àti àkójọpọ̀ kùránì. Ṣáájú kí Ànábì Muhammad (kí ìkẹ́ àti àlàáfíà Ọlọ́run ó máa bá a) ó tó papòdà ni àwọn Mùsùlùmí tí hà kùránì sí orí, tí púpọ̀ nínú wọn sì mọ̀ ọ́n tọkàntọkàn.
Lẹ́yìn ikú Ànábì Muhammad (kí ìkẹ́ àti àlàáfíà Ọlọ́run ó máa bá a), a ṣe àkójọpọ̀ kùránì pẹ̀lú àṣẹ Kàlífà àkọ́kọ́, Abu Bakr (ó lo ìṣàkóso rẹ̀ láti ọdún 632 sí ọdún 634). Àwọn Sọ̀hábà tí wọ́n ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀ tàbí tí wọ́n mọ̀ ọ́n tọkàntọkàn ni wọ́n ṣàkójọ gbogbo rẹ̀ jọ kí ó lè wà nínú ìwé kan ṣoṣo kí á má ba à pàdánù wọn.
Ní àkókò ìjọba Kàlífà kẹta, Uthman ibn Affan ẹni tí ó lo ìṣàkóso láàárín ọdún 644 sí ọdún 656, ni wọ́n dá ẹ̀dà kan tí a fọwọ́ sí sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí èyí tí a fọwọ́ kọ tí ó sì pé pérépéré. Ẹ̀dà yìí ni a mọ̀ sí Mushaf ‘Uthmānī, tí a sì kà á sí ìpìlẹ̀ kùránì èyí tí a mọ̀ lónìí. Ó paṣẹ kí ẹ̀dà yìí ó kárí káàkiri àwọn agbègbè àti ìletò tí àwọn Mùsùlùmí wà nígbà náà, kí ìyàtọ̀ kíkà ó má ba à dàrú láàárín àwọn Mùsùlùmí.
Síbẹ̀, àwọn ìlà kíkà (Qirā’āt) kan wà tí wọ́n ní ìyàtọ̀ kékeré nínú ìtúmọ̀ tàbí bí a ṣe máa ń ka àwọn ọ̀rọ̀ kan, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo wọn dá lórí ìpìlẹ̀ kan náà.
Ní ayé òde òní, ìwádìí jinlẹ̀ nípa kùránì ti di ẹ̀ka ẹ̀kọ́ kan tí a mọ̀ sí ẹ̀kọ́ nípa kùránì, níbi tí àwọn amòye ti ń ṣe ìtúpalẹ̀ lórí ìtàn, èdè, àkójọpọ̀, àti ìtumọ̀ rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì àti ẹ̀kọ́ gíga.
| Àyọkà yìí tàbí apá rẹ̀ únfẹ́ àtúnṣe sí. Ẹ le fẹ̀ jù báyìí lọ tàbí kí ẹ ṣàtúnṣe rẹ̀ lọ́nà tí yíò mu kúnrẹ́rẹ́. Ẹ ran Wikipedia lọ́wọ́ láti fẹ̀ẹ́ jù báyìí lọ. |
Àwọn ìwé Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Guillaume, Alfred (1954). Islam. Edinburgh: Penguin books. p. 74. "It may be affirmed that within the literature of the Arabs, wide and fecund as it is both in poetry and in elevated prose, there is nothing to compare with it."
- ↑ Toropov, Brandon; Buckles, Luke (2004). Complete Idiot's Guide to World Religions. Alpha. p. 126. ISBN 978-1-59257-222-9. "Muslims believe that Muhammad's many divine encounters during his years in Mecca and Medina inspired the remainder of the Qur'an, which, nearly fourteen centuries later, remains the Arabic language's preeminent masterpiece."
- ↑ Esposito, John (2010). Islam: The Straight Path (4th ed.). Oxford University Press. p. 21. ISBN 978-0-19-539600-3. "Throughout history, many Arab Christians as well have regarded it as the perfection of the Arabic language and literature."
- (Gẹ̀ẹ́sì) Al-Quran (Kùránì) Archived 2009-01-29 at the Wayback Machine.
- AL QURA`AN ALAPỌNLE PẸLU ITUMỌ RẸ NI EDE YORUBA