Nancy Illoh

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Nancy Illoh
Iléẹ̀kọ́ gígaNnamdi Azikiwe University
Iṣẹ́TV presenter
Journalist
Media Consultant
EmployerAfrica Independent Television

Nancy Illoh jẹ́ akọ̀ròyìn, ọmọ orílẹ̀-èdè Naijiria. Ó jẹ́ olóòtú ètò "MoneyShow" lórí Africa Independent Television, ó sì tún jẹ́ olùdámọ̀ràn media àti alákòóso òwò ilẹ̀ Afirika ní Daarsat. Ó jẹ́ alákòóso àgbà ti African Economic Congress.

Ìgbésí ayé àti ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọmọ bíbí ipinle Delta ní Illoh, ó sì jẹ́ àkọ́bí nínú ọmọ mẹ́fà. Wọ́n bí i ní Ìpínlẹ̀ Èkó, lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà níbi tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ kí ó tó wá lọ Yunifásítì Nnamdi Azikiwe, Awka níbi tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè BSc. nínú ìmọ̀ Parasitology àti Entomology.

Iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Nancy Illoh jẹ́ agbéròyìn sáfẹ́fẹ́, àti olóòtú ètò nípa ọ̀rọ̀ owó-ìṣúná àti ètò ọrọ̀-ajé tí wọ́n máa ń fi hàn ní Naijiria àti ilẹ̀ Adúláwọ̀.

Ní ọdún 2007, ó dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ tó ń gbé ètò "MoneyShow" kalẹ̀, tí wọ́n máa ń fi hàn lórí AIT, tí wọ́n sì máa ń ṣe ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò pẹ̀lú àwọn ọmọ Africa lórí ètò ọrọ̀-ajé àti owó-ìṣụ́ná. Òun àti ẹgbẹ́ rè ti ṣe ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò fún Ààrẹ àná ti African Development Bank, tórúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Donald Kaberuka, ọ̀jọ̀gbọ́n John Kuffor, tó jẹ́ Ààrẹ ìlú Ghana tẹ́lẹ̀, Adams Oshiomhole àti Sanusi Lamido Sanusi, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. [1]

Obi Jideuwa, tí ó jẹ́ Ọba ìlú Issele Azagba, ní apá Àríwá Aniocha ní ipinle Delta fi joyè Adã Né kwùlí Ọwáa.

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Empty citation (help)