Jump to content

Olusola Idris Osolo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Otenibotemole II
Àdàkọ:Post-nominals
Olofin Adimula Oodua

Otenibotemole II
Reign ọjọ́ kẹsàn-án oṣù kejì ọdún 2024Àdàkọ:Sndashpresent
Coronation Ọgbọ́n ọjọ́ oṣù kẹta ọdún 2024
Predecessor Abdul-Lateef Adeniran Akanni Ojikutujoye I
Spouse
  • Taheebat Omotolani Osolo
Issue
3
Full name
Olusola Idris Adebowale Lamidi Osolo
House Okewaye Ruling House
Father Late Musiliu Olatunji Lamidi
Mother Alhaja Azeezat Omolola Lamidi
Born 27 Oṣù Kẹjọ 1988 (1988-08-27) (ọmọ ọdún 35)
Ado-odo, Western State, Nigeria (now in Ìpínlẹ̀ Ògùn, Nigeria)

Oba Olusola Idris Osolo tí a tún mọ̀ sí (Otenibotemole II) Àdàkọ:Post-nominals (tí wọ́n bí lọ́jọ́ ketàdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹjọ ọdún 1988) ni ọba Adó-odò kọkànlélógójì àti Olofin Adimula Oodua ti Ado-Odo. Ó gorí ìtẹ́ lọ́jọ́ kẹsàn-án oṣù kejì ọdún 2024 lẹ́yìn ikú ọba Abdul-Lateef Adeniran Akanni Ojikutujoye I tí ó jẹ́ Olofin Adimula Oodua ogójì ìlú Ado-Odo.[1]

Ìran rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọn bí Ọba Ọtẹ̀níbọ̀tẹ̀mọ́lẹ̀ II ní ìdílé Ọ̀sọ́lọ̀ ti ìdílé ọba Okéwayè, ọkàn nínú àwọn ìdílé ọba mẹ́rin tí ó wà ní Adó-odò. Bàbá rẹ̀ tí ó ti kú, Músílíù Ọlátúnjí Lámídì ti ṣe igbákejì Ọ̀gá-ọlọ́pàá àgbà kí ó tó kú lóṣù kẹrin ọdún 1988, ó jẹ́ ìran Ọba Aṣádé Awòpẹ́ ti Ọtẹ̀níbọ̀tẹ̀mọ́lẹ̀ tó jọba lọ́dún 1884 sí 1913.[2] Ìyá rẹ̀, Alhaja Azeezat Ọmọlọlá Lámídì (ọmọ Agbógunlórí), jẹ́ ènìyàn pàtàkì tí o ti jẹ oyè òtún ìyálọ́jà àti Ọ̀tún Ìyá Àdínnìn ti ilu Adó-odò.

Ìyànsípò àti ìgbà dé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ìgbìyànjú láti yan ọmọ oyè tòótọ́ sípò In a bid to determine the rightful heir to the revered position of Ọlọ́fin Adìmúlà Oòduà, wọ́n yan Ọlọ́fin Olúṣọlá Ọsọ́lọ̀ sáàárín àwọn ọmọ oyè mẹ́rìnlá láti ìdílé oyè ọba Òkèwáyé ti Adó-odò tí àwọn náà lẹ́tọ̀ọ́ sí ìtẹ́ ọba Adó-odò. Kọ́míṣánnà fún Ìjọba-ìbílẹ̀ àti ọ̀rọ̀ nípa oyè jíjẹ ní Ìpínlẹ̀ Ògùn àti àjọṣepọ̀ pẹ̀lú ìjọba-ìbílẹ̀ Adó-odò /Ọ̀tà, ṣe ìdìbò lọ́jọ́ kẹsàn-án oṣù kejì ọdún 2024. Ìdìbò náà jẹ́ èyí tí kò ní èrú tí ó sì tẹ́lẹ̀ ìlànà òfin láìṣẹègbè fún ẹni kankan.[3][4]

Ó borí láàárín gbogbo àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ nígbà tí ó kó ìbò tó pọ̀jù àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀ lọ. Bíborí rẹ́ kì í ṣe iyì rẹ̀ nìkan, ṣùgbọ́n ìjẹ́rìí sí ìwà àti gbajúmọ̀ rẹ̀ àti bí ó ti ṣe ti máa ń dá sí ètò ìlú látẹ̀yìnwá. Àti bí ó ṣe mọ̀ nípa àṣà, ìṣe àti bí wọ́n ṣe ń darí ìlú náà l. Ó gbà ọ̀pá-àṣẹ lọ́jọ́ ọgbọ̀n, oṣù kẹta ọdún 2024.[5]

Kọ́míṣánnà Ìpínlẹ̀ Ògùn fún Ìjọba Ìbílẹ̀ àti ọ̀rọ̀ nípa oyè jíjẹ ń fún ọba Olúṣọlá ní ọ̀pá-àṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọba Adó-odò

Ìgbésí ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìyàwó rẹ̀ ni Olorì Taheebat Ọmọtọ́lání Ọsọ́lọ̀, wọ́n bímọ mẹta.

Bákan náà, ó jẹ́ ẹni tí ó fẹ́ràn eré-ìdárayá, pàápàá jù lọ, ó féràn ìdàgbàsókè àwọn ọ̀dọ́. Ó wà lára àwọn agbábọ́ọ̀lù-àfẹ́sẹ̀gbá, kódà, ó wà lára àwọn tó gbá ayò wọlé nígbà tí wọ́n gbá ìdíje aláfẹ́ kan tí wọ́n pè ní Adó-odò Legend, tí àwọn ọ̀dọ́ Adó-odò ṣètò lọ́dún 2023 ní pápá ìṣeré tó dára.[6]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Excitement as Gov Abiodun presents staff of office to young monarch of ancient town". pulse.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 30 March 2024. Retrieved 2024-03-30. 
  2. "35-yr-old prince ascends his ancestor's throne 111 years after his progenitor's death". pulse.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 28 February 2024. Retrieved 2024-02-28. 
  3. "Lamidi-Osolo Elected as Olofin Adimula Odua of Ado Odo Kingdom". independent.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 10 February 2024. Retrieved 2024-02-10. 
  4. "President Tinubu Congratulates Oba Olusola Lamidi–Osolo on Ascension to the Throne of Olofin of Ado–Odo". statehouse.gov.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2024-03-31. 
  5. "Abiodun presents staff of office to 35-year-old monarch". punchng.com (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 30 March 2024. Retrieved 2024-03-31. 
  6. "Prince Idris Olusola Lamidi-Osolo Emerges As Elect Olofin Adimula Odua of Ado Odo Kingdom". octagonagentsofdevelopmentdirectory.com.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2024-02-10.