Jump to content

Pelu Awofeso

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Pelu Awofeso
Orílẹ̀-èdèNigerian
Iṣẹ́Journalist, travel-writer, tour guide
Gbajúmọ̀ fúnTour guiding, travel writing
AwardsCNN/Multichoice African Journalists Award

Pẹ̀lú Awófẹ̀sọ̀ jẹ́ akọ̀ròyìn ọmọ orílẹ̀-edè Nàìjíríà, ó jẹ́ ọ̀ǹkọ̀wé nípa ìrìn-àjò àti àṣà, tó ń gbé ìlú Èkó, ní] Nàìjíríà. Ó jáwẹ́ olúborí nínú ìdíje ti CNN/Multichoice ní Africa fún àmì-ẹ̀yẹ ti ẹ̀ka àwọn oníròyìn nípa ìrìn-àjò. Ní ọ̀pọ̀ ìgbà ní à ń ṣe àpèjúwe rẹ̀ gẹ́gé bíi "aṣáájú òǹkọ̀wé nípa ìrìn-àjò" [1] Ó tún jẹ́ òǹkọ̀wé tí a ṣatẹ̀jáde ìwé rẹ̀.[2]


Iṣẹ́ Ìṣe Rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Awofeso sọ pé òun bẹ̀rẹ̀ sí ní ní ìfẹ́ sí ìrìn-àjò lẹ́yìn ìrírí àkọ́kọ́ tí ó ní nípa ìlú Jos ní Ìpínlẹ̀ Plateau, ní Nàìjíríà, ní ọdún 1998..[3] Ìrírí tí ó ní, ní í ṣe pẹ̀lú bí ẹwà ìlú náà ṣe fún un ní ìyàlẹ́nu gan-an, àti bí ó ṣe rí “àwọn ìṣọwọ́kọ̀wé àtijọ́ tí àwọn British Land kọ,” tí wọ́n ṣe àkọsílẹ̀ ìrìn-àjò wọn ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ní Nàìjíríà gẹ́gẹ́ bí colonialists , ló fún un ní ìmísí láti gba ìrìn-àjò gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́-ọkàn (hobby) rẹ̀.

Ó sọ wípé "Mo rí àwọn àwòrán láti ọdún 1930s, 1940s àti 1950s; wọ́n lágbára gidi gan-an tó bẹ́ẹ̀ tí mo fi ń rí bí ẹni pé mò ń rí wà àkókò náà gan-an. Lẹ́yìn tí wọ́n kúrò, mi ò rò pé ọ̀pọ̀ ènìyàn tún ń ṣe irú iṣẹ́ bẹ́ẹ̀ mọ́. Àwọn ìrírí wọ̀nyí ló dá ìfẹ́ sí mi lọ́kàn láti tẹ̀ lé ìgbésẹ̀ wọn, kí n máa rin ìrìn àjò káàkiri Nàìjíríà, kí n sì ṣe àkọsílẹ̀ ohun tí mo ti rí. Ó tún mú kí n nífẹ̀ẹ́ púpọ̀ sí Jọ́ọ̀sì àti sí ìrìn-àjò, kí n lè kọ̀wé nípa ibi ẹlẹ́wà yìí tí àwọn ènìyàn ti kọ̀wé nípa rẹ̀ ní àádọ́ta ọdún sẹ́yìn. Mo fẹ́ kọ nǹkan tó ma ṣàǹfàní fún àwùjọ. Mo dẹ̀ ní láti ronú nípa kíkọ nǹkan nípa Nàìjíríà lọ́nà tí yóò jẹ́ kí àwọn ènìyàn mọ rírì rẹ̀,nílé, lóko àti lẹ́yìn odi.[4]

Títí di 2017,Ó ti ṣe àbẹ̀wò sí àwọn Ìpínlẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n nínú ìpínlẹ̀ mẹ́rìndínlógójí tí a ní ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà [5] ó sì ti kó ìwé lórí púpọ̀ nínú wọn . Wọ́n ṣe àfiwéra iṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú Looking for Transwonderland Noo-Saro-Wiwa ṣe àgbéjáde rẹ̀.[6]

Àwọn àtẹ̀jáde ìwé láti ọwọ́ rẹ

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Awofeso ni olùtẹ̀wé ìwé ìròyìn ìrìnàjò lórí ayélujára kan tí a pè ní Waka About.[7] Ó tún ni olóòtú ìwé Route 234, ìwé ìtàn ìrìnàjò kan tí a ṣàpèjúwe gẹ́gẹ́ bí "àkójọ ìtàn láti ọ̀dọ̀ àwọn oníròyìn Nàìjíríà tí ó ṣe àgbéyẹ̀wò ìrírí ara ẹni nígbà tí wọ́n ń rìnrìn àjò níta Nàìjíríà"[8] Ohun tí ó dúró fún, "ní gbogbogbòò, jẹ́ ìdásí sí ààyè kan níbi tí a ti nílò ìsapá púpọ̀ sí i irú èyí."[9]

Ní ọdún 2010, ó tẹ ìwé Tour of Duty jáde, ìwé kan tí ó “kọ sílẹ̀ fún oṣù mẹ́wàá tí ó rìnrìn àjò ní gbogbo Nàìjíríà, ó sì sọ ìtàn àwọn ènìyàn àti àwọn ibi tí ó bá pàdé lójú ọ̀nà, láti ọ̀dọ̀ àwọn tí ń ta iyanrìn ní Yenagoa sí àwọn ọdẹ ní Osogbo.[10]

Àwọn ìrìnàjò rẹ̀ míràn

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Awofeso, ní ọdún 2014, tún dá ẹgbẹ́ kan sílẹ̀ tí a ń pè ní "Beach Samaritans" tí wọ́n ń rìn kiri etíkun ní Èkó láti fọ àwọn ìdọ̀tí àti ìdọ̀tí tí a kò fẹ́ mọ́.

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "Pelu Awofeso: Nigeria’s foremost travel writer | MyWeku Tastes". MyWeku Tastes. 10 April 2016. Archived from the original on 6 November 2017. https://web.archive.org/web/20171106103928/http://mywekutastes.com/pelu-awofeso-nigerias-foremost-travel-writer/.
  2. "Ajimobi, Tinubu urge journalists to be fearless". The Punch. Archived from the original on 2015-06-15. Retrieved 2015-06-13. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. "Q&A: Travel writer, journalist and publisher Pelu Awofeso". 15 July 2013. https://africainwords.com/2013/07/15/qa-travel-writer-journalist-and-publisher-pelu-awofeso/.
  4. "Q&A: Travel writer, journalist and publisher Pelu Awofeso". 2013-07-15. https://africainwords.com/2013/07/15/qa-travel-writer-journalist-and-publisher-pelu-awofeso/.
  5. "Northern Nigeria Is Vastly Beautiful – Pelu Awofeso". Concise News. 27 January 2017. https://www.concisenews.global/news/northern-nigeria-is-vastly-beautiful-pelu-awofeso/.
  6. Jones, Rebecca (2014). "'Nigeria is my Playground': Pẹlu Awofẹsọ's Nigerian travel writing" (in en). African Research and Documentation 125: 65–85. doi:10.1017/S0305862X00020665. ISSN 0305-862X. https://www.cambridge.org/core/journals/african-research-and-documentation/article/abs/nigeria-is-my-playground-pelu-awofesos-nigerian-travel-writing/44402676BED6C93485B438D17FEFA800.
  7. "WORLD TOURISM DAY: Travel writer picks Jos as Nigeria's hottest tourist destination despite violence, By Omena Abenabe – Premium Times Nigeria". Premium Times Nigeria. 29 September 2013. https://www.premiumtimesng.com/entertainment/145638-world-tourism-day-travel-writer-picks-jos-nigerias-hottest-tourist-destination-despite-violence-omena-abenabe.html.
  8. Awofeso, Pelu (2 June 2016). "Route 234, an Ebook by Pelu Awofeso". Smashwords. Archived from the original on 7 November 2017. Retrieved 3 November 2017. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  9. "Travel as Life: A Review of Route 234". ktravula – a travelogue!. 16 September 2016. http://www.ktravula.com/2016/09/travel-as-life-a-review-of-route-234/.
  10. "Q&A: Travel writer, journalist and publisher Pelu Awofeso". 15 July 2013. https://africainwords.com/2013/07/15/qa-travel-writer-journalist-and-publisher-pelu-awofeso/.