Soji Cole

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Olùborí èbùn Lítíráṣọ̀ fún NLNG ti ọdún 2018, Soji Cole ni ọfiisi rẹ ní Yunifásítì ti ìlú Ìbàdàn ni oṣù kẹwàá ọdún 2018.

Olusoji Henry Cole jé olùkọ́ àgbà ilé èkó kan ní Nàìjíríà, tí í şe ti kan Yunifásitì t'ìlú Ìbàdàn. Gbajú-gbajà akòtàn àti onkòwé ní ó jé pèlú. Ó jé olùgba èbun fún Lítíréşo ní Nàìjíríà t'odún 2018. Àwọn agbègbè tàbí àfojúsùn ìwádìí rẹ dá l'órí i eré òun ìtójú u àwọn ìjìnlè ogbè àti ìwádìí iṣé àdáṣe ti àṣà.

Ìwé e rè, Embers je òkan nínú u àwọn ìwé Nàìjíríà tí ó dára jù lọ fún ọdún 2018 nínú u àkójọ ìwe ìròyìn ÀgbékèléOjoojúmó (DailyTrust).

Cole jé akẹ́kọ̀ọ́ jáde ilé ìwé gíga ti Yunifásitì Ìbàdàn (University of Ibadan). Ó tún jé ẹlégbé àbèwò ní ilé èkó gíga ti Roehampton.

Cole ṣo fún Dailytrust pé kíkọ àwọn ìtàn kúkúrú ni bí òun ṣe ní ìkéde àkókó ọ rè. Nígbà tí ó ń s'òrò l'órí i àwọn ìtaláyà tí àwọn onkòwé tí ó ṣé yọ ní orílè èdè Nàìjíríà. Ó s'ọ̀rọ̀ àwọn ìdíwó ìnáwó àti ìdínkù àwon olùgbé ìlú bí i àwọn okùnfà tí ń dín awon awakò ìmòwé kù l'óríle èdè ná à. Ó tún ṣ'àlàyé bí iná ṣe jé ìpèníjà ń lá l'ákòókò tó ńko àwọn ìwé àkọólè rè. Nínú u ìfòròwánilénuwò pèlú Ìwé Ìròyìn Oòrùn (The Sun), Cole rántí pé òun béèrè ìwé kíkọ l'ákòkóò tí òun wà ní ilé ìwè alákòóbèrè láti ta yo láàárín in àwọn ojúgbé e rè. Ó tún sọ àsọtélè bí i òdó kékeré mi ṣe di ìwé ìtàn àtèjáde àkókó rẹ. Ó ṣe àtèjáde eré àkókó ọ rè, "Bóyá ní òla" (2014), ìtàn tí ó dá l'órí i ipò tí àwọn ènìyàn Niger Delta wà. Ìwé ná à ní atokọ fún ìgbà pípé l'énu gbígba ìwé àṣẹ l'órílè èdè Nàìjíríà l'ódún un 2014. L'éhìn-ò-r'ẹhìn, ó padà gba àmì èrí Àpéjo Àwon Onkòtàn (Association of Authors, ANA) ti Nàìjíríà. Ní Oṣù Kẹwàá (Oṣù Òwàrà), ọdún 2018, íwé e Cole mìíràn, Embers, f'arahàn gégè bíi èyí tó dára jùlọ nínú u àwọn òkàndínláàdórùn- ún(89) tí a şe àfihàn won fún pípéye, tó sì jo'jú fún ìwé lílò ní 2018. Ìwé náà dá l'órí i ipa tí ìwà ipá àti ìkolù ti èsìn ń kó l'órí i ìbágbépò àwọn ènìyàn ní Àríwá Nàìjíríà.

  • Odò kékeré mi (2010)
  • Ghost (2014)
  • Bambo Bambo (2014)
  • Bóyá Òla (2014)
  • Agbègbè Ogun (2017)
  • Embers

Yàyò sí àwọn àmì èyẹ tí ó wà ní ìsàlè, Cole ti ní atokọ fun Wolé Şóyínká Prize fún Lítíréşo ní Áfíríkà àti ìdíje ìfigagbága iṣé kíkọ BBC World.

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]