Titilope Sonuga

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Titilope Sonuga
Ọjọ́ìbíIlu Èkó
Ọmọ orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Iṣẹ́akéwì . enginíà, àti òṣèré

Titilope Sonuga, ẹni tí àwọn èèyàn mọ sì Titi Sonuga, je akéwì, enginíà, àti òṣèré ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.[1] Wọ́n bíi sì ìlú Èkó, ó sì lọ sí orílẹ̀ èdè Canada nígbà tí ó pè ọmọ ọdún mẹ́tàlá.[2] Ó siṣẹ́ fún ọdún márùn-ún gẹ́gẹ́ bíi enginíà. Ní ọdún 2011, ó gbà àmì ẹ̀yẹ onkọ̀we tuntun láti ọ̀dọ̀ Canadian Authors Association. Ní ọdún 2012, ó gbé ìgbà orókè níbi ìdíje Maya Angelou Poetry Contest.[3] Ní oṣù karùn-ún ọdún 2015, ó di akéwì àkọ́kọ́ tí ó má farahàn níbi ayẹyẹ tí wọn fi gbé Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà sórí òye. Sonuga tí kéwì níbi ayẹyẹ Lagos International Poetry Festival.[4][5] Yàtọ̀ sí ewì, Sonuga tí kópa nínú eré ṣíṣe. Ó kọ ipa Eki nínú eré Gidi Up pẹ̀lú àwọn òṣèré bíi OC Ukeje, Deyemi Okanlawon, Somkele Iyamah àti Ikechukwu Onunaku.[6] Ó jẹ́ àmbásẹ́dọ̀ fún She Will Connect Program ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ó kọ orin ' 'Ada The Country' '. Ní ọdún 2015, ó ṣe ìkéde ìgbéyàwó rẹ pẹ̀lú ayàwòrán tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Ṣeun Williams.[7][8]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "Poet Titilope Sonuga talks Leaving a Career in Engineering to Follow Her Dreams | Watch Episode 2 of 'Culture Diaries'", BellaNaija.com, 4 March 2016. Retrieved 7 October 2016.
  2. "Titilope Sonuga: Beautiful, Confident and Poetic", Wordup 411, 9 December 2013.
  3. "Clear message, language impresses poetry judges", Edmonton Journal, 24 October 2012; via PressReader.
  4. "Titi Sonuga". Lagospoetryfestival.com. Archived from the original on 23 September 2016. Retrieved 22 September 2016. 
  5. "About: Titilope Sonuga". Poejazzi.com. Retrieved 22 September 2016. 
  6. Gidi cast on The Juice, Ndanitv, Retrieved 6 October 2016.
  7. "Titilope Sonuga is engaged!". Pulse. 1 July 2015. Retrieved 22 September 2016. 
  8. editor (2020-02-02). "TITILOPE SONUGA: EMBRACING MOTHERHOOD, ELECTRIFYING THE STAGE". THISDAYLIVE (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2020-05-29.