Arinola Olasumbo Sanya

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Arinola OlaSumbo Sunya
Fọ́tò Ọ̀jọ̀gbọ́n Arinola Olasunmbo Sanya tí wọ́n yà ní ọ́fícì rẹ̀ ní Yunifásitì ìlú Ibadan ní ọdun 2013
Ọjọ́ìbí1953
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Iṣẹ́Physiotherapist

Arinola Olasumbo Sanya[1] (tí a bí ní ọdun 1953) jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n ní Yunifásítì ìlú Ìbàdàn àti Kọmíṣọ́nà fún ètò-ìlera ara ti Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Arinola di òjògbón ní ọdun 2000, èyí tí ó sọ di obìnrin àkọ́kọ́ láti di ọ̀jọ̀gbón nínú bí a ṣe ń dá isẹ́ ara bọ̀ sípò (physiotherapy) ní orílẹ̀ Afrika, àti obìnrin àkọ́kọ́ láti di ọ̀jọ̀gbọ́n nínú ìmò Physiotherapy ní Nàìjíríà. Ó wà lára àwọn Ẹni iyì ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́.[2]

Arinola ni igbá kejì adarí Yunifásítì ìlú Ìbàdàn.[3] Arinola bẹ̀rẹ̀ ẹ̀kọ́ ní Salvation Army Primary School ní Surulere ti Ìpínlẹ̀ Èkó. Ó tẹ̀síwájú ní Queens College, Yaba, Ìpínlè Èkó níbi tí wọ́n ti fi joyè Head Girl. Ó kẹ́kọ̀ọ́ nípa ìmò Physiotherapy ní Yunifásítì ìlú Ìbàdàn.

Ìsìn ìjọba[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Arinola di Kọmíṣọ́nà fún ètò-ìlera ara ti Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọdun 2005.[4]

Ìdílé[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọkọ Ọ̀jọ̀gbọ́n Sanya ní Dr. Yemi Sanya, onímọ̀ ọ̀gùn òyìnbó àti oníṣòwò ní ìpínlẹ̀ Èkó, Nàìjíríà. Wọ́n ní ọmọ mẹrin.[5]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "CITATION OF PROFESSOR ARINOLA OLASUMBO SANYA | UNIVERSITY OF IBADAN". ui.edu.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2017-12-22. 
  2. "UI appoints new DVC, registrar — the Punch - Nigeria's Most Widely Read Newspaper". Archived from the original on 2012-04-28. Retrieved 2012-05-12.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. "CITATION OF PROFESSOR ARINOLA OLASUMBO SANYA | UNIVERSITY OF IBADAN". www.ui.edu.ng. Archived from the original on 2021-05-20. Retrieved 2021-05-20. 
  4. "Arinola Olasumbo Sanya". www.wikidata.org (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2021-05-20. 
  5. "Nigeria Physiotherapy Network - Arinola O. Sanya". www.nigeriaphysio.net. Retrieved 2022-08-10.