Jump to content

Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Oyo State)
Oyo
Skyline of Ibadan, the largest city and seat of the state
Skyline of Ibadan, the largest city and seat of the state
Flag of Oyo State
Flag
Seal of Ọyọ State
Seal
Nickname(s): 
Location of Oyo State in Nigeria
Location of Oyo State in Nigeria
Coordinates: 8°00′N 4°00′E / 8.000°N 4.000°E / 8.000; 4.000Coordinates: 8°00′N 4°00′E / 8.000°N 4.000°E / 8.000; 4.000[1]
Country Nigeria
Date created3 February 1976
CapitalIbadan
Government
  BodyGovernment of Oyo State
  Governor[2]Seyi Makinde (PDP)
  Deputy GovernorBayo Lawal (PDP)
  LegislatureOyo State House of Assembly
  SenatorsC: Yunus Akintunde (APC)
N: Abdulfatai Buhari (APC)
S: Sharafadeen Alli (APC)
  RepresentativesList
Area
  Total28,454 km2 (10,986 sq mi)
Population
 (2006)[3]
  Total5,580,894[4]
  Estimate 
(2022)
7,976,100[5]
GDP (PPP)
  Year2021
  Total$23.8 billion[6]
  Per capita$2,560[6]
Time zoneUTC+01 (WAT)
postal code
200001
ISO 3166 codeNG-OY
HDI (2022)0.603[7]
medium · 15th of 37
Websiteoyostate.gov.ng

Ọ̀yọ́ jẹ́ ìpínlẹ̀ kan ní gúúsù ìwọ̀ oùrùn Nàìjíríà . Olú ìlú rẹ̀ ni Ìbàdàn, ìlú kẹta tí àwọn èèyàn pọ̀sí jùlọ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti ìlú kejì tí àwọ́n èèyán pọ̀sí julọ ni Afirika . [8] Ipínlẹ̀ Ọ̀yọ́ wà ní paàlà ní àríwá pẹ̀lú ìpínlẹ̀ Kwara pẹ̀lú kìlómítà ọ̀ọ́dúnrún lé lógójì ódín mẹ́ta, sí gúúsù ìlà-oòrùn nípasẹ̀ Ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun pẹ̀lú kìlómítà mẹ́tadínláàádọ̀wá, apá kan kọjá Odò Ọ̀ṣun, àti sí gúúsù pẹ̀lú ÌÌpínlẹ̀ Ôgun, àti sí ìwọ̀-õrùn pẹ̀lú ilẹ̀ olómìnira Benin pẹ̀lú kìlómítà méjìdínlọ́gọ́rùn-ún. Pẹ̀lú iye àwọn olùgbé tó tó mílíọ̀nù lọ́nà méje ó lé ní ọdún 2022, Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ jẹ́ Ìpínlẹ̀ kẹfa tí àwọn ènìyàn pọ̀ sí julọ ní orílẹ̀- èdè Nàìjíríà . [9]

Àwọn ọmọ Yorùbá ló pọ̀ jù nínú àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ Oyo. [10] Wọ́n pè é ní "Ìpínlẹ̀ Aṣíwájú", Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ òde òní sì wà ní agbègbè tí Ilẹ̀ Ọ̀yọ́ ń ṣàkóso tẹ́lẹ̀. Ilẹ̀ Ọ̀yọ́ jẹ́ alágbára. [11] [12] Ilẹ̀ ọba Yorùbá tí ó ń ṣàkóso ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìlú pàtàkì ní ilẹ̀ Yorùbá láti ọdún c.1300 sí 1896. [13] [14] A kọ́ọ ní àárín ọdún 1830, Ọ̀yọ́ ìgbàlódé tí a mọ̀ sí ( Ọ̀yọ́ Àtìbà ) ni a kà sí àṣẹ́kù ní àkókò ìjọba Ọ̀yọ́ láti ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ kúrò ní olú ìlú àtijọ́ ní àríwá, "Oyo Àtijọ́" tí a mọ̀ sí (Ọ̀yọ́-Ilé). Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìjọba Ọ̀yọ́ ti ìgbà àtijọ́ ṣubú ní ọdún 1835, Aláàfin (onílé àti olùtọ́jú ààfin) ń tẹ̀síwájú láti máa jẹ́ ipó ẹ̀yẹ ní ìlú Ọ̀yọ́ tuntun èyí tó wà ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ òde oní. [15]

Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ̀ ni ìpínlẹ̀ tó tóbi jùlọ ní Gúúsù Nàìjíríà tí a bá ń sọ nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀, ó sì jẹ́ ìpínlẹ̀ kejì ti àwọn ènìyàn pọ̀sí jùlọ ní Gúúsù Nàìjíríà lẹ́yìn ìpínlẹ̀ Èkó. Gẹ́gẹ́ bí ìkànìyàn tó wáyé ní ọdún 2006, ìpínlẹ̀ náà wà ní ipò kẹrin ní Nàìjíríà pẹ̀lú iye ènìyàn tó lé ní mílíọ̀nù márùn-ún àtààbọ̀ ó lé díẹ̀ (5,580,894). Ìṣirò tuntun tí wọ́n ṣe ní ọdún 2022 sọ pé iye ènìyàn ìpínlẹ̀ náà yóò tó mílíọ̀nù méjọ ó dín diẹ̀ (7,976,100), èyí tó mú kí ó jẹ́ ibi kẹfà tí àwọn ènìyàn pọ̀ sí jùlọ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà . [9] A mọ̀ ọ́n sí ibi tí Yunifásítì àkọ́kọ́ wà ní Nàìjíríà, [16] Yunifásítì ilẹ̀ Ibàdàn, [17] tí wọ́n dá sílẹ̀ ní ọdún 1948, wọ́n gbà pé ìpínlẹ̀ náà ni ìpínlẹ̀ àkọ́kọ́ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà pẹ̀lú ibùdó ilé iṣẹ́ móhùnmáwòrán àkọ́kọ́, ọ̀nà àkọ́kọ́ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, pápá ìṣeré àkọ́kọ́ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ọ̀nà ọkọ̀ ojú irin àkọ́kọ́ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ilé ìwòsàn olùkọ́ àkọ́kọ́ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àti àwọn mìíràn.

Ibadan ni Olú ìlú òun sì ni ìlú kẹta tí àwọn ènìyàn pọ̀ sí jùlọ ní Nàìjíríà gẹ́gẹ́ bí ètò ìkànìyàn tó wáyé ní ọdún 2006. Ìpínlẹ̀ náà ní iye àwọn ìlú kéréje àti ìlú ńlá tí a mẹ́nu bà jùlọ nínú àwọn àádọ́ta ìlú tí àwọn ènìyàn pọ̀ sí jùlọ ní Nàìjíríà pẹ̀lú Ìbàdàn, Ògbómọ̀ṣọ́, Ọ̀yọ́, Ṣakí àti Ìṣẹ́yìn tí gbogbo wọn wà nínú àkójọ àwọn ìlú náà. Ọrọ̀ ajé ìpínlẹ̀ náà ṣì jẹ́ ti àgbẹ̀, pẹ̀lú ìlú ìwọ̀ oòrùn Ṣakí tí a ń pè ní agbọ̀n oúnjẹ ìpínlẹ̀ náà. Ẹ̀gẹ́, kòkó, àti tábà jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ohun ọ̀gbìn pàtàkì jùlọ nínú ọrọ̀ ajé Ìpínlẹ̀ Oyo. [18] [19]

Agbègbè àti Àyíká

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Ijio Hill, Iwajowa LGA, Ipinle Oyo, Nàìjíríà

Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ gbòòrò tó nǹkan bí kìlómítà ẹgbẹ̀rún lọ́nà méjìdínlọ́gbàn ó lé tí ó jẹ́ onígun mẹ́rin [28,454], ó sì wà ní ipò kẹrìnlá nípa ìwọ̀n ilẹ̀. [20] Àwọn àpáta líle àtijọ́ àti àwọn òkè kéékèèké tó rí bíi igbá ló wà níbẹ̀, tí wọ́n ń ga sókè láti nǹkan bí ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta mítà ní apá gúúsù, tí wọ́n sì ga tó nǹkan bí ẹgbẹ̀fà mítà lókè ìwọ̀n òkun ní apá àríwá. [21] Àwọn odò pàtàkì bíi Ògùn, Ọbà, Ọ̀yán, Ọ̀tìn, Òfìkì, Ṣáṣá, Ọ̀nì, Ẹ̀rinlé àti Ọ̀ṣun ló bẹ̀rẹ̀ láti orí òkè gíga yìí. Àwọn apá gúúsù àti gúúsù ìlà oòrùn ìpínlẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀tẹ́lẹ̀ tó tẹ́ rẹrẹ. [20]

Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní òùnkà a[wọn oun adayeba bíi ibi tí a ń kó àwọn ẹranko sí ní Ọ̀yọ́ àtijọ́, ọgbà-ìtura ti Agodi ati awọn ibi ìgbafẹ́. Ni àwọn agbègbè yìí ní ìgbà àtijọ́ ni ibugbe àwọn ajágbó ti ilẹ̀ Afirika ti o wa ninu ewu, ; sibẹsibẹ, a ro pe àwọn ajágbó yii ni wọ́n ti patán ní àwọn agbègbè yìí. [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (December 2022)">Ti o nilo itọkasi</span> ]

Ojù ọjọ́ pínsí oríṣìí, pàápàá jùlọ ígbà tí òjò tó máa n mú ọ̀gìnìntìn àti ìgbà ẹ̀ẹ̀run. ìgbà ọ̀dá máa ń wà láti oṣù kọkànlá sí oṣù oṣù kẹta, ìgbà òjò sì máa ń bẹ̀rẹ̀ láti oṣù kẹrin títí di oṣù kẹwàá. Ìwọ̀n ojú ọjọ́ màa ń wà láàrín ìwọ̀n márùndínlọ́gbọ̀n (25 °C (77.0 °F) sí ìwọ̀n márùndínlógójì (35 °C (95.0 °F), lọ́pọ̀ ìgbà jákèjádò ọdún. [22]

Wọ́n dá a sílẹ̀ ní ọdún 1976 [23] láti Ìpínlẹ̀ Ìwọ̀ Oòrùn, Ìpínlẹ̀ Ọsun wà nínú rẹ̀, èyí tí wọ́n padà pín sí méjì ní ọdún 1991. Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ̀ jẹ́ ìpínlẹ̀ tó wà ní ìṣọ̀kan tó sì jẹ́ wípé àwọn ẹ̀yà Yorùbá ni wọ́n pọ̀jù níbẹ̀, tí wọ́n sì yan iṣẹ́ àgbẹ̀ láàyò, ṣùgbọ́n tí wọ́n ní ìfẹ́ sí gbígbé ní àwọn ìlú ńlá tí àwọn èrò pọ̀ sí. [24] Àwọn ọmọ ìbílẹ̀ náà ní pàtàkì jẹ́ àwọn ọmọ Ọ̀yọ́, àwọn Òkè-Ògùn, àwọn Ìbàdàn [25] àti àwọn Ìbàràpá, tí gbogbo wọn jẹ́ ẹ̀yà Yorùbá. Ìbàdàn ni ibùdó ìṣàkóso Ìpínlẹ̀ Ìwọ̀ Oòrùn àtijọ́ láti ìgbà ìjọba àwọn ará Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì .

Yàtọ̀ sí ìlú ibadan, àwọn ìlú ńlá àti ìlú kéréjé mìíràn tó ṣeyebíye ní ìpínlẹ̀ Ọyọ ni ìlú Ọ̀yọ́, Ògbómọ̀sọ́, Ìsẹ́yìn-Òkèògùn, Ìpàpó-Òkèògùn, Kíṣì-Òkèògùn, Òkehò-Òkèògùn, Saki-Òkèògùn, Igbeti-Òkèògùn, Igboho-Òkèògùno, Erúwà-Ìbàràpá, Ìròkò, Lànlátẹ̀, Ọ̀jẹ̀Owódé-Òkèògùn, Ṣẹ̀pẹ̀tẹ̀rí-Òkèògùn, Ìlọrǎ-Ọ̀yọ́, Jóbèlè-Ọ̀yọ̌ , Aáwẹ́-Ọ̀yọ́[26]

Ní ọdún 2024, àwọn ọmọ ilẹ̀ Yorùbá tí wọ́n yapa kúrò ní ìlú Ìbàdàn gbìyànjú láti dojú ìjọba ìpínlẹ̀ náà bolẹ̀ ṣùgbọ́n wọn kò ṣe àṣeyọrí.

Àwọn àkọsílẹ̀ àti àwọn oun tó lààmì-laaka

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Àwọn ilé gogoro Bower, Ibadan

Ilé ẹ̀kọ́ gíga àkọ́kọ́ tí ó ń fúnni ní ìwé ẹ̀rí ní Nàìjíríà ni Yunifásítì Ibadan (tí a dá sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí kọ́lẹ́ẹ̀jì ti Yunifásítì ti ìlú London nígbà tí wọ́n dá a sílẹ̀ ní ọdún 1948, tí wọ́n sì yí i padà sí yunifásítì aládàáni ní ọdún 1962). [27] Àwọn yunifásítì mìíràn ní ìpínlẹ̀ Ọyọ́ ni: Lead City University, Ìbàdàn, ] Ajayi Crowther University, Ọ̀yọ́, ] Koladaisi University, Dominican University, Ibadan, àti Ladoke Akintola University of Technology, Ogbomoso . Ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìṣé ti ìlú Ìbàdàn, Ilé ẹ̀kọ́ tó ń rísí iṣẹ́ àgbẹ̀ àti ìmọ̀ ẹ̀rọ ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, Igbó Ọrà, Ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìṣe ti Adéṣeun Ògúndoyin tì ò wà ní Èrúwà ní Ìpínlẹ̀ Oyo. [28]

Àwọn ilé ìwé girama okòólélọ́ọ̀ọ́dúnrún ó lé mẹ́rin (324) àti àwọn ilé ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ìjọba ẹgbẹ̀jọ ó dín mẹ́rìnlélógójì (1,576) ló wà ní ìpínlẹ̀ náà. Àwọn ilé ẹ̀kọ́ pàtàkì mìíràn ní ìlú náà ni Ilé Ìwòsàn Yunifásítì, Ibadan ; ilé ìwòsàn olùkọ́ni àkọ́kọ́ ní Nàìjíríà àti International Institute of Tropical Agriculture (IITA). [29] Ilé Kòkó tí ó wà ní Ibadan ni ilé gíga àkọ́kọ́ tí a kọ́ ní Áfíríkà. [30]

Ìpínlẹ̀ náà ni NTA Ibadan, ilé iṣẹ́ móùnmáwòrán àkọ́kọ́ nílẹ̀ Áfíríkà wâ, àti Pápá ìṣeré Obafemi Awolowo (tí a mọ̀ sí Liberty tẹ́lẹ̀), pápá ìṣeré kan tí ó lè gba ènìyàn lọ́nà ẹgbẹ̀rún márùndínlógójì lẹ́ẹ̀kanṣoṣo. [31]

Àwọn ibi ìtura pàtàkì mìíràn tí ó wà ní ìpínlẹ̀ náà ni: Ọgbà Ewéko Agodi, Adágún Ado-Awaye tí a ti dá dúró, Gbọ̀ngàn Màpó, Ọgbà Ẹranko Yunifásítì ti Ibadan, Ido Ère ọmọ ológun to wà ní Ìdó, Ibi Ìtura Trans-Wonderland, Ibi tí a ǹ kò àwọn ẹranko sí ní Ọ̀yọ́ Àtijọ́ tí ó wà ní ibi ìtàn ti olú-ìlú ìgbàanì ti Ilẹ̀ Ọba Ọ̀yọ̌ àtijọ́, Ìyámọ̀pọ́ àti Òkè Agbele ní Ìgbẹ́tì, Ilé Gogoro Bower àti Ilé-iṣẹ́ Àṣà tó wà ní Mọ́kọ́lá. Ìpínlẹ̀ náà ni ó ní ilé iṣẹ́ rédíò àkọ́kọ́, àti ibùdó tẹlifíṣọ̀n àdáni àkọ́kọ́, Galaxy Television ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. [32]

Òkè Oloke Meji

Ìjọba àti ìṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Lábẹ́ òfin Nàìjíríà ti ọdún 1999 ìjọba ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, àti àwọn ìpínlẹ̀ márùndílógójì mìíràn ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ni a pín sí àwọn ẹka mẹ́ta láti wà ní ìbámu pẹ̀lu ìjọba olómìnira Nàìjíríà tí ó tún jẹ́ ipele mẹ́ta: ẹka aláṣẹ, ẹka aṣòfin àti ètò ìdájọ́ . [33] Olórí fún Ẹka aláṣẹ ti ìjọba ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ni gomina alaṣẹ ti a dìbòyàn tó jẹ́ alága Ìgbìmọ̀ Aláṣẹ ti Ìpínlẹ̀ tí ó jẹ́ àwọn tí a yàn sípò. Gómìnà tó wà ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ lọ́wọ́lọ́wọ́ ni onímọ̀ ẹ̀rọ Sèyí Mákindé pẹ̀lú Báyọ̀ Lawal tí ń ṣe igbákejì gómìnà. [34] Ẹka ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin ní adarí tí a dìbò yàn sí ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin. Ẹni tí ójẹ́ Agbọ̀rọ̀sọ ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin lọ́wọ́lọ́wọ́ ni Hon. Ọ̀kánlàwọ́n uriel A . [35] Níparí, adájọ́ àgbà ní ilé-ẹjọ́ giga ti ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ni ó jẹ́ adarí fún ẹka ètò ìdájọ́. Adájọ́ àgbà ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ lọ́wọ́lọ́wọ́ báyǐ ni Muktar Abímbọ́lá. [36]

Lọ́wọ́lọ́wọ́, Ìpínlẹ̀ Oyo ní ilé-ẹ̀kọ́ alàkọ́bẹ̀rẹ̀ ti ìjọba tí o jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé mẹ́rin (2,004), ilé-ẹ̀kọ́ ọmọ-ọwọ́/alàkọ́bẹ̀rẹ̀ aládàńí tí ó jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún lé mọ́kànléláàádọ́rin, ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti ìjọba ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún lé mọ́kàndínláàádọ́rin (969) pẹ̀lú ilé-ẹ̀kọ́ ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì méje àti ilé-ẹ̀kọ́ gíga aládàńí tí ó jẹ́ mẹ́tàdínlọ́gọ́ta (57). Ìpínlẹ̀ náà tún ní àwọn kọ́lẹ́ẹ̀jì ìmọ̀-ẹ̀rọ ìjọba márùn-ún èyí tí ó wà ní Ọ̀yọ̀, Ògbómọ̀ṣọ́, Ìbàdàn, [37] Ṣakí-Òkèògùn [38] àti Ìṣẹ́yìn-Òkèògùn pẹ̀lú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí ó tó ẹgbàálélẹ́gbẹ̀rin le oókandínlọ́gbọ̀n (2,829) tí wọ́n forúkọ sílẹ̀ ní sáà ẹ̀kọ́ 2000 sí 2001. Ibùdó ìtọ́sọ́nà fún àwọn ọ̀dọ́ ti orílẹ̀-èdè (NYSC) wà ní ìlú Ìṣẹ́yìn. [39]

Ibùgbé àwọn òǹkọ̀wé Ẹbẹdí tó wà ní òkè-ìhà bárékè àwọn ológun Ìṣẹ́yìn jẹ ibùgbé àgbáyé tí ó ti mú àwọn òǹkọ̀wé, àwọn oníṣẹ́ ìròyìn àti àwọn òǹkàwé ńlá wá láti gbogbo àgbáyé, títí kan olùgbàje Nobel àkọ́kọ́ nílẹ̀ Áfíríkà, Ọ̀jọ̀gbọ́n Wọlé Ṣóyínká, Jùmọ̀kẹ́ Verissiomo, Fúnmi Àlùkò, Richard Ali, Paul Liam àti àwọn mìíràn.[40]

Àwọn ilé-ẹ̀kọ́ girama tó gbajúmọ̀ nínú ìtàn ni Ilé-ẹ̀kọ́ St Anne Ìbàdàn (1869), Wesley College, Ìbàdàn (1905), Ilé-ẹ̀kọ́ Grammar Ìbàdàn (1913), Ilé-ẹ̀kọ́ Ìjọba, Ìbàdàn (1927), Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Tèrésà mimọ́ Ìbàdàn (1932), Ilé-ẹ̀kọ́ gíga àwọn ọmọkùnrin Ìbàdàn (1938), Olivet Heights Ọ̀yọ́ (1945), Ilé-ẹ̀kọ́ Queen, Ìbàdàn (1952), Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Lòyólà, Ìbàdàn(1954), Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Bernadine mímọ́ ti ìlú Ọ̀yọ́ (1957), Ilé-ẹ̀kọ́ Girama Lágelú Ìbàdàn (1958), Ilé-ẹ̀kọ́ Girama Àgbègbè Ìṣẹ́yín (1964), Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Methodist, Ìbàdàn (1961) Ilé-ẹ̀kọ́ Girama Patrick Mímọ́ Ìbàdàn (1962) àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ mìíràn. Ó tún jẹ́ ilé ìtọ́jú ìmọ̀ tó gbajúmọ̀ ní Áfíríkà, Yunifásítì Ibadan tó gbajúmọ̀ (Wọ́n dá Yunifásítì náà sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ilé-ẹ̀kọ́ gíga olòmìnira ti Yunifásítì ti ìlú London, nígbà náà ni wọ́n ń pè é ní Yunifásítì kọ́lẹ̀jì, Ìbàdàn ).

Àwọn kọ́lẹ́ẹ̀jì ìmọ̀-ẹ̀rọ tuntun méjì tí wọ́n wà ní Ìṣẹ́yìn, agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ ìlú Ìṣẹ́yìn àti Ikija ní agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ Olúyọ̀lé ni wọ́n dá sílẹ̀ ní sáà ẹ̀kọ́ ọdún 2001 sí 2002. Kọ́lẹ́ẹ̀jì ẹ̀kọ́ ti Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, èyí tó wà ní ìlú Ọ̀yọ́. Ilé-ẹ̀kọ́ Gbogbonìṣe, Ibadan pẹ̀lú àwọn ẹka rẹ̀ méjì tí ó wà ní Erúwà àti Sakí-Òkèògùn, (tí a mọ̀ sí ilé ẹ̀kọ́ gbogbonìṣé Òkè-Ògùn báyìí) àti Yunifásitì ìmọ̀-ẹ̀rọ ti Ìpínlẹ̀ nâ, Yunifàsitì ìmọ̀-ẹ̀rọ Ladoke Akintola (LAUTECH), Ògbómọ̀ṣọ́ [41] tí ìjọba Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ àti Ọ̀sun jọ ní papọ̀. Ilé-Èkọ́ gbogbonìṣe aládàáni (SAF Polytechnic, Iseyin) tó wà ní ìlú Ìṣẹ́yìn. Ibi tí a ti ń kọ́ni nípa iṣẹ́ ọwọ kan wà ní ìjọba ìbílẹ̀ ìwọ̀-oòrùn Sakí tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́: Ilé-Èkọ́ gbogbonìṣe àwọn ọba (Kings Poly), Ṣakí-Òkèògùn [42] [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (December 2022)">ìtọ́kasí tí a nílò</span> ]

Ní àfikún, Ilé-ẹ̀kọ́ ìjọba àpapọ̀ fún ìlera àwọn ẹranko àti ìmọ̀ ẹ̀rọ to wà ní Ìbàdàn ; Ilé ẹ̀kọ́ ìjọba àpapọ̀ fún àwọn olùkọ́ni (èyí tí ó jẹ́ àrà ọ̀tọ̀) tó wà ní ìlú Ọ̀yọ́, Ilé-ẹ̀kọ́ ìjọba àpapọ̀ tí wọn ti ń kọ́ nípa ìwọ̀n ilẹ̀ tí ó wà ní ìlú Ọ̀yọ́Federal School of Surveying, Oyo; Ìtẹ̀dó ibi ìwadìí kòkó ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà (CRIN), Ibùdó ẹ̀kọ́ àti ìwádìí nípa iṣẹ́ àgbẹ̀ (IAR&T), Ìgbìmọ̀ tó ń rísí ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ sáyẹ́ǹsì ní orílẹ̀ èsè Nàìjíríà (NISLT), Ilé ẹ̀kọ́ ìjọba àpapọ lórí ìmọ̀ inú igbó àti aginjù tí ó wà ní ìlú Ìbàdàn (FEDCOFOR), ẹka kan nínú Ẹka tó ń rísí ìwádìí ọ̀rọ̀ igbó àti aginjù tí ó wà ní ìlú orílẹ̀ èdè Nàìjíríà (FRIN) àti Ẹka tó ń rísí ìwádìí lórí ọ̀rọ̀ okòwò àti ọ̀rọ̀ àwùjọ ní Orílẹ̀ èdè Nàìjíríà (NISER), gbogbo wọn ni wọ́n wà ní ìlú Ìbàdàn. [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (December 2022)">Ti o nilo itọkasi</span> ]

Bákanńà, àwọn ilé-ìwe àwọn adaranjẹ̀ marùndinlògún ló wà ní Ìpínlẹ̀ náà. Àwon ni Gaa Jooro ati Gaa Baálé, méjèèjì wà ní Kìṣí (ìjọba ìbílẹ̀ Ìrẹ́pọ̀); Ìjọba Baochilu; Àrin-Oyè, Abíógun, Okaka àti Baba-Ode (ìjọba ìbílẹ̀ Itesiwaju); Ìgànná (Ìjọba ìbílẹ̀ Ìwájọ̀wà); Ìgàngàn àti Ayétẹ̀ (Ìjọba ìbílẹ̀ Àríwá Ìbàràpá); Gaa Kondo ati Igbó-Ọrà, (Ìjọba ìbílẹ̀ ààrin gbùngbùn Ìbàràpá) ati Ṣẹ̀pẹ̀tẹ̀rí (ìjọba ìbílẹ̀ ìlà oòrùn Ṣakí). Àwọn ilé-iṣẹ́ ètò-ẹ̀kọ́ onítẹ̀síwájú igba ó lé mẹ́tàlá wa ló wà kaàkiri gbogbo Ìpínlẹ̀ náà. [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (June 2021)">ti nilo itọkasi</span> ]

Awọn ile-iwe alakọbẹrẹ márùndínlógún àti àwọn ẹ̀yà pàtàkì mẹ́jọ ní àwọn ilé-ìwé girama ló wà fún àwọn aláàbọ̀ ara. Àwọn olùkọ́ tí ó tó ẹgbẹ̀rún lọ́nà mọ́kànla ó lé lẹ́ẹ̀dẹ́gbẹ̀rin le méjìlélọ́gbàn (11,732) wà ní àwọn ilé-ìwé girama ti ìjọba ati awọn oṣiṣẹ ẹgbàá lé lẹ́gbẹ̀rin din mọ́kànlá (2,789) tí kìí ṣe olùkọ́ni. [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (May 2020)">Ti o nilo itọkasi</span> ]

Ilé-iṣẹ́ fún Ẹ̀kọ́ àwọn Àgbàlagbà àti àwọn tí kìí lo ìwé (AANFE) ń tọ́jú àwọn àgbàlagbà tí wọn kò ní àǹfààní láti lọ sí ilé ìkẹ́kọ̀ọ́. Ilé-iṣẹ́ náà ní àwọn yàrá ìkẹ́kọ̀ọ́ tí ó tó irinwó lé márùnléláàádọ́ta (455) tí ó wà ní àwọn agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́tàlélọ́gbàn ní ìpínlẹ̀ náà, nígbà tí àwọn àgbàlagbà tí kò mọ̀ọ́kọ-mọ̀ọ́kà tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún lọ́nà igba (200,000) àti àwọn àgbàlagbà tí yálà wọ́n lè kọ tàbí kà tí ó tó ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rin (80,000) ni wọ́n ti ṣe ìdánilẹẹ́kọọ̀ọ́ fún láìpẹ́ yìí. [43]

Àkójọ àwọn yunifásítì

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn yunifásítì wọ̀nyí ni wọ́n wà ní ìpínlẹ̀ Oyo; [44]

Àkójọ àwọn ilé-ẹ̀kọ Gbogbonìṣe

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àkójọ àwọn ilé-ẹ̀kọ́ gíga pàtàkì

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

 

Àkójọ àwọn ilé-ẹ̀kọ́ pàtàkì

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àkójọ àwọn ilé-ẹ̀kọ Gbogbonìṣe aládàání tí a forúkọ wọn sílẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

 

Àwọn Ọ̀nà Àpapọ̀ Ìjọba

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn wọ̀nyí ní:

  • A1 gẹ́gẹ́ bí apá kan ti African Unity Road TAH2: Trans-African Highway 2 sí àríwá sí Ibadan àti àríwá sí àríwá nípasẹ̀ Oyo àti Ogbomosho sí Kwara State ní Oterere,
  • A5 ila-oorun lati Ipinle Ogun ni Omin Adio si Ibadan,
  • A7 ariwa iwọ-oorun lati Ipinle Kwara ni Olorulekan nipasẹ Igbeti ati Kishi si Ipinle Kwara lẹẹkansi ni Batabi,
  • Ọ̀nà E1 Lagos-Ibadan Expressway sí àríwá sí Ibadan,
  • A122 ní ìlà-oòrùn láti Ìbàdàn sí Ìpínlẹ̀ Osun ní Erinmi.

Àwọn ọ̀nà pàtàkì mìíràn pẹ̀lú:

  • the Shaki-Gwanara Rd northwest to Kwara State [47] at Owode,
  • the Shaki-Alabafi Rd north to Kwara State at Ifelodun,
  • the Saki-Igboho/Ilorin/Saki-Ogbooro Rd east from Shaki to Igboho ,
  • the Oko-Elerin Rd southeast from Ogbomosho via Ajomo to Osun State at Ilie,
  • the Oko-Iresa-Aadu Rd/Olokun-Iresa-Pa Rd south from Ajomo via Oko to Osun State at Afaro as the Ejigbo-Oko Rd,
  • Ọ̀nà Awe ní gúúsù ìlà-oòrùn láti A1 ní Oyo sí Ìpínlẹ̀ Osun ní Kiyeseni gẹ́gẹ́ bí Ọ̀nà Ojongbodu-Awe-Alabo-Iwo,
  • Ọ̀nà Ìbàdàn-Ìwò ní àríwá ìlà-oòrùn sí Ìpínlẹ̀ Osun,
  • Orita-Aperin-Beere Rd southeast from Ibadan to Odi Aperin,
  • the Olorunda Rd from Odi Aperin as the Akaran Rd to Ogun State at Olugbuyi as the Ibadan-Ijebu-Igbo Rd,
  • Ijebu-Ode-Idi-Ayunre Rd ní gúúsù láti Ibadan sí Ogun State ní Mamu,
  • the Igbara-Orile-Ijeun Rd south to Ogun State at Ijade.

Àwọn ọkọ̀ ojú irin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ibadan jẹ́ ibùdó pàtàkì lórí ìrìn àjò ojú irin ìwọ̀ oòrùn láti Èkó sí Kano (1899) lórí 1067 mm (3ˈ6") Cape Gauge, pẹ̀lú 1435 tuntun mm (4ˈ8½") laini iwọn boṣewa lati Eko si Ibadan ṣii ni ọdun 2021.

Pápá ọkọ̀ òfúrufú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Papa ọkọ ofurufu Ibadan ǹ ṣiṣẹ́ lọ sí ìlú Abuja àti Èkó nípasẹ̀ Air Peace ati Overland Airways.

Àkójọ àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba lọ́wọ́lọ́wọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Kọmíṣọ́nà/Ọ̀gá Iṣẹ́-ìránṣẹ́/Ọ́fíìsì
Oluwaseyi Makinde Gómìnà
Bayo Lawal Igbákejì Gómìnà
Adebo Ogundoyin Alága Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀
Olubamiwo Adeosun Akọ̀wé fún Ìjọba Ìpínlẹ̀
Hon. Segun Ogunwuyi Olórí Òṣìṣẹ́
Akinola Ojo Kọmíṣọ́nà fún Ìnáwó
Hon Temilolu Ashamu Kọmíṣọ́nà fún Agbára àti Àwọn Ohun Alumọ́ọ́nì
Amidat O. Agboola Olórí Iṣẹ́
Olórí Obafemi Ademola Ojo Kọmíṣọ́nà fún Ìjọba Ìbílẹ̀ àti ọ̀rọ̀ oyè jíjẹ
Oyelowo Oyewo Agbẹjọ́rò Àgbà àti Kọmíṣọ́nà fún Ìdájọ́

Iṣẹ́ àgbẹ̀ ni iṣẹ́ pàtàkì tí àwọn ènìyàn ní Ìpínlẹ̀ Oyo ń ṣe. Ojú ọjọ́ ní ìpínlẹ̀ náà ló ń mú kí àwọn èèyàn máa gbin àwọn ohun ọ̀gbìn bí àgbàdo, iṣu, ẹ̀gẹ́, ọkà bàbà, ìrẹsì, ọ̀gẹ̀dẹ̀, kòkó, èso ọ̀pẹ, cashew àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ilé oko ìjọba ló wà ní Ìsẹ́yìn/Ìpàpó, Ìlọràá, Èrúwà, Ògbómọ̀ṣọ́, Ìrẹsàadú, Ìjàyè, Àkùfò àti Lálúpọn . Ọ̀pọ̀lọpọ̀ amọ̀, amọ̀-funfun àti òkúta-omi-bírín ló wà níbẹ̀. Àwọn ọgbà ẹran ọ̀sìn tó pọ̀ tún wà ní Saki, Fasola àti Ibadan, oko wàrà kan ní Mọ́nàtán ní Ibadan àti Ètò Ìdàgbàsókè Ọ̀gbìn ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, pẹ̀lú olú ilé-iṣẹ́ rẹ̀ ní Ṣakí. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ilé-iṣẹ́ àgbẹ̀ àgbáyé àti ti ìjọba àpapọ̀ ló wà ní ìpínlẹ̀ náà. [ <span title="This claim needs references to reliable sources. (December 2022)">ìtọ́kasí tí a nílò</span> ]

Àwọn Agbègbè Ìjọba Ìbílẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìpínlẹ̀ Oyo ní àwọn agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́tàlélọ́gbọ̀n. [48] Àwọn ni:  

Àwọn ènìyàn pàtàkì àti Ọ̀tọ̀ǹkùlú Ìlú tí wọ́n jẹ́ ọmọ bíbí Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọ̀rọ̀ Òṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A ń darí ìlú náà láti ọwọ́ Gómìnà tí àwọn ará ìlú dìbò yàn, tí ó ń ṣiṣẹ́ papọ̀ pẹ̀lu àwọn ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ipinlẹ naa tí gbogbo wọn sì ń darí ìjọba ìpínlẹ̀ náà. Ìlú Ìbàdàn ni olú-ìlú ìpínlẹ̀ náà. [51]

A máa ń yan gómìnà ìpínlẹ̀ kọ̀ọ̀kan nípa lílo ìlànà onìlọ̀ọ́po méjì. Láti di olùdíje ní ipele àkọ́kọ́, olùdíje gbọ́dọ̀ gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìbò tí ó to ìdá márundínlọ́gbọ̀n nínú ọgọ́rùn-ún tàbí jubẹ́ lọ tàbí ó kéré jù ìdá méjì nínú mẹ́ta ìbò àwọn Ìjọba Ìpínlẹ̀. Tí kò bá sí olùdíje tó jáwé olúborí, àtúndì ìdìbo yóò wáyé láàárín àwọn olùdíje méjì tó ní ìbò tó ga jùlọ láàárín àkójọ àwọn ìdìbò tí wọ́n dì ní gbogbo àwọn ìjọba ìbílẹ̀. [52]

Àwọn ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. The Encyclopedia of African-American Heritage by Susan Altman, Chapter O, page 183
  2. See List of governors of Oyo State for a list of prior governors
  3. Archived 2009-08-26 at the Wayback Machine. State overview
  4. "2006 PHC Priority Tables – NATIONAL POPULATION COMMISSION". population.gov.ng (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2017-10-10. Retrieved 2017-10-10. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  5. "Oyo State: Subdivision". www.citypopulation.de. Archived from the original on 2024-02-07. Retrieved 2024-02-07. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  6. 1 2 Okeowo, Gabriel; Fatoba, Iyanuoluwa, eds. (2022-10-13). "State of States 2022 Edition" (PDF). Budgit.org. BudgIT. Archived from the original (PDF) on 2023-03-31. Retrieved 2023-03-07. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  7. "Sub-national HDI - Area Database - Global Data Lab". hdi.globaldatalab.org (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 2018-09-23. Retrieved 2018-09-13. Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  8. Empty citation (help)
  9. 1 2 Empty citation (help)
  10. Empty citation (help)
  11. Empty citation (help)
  12. Empty citation (help)
  13. History of Nigeria.. New York.
  14. The History of the Yorubas: From the Earliest Times to the Beginning of the British Protectorate. https://books.google.com/books?id=7XSiGw4_qlAC.
  15. THE ỌYỌ YORUBA AND THE ATLANTIC TRADE, 1670-1830. https://www.jstor.org/stable/41856687.
  16. Empty citation (help)
  17. Empty citation (help)
  18. Empty citation (help)
  19. Empty citation (help)
  20. 1 2 Empty citation (help)
  21. Empty citation (help)
  22. Empty citation (help)
  23. Empty citation (help)
  24. Empty citation (help)
  25. Empty citation (help)
  26. Empty citation (help)
  27. Empty citation (help)
  28. The History of the Yorubas: From the Earliest Times to the Beginning of the British Protectorate. https://books.google.com/books?id=7XSiGw4_qlAC.
  29. Empty citation (help)
  30. Empty citation (help)
  31. Empty citation (help)
  32. Empty citation (help)
  33. Empty citation (help)
  34. Empty citation (help)
  35. Empty citation (help)
  36. The History of the Yorubas: From the Earliest Times to the Beginning of the British Protectorate. https://books.google.com/books?id=7XSiGw4_qlAC.
  37. Empty citation (help)
  38. Empty citation (help)
  39. History of Nigeria.. New York.
  40. Empty citation (help)
  41. Empty citation (help)
  42. Empty citation (help)
  43. Empty citation (help)
  44. Empty citation (help)
  45. Empty citation (help)
  46. Empty citation (help)
  47. Empty citation (help)
  48. Empty citation (help)
  49. Empty citation (help)
  50. Empty citation (help)
  51. Empty citation (help)
  52. Empty citation (help)

Àwọn ojú òpó ayélujára

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àdàkọ:Geographic location