Jump to content

Olóyè Teslim Folárìn

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Teslim Folarin)
Teslim Folarin
Folarin in 2014
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí30 Oṣù Kẹ̀wá 1963 (1963-10-30) (ọmọ ọdún 62)
Ibadan, Western Region (now in Oyo State), Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúAll Progressive Congress (2017–present)
(Àwọn) olólùfẹ́
Angela Folarin
(died 2022)
[1]
EducationMethodist Boys' High School, Lagos
OccupationPolitician

Teslim Kọ́láwolé Folárìn OFR (a bi ní ọgbọ̀ńjọ́ oṣù kẹwàá, ọdún 1963) jẹ́ olóṣèlú Nàìjíríà,[1] ó jẹ́ olùdíje gómìnà ti All Progressives Congress ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ fún ìbò gómìná tí ó wáyé ni ọdún 2023 tí ó sì pàdánù sí ọwọ́ gómìnà tí ó ń bẹ lórí oyè èyinì Sèyí Mákindé.[2] Ó fi ìgbàkan jẹ́ ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà níbi tí ó ti ṣojú ẹkùn ti ààrin gbùgbùn ti ìpìnlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní ọdún 2003 sí 2011; àti láti ọdún 2019 sí 2023.

Ìgbà èwe àti ilé ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Teslim Kọ́láwọlé Fọlárìn ni a bí ní ọgbọ̀ńjọ́ Oṣu Kẹwa ọdun 1963, sí inú ẹbí Alhaji ati Alhaja Hamzat Fọlàrìn. Ó ṣẹ̀wá láti ilé Baálẹ̀ ti àgbègbè Ọjà Igbó ní ìjọba ìbílẹ̀ Àríwa-ilà-oòrùn ilẹ̀ Ìbàdàn ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́. Folárìn ni ó jẹ Mọ́gàjí ti Ilé ẹbí rẹ̀ tí ó sì tún jẹ́ èèkàn olóye ní ílẹ̀ Ìbàdàn. Ó jẹ́ Lágúnà Olúbádàn ti ilẹ̀ Ìbàdàn. [3]

Fọlárìn lọ ilé ìwé alákọ̌bẹ̀rẹ̀ ní ìlú Èkó ; ètò ẹ̀kọ́ girama rẹ̀ parí ní ilé-ìwé girama àkọ́kọ́ ti Nàìjíríà, Methodist Boys' High School, ní ìlú Èkó . Fọlárìn kẹ́kọ̌ gboyè nínú ìmọ̀-ọ̀rọ̀ òṣèlú láti ilé ẹ̀kọ́ gíga Unifásitì ti ilẹ̀ Ìbàdàn [4] àti ìwé-ẹ̀kọ́ diploma láti Harvard University , ní orílẹ̀ èdè Amẹ́ríkà. Ó lo àwọn ọdún dìẹ́ ní Ìlú ọba láti ṣàjọpọ̀ ìrírí tí ó ṣe pàtàkì, pẹ̀lú àwọn ipa ìṣàkóso lẹ́ka ìṣòwò ní ìlú ọba bákańàn ṣáájú kí ó tó padà sí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ní ọdún 2002. Fọlárìn ṣe iṣẹ Àgùnbánirọ̀ èyítí ìjọba orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ṣe ní ọ̀ranyàn fún gbogbo akẹ́kọ̀ọ́ jáde ní ilé ẹ̀kọ́ gíga rẹ̀ ní ìlú Kàdúná tí ó sì darapọ̀ mọ́ òṣèlú lẹ́hǐnnà. [3]

Iṣẹ́ olóṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Fọlárìn díje ní ọdún 2003 láti ṣojú ẹkùn ààrin gbùngbùn ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ ní èyí tí ó jáwé olúborí ní ẹni ọdún oókàndínlógójì lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ kanńàn ní ọdún òṣèlú PDP tí ó sì tún wọlé elẹ́ẹ̀kejì lábẹ̀ àsìà ẹgbẹ́ kanńàn ní ọdún 2007. Folarin jẹ́ aṣòfin kan ṣoṣo ní ìpínlẹ̀ Oyo tó ti sìn fún ìgbà méjì nínú Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin àgbà ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣófin àgbà, wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bí Olórí Ilé. Folarin tún ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bíi ọ̀kan nínú ọmọ ìgbìmọ̀ tí ó ń rísí ọ̀rọ̀ okòwò àti àwọn òfin tí ó rọ̀mọ, ọ̀rọ̀ àti ìrìn àjò orí omi bí ótilẹ̀ jẹ́ wípé ohun tí ó nì ìfẹ́ sí jùlọ ni ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́, ìpèse iná mọ̀nàmọ́ná ati ohun àlùmọ́nì ti inù omi. Folarin kópa nínú ìwádìí ọ̀rọ̀ tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìwà ìbàjẹ́ tí ó wáyé níbi ìpèsè iná ìjọ̀ba lọ́dún 2008. Gẹ́gẹ́bí Olùdarí ti Ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà, ó ṣaájú ìjíròrò lórí àtúnto gbogbo àwọn ìwé-àṣẹ alákǒso àti pé ó ṣe agbátẹrù sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìwe òfin mìráǹ lábẹ́lẹ̀. [5] Lára wọn ni ìwe tí ó dá lórí ọ̀rọ́ mádàmídaà-òfò, ọ̀rọ̀ ówo ìfẹ̀hìntì fún àwọn ọmọ ológun àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ.

Folarin gba ìwe láti díje sí ipò gómìnà ti ẹgbẹ́ òṣèlú rẹ̀, People's Democratic Party (PDP) ní ọdún 2014. [6] Ó pàdánù sí ọwọ́ Abiola Ajimobi ti ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress ẹni tí ó jẹ́ gómìnà fún ìpínlẹ̀ ọ́yọ́ ní ìgbànǎ.

Fọlarin lọ sínú ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress ní Oṣù kejìlá ọdún 2017. [7]

Fọlarin ni a dìbò yàn láti lọ ṣojú ààrin gbùngbùn ti ìpílẹ̀ ọ̀yọ́ ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà lábẹ́ àsìá ẹgbe òṣèlúti All Progressives Congress (APC) ní Oṣù Kẹsàn-án ọdún 2018. [8]

Folarin gba ipò yǐ lọ̀wọ̀ aṣòfin tí ń ṣojú agbegbe ààrin gbùngbùn Ọ̀yọ́ ni ọdún 2019 ẹni tí ń ṣe, Ayaba Monsurat Sunmonu àti àwọn olùdíje mìíràn. Ó jẹ́ ààrẹ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà lórí àwọn ohun tó wà láyìíká nílé ìgbìmọ́ aṣòfin àgbà kẹsàn-án. Ó tún wà nínú àwọn ìgbìmọ̀ mìíràn bíi Ìwádìí àti Ọ̀tẹlẹẹ̀múyẹ́, àjọ tóń ṣètò ìdìbò, Ìparílé, Àtúnṣe ìwé òfin, Ètò ìnáwó, àwọn àfojúsùn Ìdàgbàsókè àwùjọ (SDG) àti ọ̀rọ̀ àwọn ọmọ ogun ti òfúrufú.

Fọlarin tún díje nínú ètò ìdìbò ti gomìnà ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ ní ọdún 2023 lórí pẹpẹ ti All Progressives Congress ṣùgbọ́n ó pàdánù sí ọwọ́ Gomìnà Seyi Makinde ti ẹgbẹ́ òṣèlú ti PDP. [9]

Ní ọdún 2011, Fọlarin, àti àwọn mẹ́ta mìíràn ni a fi ẹ̀sùn kàn fún ikúu Lateef Salako ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́.

Ìgbésí ayé ara ẹni

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Folarin fẹ́ Agbejẹ́rọ̀ Angela Folarin ẹni tí ó jáde láye ní ọdún 2022, ọba òkè fi àwọn ọmọ jíǹki wọn.

  1. 1 2 "Oyo senator, Teslim Folarin, loses wife". 2022-01-28. https://www.vanguardngr.com/2022/01/oyo-senator-teslim-folarin-loses-wife/.
  2. "Teslim Folarin emerges Oyo APC governorship candidate". 2022-05-28. https://premiumtimesng.com/regional/ssouth-west/532979-teslim-folarin-emerges-oyo-apc-governorship-candidate.html.
  3. 1 2 Empty citation (help)
  4. "Folarin to deliver 2021 UI alumni lecture, to be honoured with award of excellence". 2021-08-27. https://www.vanguardngr.com/2021/08/folarin-to-deliver-2021-ui-alumni-lecture-to-be-honoured-with-award-of-excellence/.
  5. "Who is Afraid of Senator Teslim Folarin?". Leadership. Archived from the original on 2014-12-01. https://web.archive.org/web/20141201192227/https://leadership.ng/news/388417/afraid-senator-teslim-folarin. Retrieved 2015-04-25.
  6. "PDP leaders mobilise support for Jonathan, Folarin in Oyo". https://guardian.ng/news/nigeria/national/pdp-leaders-mobilise-support-for-jonathan-folarin-in-oyo/.
  7. Wande, S-Davies (2017-12-13). "'Mother of all defections': Alao-Akala, Folarin, Adigun, Arapaja, others officially join APC in Oyo". Nigerian Tribune. https://www.tribuneonlineng.com/mother-defections-alao-akala-folarin-adigun-arapaja-others-officially-join-apc-oyo/. Retrieved 2024-08-29.
  8. "Teslim Folarin Wins Oyo Central Senatorial Seat". 2019-02-25. https://premiumtimesng.com/news/315935-teslim-folarin-wins-oyo-central-senatorial-seat.html.
  9. "Inec declare Seyi Makinde as winner of Oyo state govnorship election". BBC News Pidgin. https://www.bbc.com/pidgin/tori-65005722. Retrieved 2023-03-21.