Jump to content

Ìyábọ̀ Ọbásanjọ́

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
(Àtúnjúwe láti Iyabo Obasanjo-Bello)
Iyabo Obasanjo
Obasanjo in 2015
Senator for Ogun Central
In office
5 June 2007  6 June 2011
AsíwájúIbikunle Amosun
Arọ́pòOlugbenga Onaolapo Obadara
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí27 Oṣù Kẹrin 1967 (1967-04-27) (ọmọ ọdún 59)
Lagos, Nigeria
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeoples Democratic Party
(Àwọn) olólùfẹ́
Oluwafolajimi Akeem Bello
(m. 1999; div. 2003)
Àwọn ọmọ1
Àwọn òbí
ResidenceUnited States
Alma mater
Profession
  • Politician
  • veterinarian
  • epidemiologist
  • academic

Iyabo Obasanjo (a bi ní ọjọ̀ kẹtàdínlọ́gbọ́n oṣù Kẹrin ọdun 1967) jẹ ọmọ bíbí orílẹ̀ èdè Naijiria, onimọ nipa àjàkálẹ́-àrùn, àti aṣòfin tẹlẹ. Ó jẹ́ ọmọbìnrin ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ Olusegun Obasanjo àti ìyàwó rẹ̀ Oluremi Obasanjo.[1]

Ìgbà èwe àti ilé ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Obasanjo lọ sí Ilé-ìwé Corona ní Victoria Island, ní ìlú èkó, Ilé-ìlé-ìwé Capital ní Kaduna, àti Ilé-ìkọ́ Queen's College ní ìlú èkó. Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè gẹ́gẹ́bíi dọ́kítà oníṣègùn àwọn ẹranko láti Ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti Ìbàdàn ní ọdún 1988, ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ẹlẹ́ẹ̀kejì nípa àjàkálẹ àrùn láti Ilé-ìwé gíga ti California, Davis ni, California ní orílẹ̀ èdè Amẹrika ní ọdún 1990, ósì kẹ́kọ̀ọ́ gboyè dọ́kítà nínú ìmọ̀ yìí kańnàn láti Ilé-ìwé Cornell ní Ithaca, New York, ní ọdún 1994. [2]

Gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ṣáájú kí ó tó di aṣòfin, Obasanjo jẹ́ alákòóso fún ètò ìlera ní ìpínlẹ̀ Ògùn. [3] a dìbò yàn-án gẹ́gẹ́ bíi aṣòfin tó ń ṣojú ẹkún ààrin gbùngbùn ìpìnlẹ̀ Ògùn ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà Oṣù Kẹrin ọdún 2007. [3] Ó gbé àpótí ẹlẹ́ẹ̀kejì lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ PDP nínú ètò ìdìbò tí ó wàyé ní Oṣù Kẹrin ọdún 2011, ṣùgbọ́n ó pàdánù sọ́wọ́ ọ Olugbenga Onaolapo Obadara ti ẹgbẹ́ òṣèlú Action Congress of Nigeria (ACN), tí ó ní ìbò ọ̀kẹ́ márùn-ún lé méjì lé ní iriwó diń mọ́kànlá (102,389) sì ọ̀kẹ́ méjì àbọ̀ lé mẹ́fà lé ọ̀ọ̀dúnrún ó lé méjìlá (56,312) tí Obasanjo Bello ní.[4]

Gẹ́gẹ́ bíi Aṣòfin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A dìbò yan Obasanjo gẹ́gẹ́ bíi ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n Oṣù Kẹrin, ọdun 2007 lórí pẹpẹ ti ẹgbẹ́ People's Democratic Party (PDP); ẹni tí ó jẹ́ alátakò rẹ̀ láti inú ẹgbẹ́ òṣèlú ti Action Congress (AC) Remilekun Bakare tako èsì àbájáde ìbò yìí, ṣùgbọ́n Ilé-ẹjọ́ tó ń rísí àwọn awuyewuye to ma ń wáyé látàrí ìbò ẹ̀ka ti ìpínlẹ̀ Ògùn ti fòǹtẹ̀ lu àbájáde èsì ìbò náà. [5]

Ó jẹ́ alága ilé lórí ètò Ìlera, àti ọmọ ẹgbẹ́ ti ààbò àti ìmòye, ìgbòkègbodò àwọn ọkọ̀, ìmọ̀-ẹ̀rọ àti sáyẹ́ńsì, ètò ẹ̀kọ́, ètò Orílẹ̀-èdè, àti ọmọ ìgbìmọ̀ tó ń rísí ọ̀rọ̀ láàárín àwọn Ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin. [3] Ó pàdánù ìjókòó rẹ̀ nínú ètò ìdìbò tí ó wáyé ní ọjọ́ kẹsàn-án Oṣù Kẹrin ọdún 2011.

Ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú wá sí òpin ní ọdún 2015 nígbàtí aṣòfin Gbenga Obadara gba ipò aṣòfin tó ń ṣojú ẹkùn ìdìbò ààrin gbùngbùn ìpínlẹ̀ ògùn kúrò lọ́wọ́ rẹ̀.

Ìgbanipa tí ó fẹ́ wáyé

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní oṣù kẹrin ọdún 2003, ní ọjọ́ ètò ìdìbò àpapọ̀, wọ́n yin ìbọn mọ́n ọkọ̀ rẹ̀ ní ojú ọ̀nà Ifọ̀ ní ìpínlẹ̀ Ògùn. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sí nínú ọkọ̀ náà, àwọn àgbàlagbà mẹ́ta àti ọmọdé méjì tó wà nínú ọkọ̀ náà ni wọ́n jáde láyé. Wọn kò sì rí àwọn ọ̀daràn tó ṣiṣẹ́ láabi náà. [6]

Ní Oṣù Kẹrin ọdún 2008, Obasanjo wà lábẹ́ ìwádìí àjọ tó ń rísí ìwà ìbàjẹ́ nípa ètò ọrọ̀ ajé àti ètò ìṣúná ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà (EFCC) látàrí ìwadǐ tí wọ́n ń ṣe lórí ẹni tì ó jẹ́ mínísítà fún ọ̀rọ̀ ìlera tẹ́lẹ̀, Ọ̀jọ̀gbọ́n Adenike Grange, àti mínísítà kejì fún ọ̀rọ̀ ìlera, Gabriel Aduku, fun kíkó owó ìlú jẹ. [7] Àjọ náà kò dá gbogbo owó tí kò lò padà sí àṣùwọ̀n ìjọba àpapọ̀ ní òpin ọdún. Iye owó náà jẹ́ ọ̀ọ̀dúnrún mílíọ̀nù Naira, tí wọ́n fi ẹ̀sùn kànwọ́n wípé wọ́n sọ abẹ sí owó náà tí wọ́n sì pín láàárín mínísítà, àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba tó ga jù ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà àtí àwọn ìgbìmọ̀ tó ń rísí ọ̀rọ̀ ètò ìlera èyí tí ó jẹ̀ ọ̀gá wọn. Wọ́n pàṣẹ fún mínísítà àti igbákejì rẹ̀ láti kọ̀wé fi ipò wọn sílẹ̀ lẹ́yìn tí wọ́n san oye tí ó kànwọ́n nínú owó náà pa dà; wọ́n jù wọ́n sí àtìmọ́lé lẹ̀yín èyí ṣùgbọ́n wọ́n padà fiwọ́n sìlẹ̀ tí wọ́n sì gba onídǔró wọn. Obasanjo kò gbà láti san ìpín owó náà padà, ìyẹn mílíọ̀nù mẹ́wàá naira. Ó sọ pé àwọn mẹ́sàn-án tó wà nínú ìgbìmọ̀ rẹ̀ ni wọ́n nílò owó láti ṣiṣẹ́ ní àwọn àjọ tí wọ́n ń bójú tó. Ó sọ pé owó yìí ni wọ́n ná sórí àpérò kan lórí ìróni ní agbára tí àwọn ọmọ ìgbìmọ̀ ẹ̀ka ètò ìlera kan lọ fún ní orílẹ̀ èdè Ghánà. Ó kọ̀ láti fara hàn níwájú ìgbìmọ̀ EFCC títí di báyìí. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ránṣẹ́ pe òhun, mínísítà àtàwọn òṣìṣẹ́ ìjọba mìíràn, síbẹ̀ ó kọ̀ láti farahàn ní ilé ẹjọ́. Ọ̀sẹ̀ kan lẹ́yìn náà, ìṣẹ̀lẹ̀ apanilẹ́rìn-ín kan ṣẹlẹ̀ níbití àwọn òṣìṣẹ́ EFCC ti gbìyànjú láti mu ní ilé rẹ̀ tó wà ní agbègbè Maitama ti ìlú Àbújà, lẹ́yìn tí àwọn òṣìṣẹ́ agbófinró ti gbìyànjú láti gbe, Ìyábọ̀ padà fo ìgànnán tí ó yí ilé rẹ̀ ká láti sálọ mọ́ àwọn agbófinró lọ́wọ́. Ní ọdún 2009, Ilè-ẹjọ́ gíga tó wà ní ìlú Àbújá ni wọn da ẹjọ́ náà nù tiketike pẹ̀lú àlàyé wípé ẹjọ́ náà kò lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀.[8][9]

Ọbasanjo sọ pé ẹ̀sùn náà jẹ́ ìbanilórúkọjẹ́, ó sì sọ̀ wípé wọ́n nijú sọ òhun nítorípé òhun jẹ́ ọmọbìnrin fún ààrẹ tẹlẹ̀. [10]

Iṣẹ́ tó ṣe lẹ́yìn tó kúrò ní ipò Aṣòfin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọdún 2018, ìwé àpilẹ̀kọ kan tí Ìyábọ̀ kọ sí bàbá rẹ̀ ní ọdún 2013 jẹ jáde níbití bàbá rẹ̀ ti fi ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ ààrẹ Muhammadu Buhari, èyítí ó ti dá àwọn olólùfẹ́ ijọba Buhari lẹ́bi. Ó tún rọ ìjọba Buhari láti gbọ́ràn sí ìmọ̀ràn bàbá rẹ̀ kí ó máṣe díje fùn ipò ààrẹ lẹ́ẹ̀keji. [11]

Iṣẹ́ ilé ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ó ṣiṣẹ́ ní ẹka ìwádìí ìṣoògùn ní orílẹ̀ èdè AMẸRIKA ṣáájú kí ó tó padà sí Nàìjíríà ní ọdún 2003. Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ nígbàtí ó sì di ọdún 2013 [12] ó di ọmọ ẹgbẹ àgbà nínú ipilẹṣẹ Alakoso ti ilọsiwaju ti ilé ẹ̀kọ́ Harvard. Ó jẹ́ olùrànlọ́wọ́ ọ̀jọ̀gbọ́n ní Ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti William & Mary Department of Health Sciences. [13] Àwọn iṣẹ́ tó ṣeyebíye rẹ̀ ni ìwọ̀nyí:

Ìgbésí ayé nígbà tí ó ti tójú bọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Obasanjo di aya Oluwafolajimi Akeem Bello ní oṣù kẹsàn-án ọ́dún 1999. Àwọn tọkọtaya fi ara wọn sílẹ̀ lẹ́hìn tí Obasanjo kọ ìwé wípé òhun ò ṣemọ́ ní ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù karùn-ún ọdún 2003. Àwọn méjèèjì ní ọmọ kan; Jimi Bello tí a bí ní ọjọ́ kíní oṣù Kíní ọdun 2000 ni County Chatham, North Carolina.

Àdàkọ:OgunState-FedRep

  1. "Obasanjo's first love". Archived on 4 August 2007. Error: If you specify |archivedate=, you must also specify |archiveurl=. http://www.sunnewsonline.com/webpages/features/womanofthesun/2005/mar/29/womanofthesun-29-03-2005-001.htm.
  2. Empty citation (help)
  3. 1 2 3 Empty citation (help)
  4. Empty citation (help)
  5. Empty citation (help)
  6. Empty citation (help)
  7. Empty citation (help)
  8. Empty citation (help)
  9. Empty citation (help)
  10. Empty citation (help)
  11. Empty citation (help)
  12. Empty citation (help)
  13. Empty citation (help)