Victor Ndoma-Egba
Sen. | |
|---|---|
| Chairman | |
| In office July 2016 – January 2019 | |
| Asíwájú | Bassey Dan-Abia |
| Arọ́pò | Nelson Braimbraifa (acting) |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 8 Oṣù Kẹta 1956 |
| Ọmọorílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Ẹgbẹ́ olóṣèlú | All Progressives Congress |
Victor Ndoma-Egba CON OFR SAN (A bíi ní ọjọ́ kẹjọ Oṣù Kẹta ọdún 1956) jẹ́ olósèlu orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àti alága tẹ́lẹ̀ fún ìgbìmọ̀ Ìdàgbàsókè agbègbè Niger Delta (NDDC). Ó jẹ̀ aṣòfin fún ìgbà mẹ́ta, ó ṣojú agbègbè ààrin gbùngbùn Cross River ti ípinle Cross River ni ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ti orílẹ̀ èdè Naijiria láti ọdún 2003 sí ọdún 2015. [1]
Ìpìlẹ̀ Ayé rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Victor Ndoma-Egba ni a bi ní ọjọ́ kẹjọ Oṣù Kẹta , ọdun 1956 ní Ikom, ìpínlẹ̀ Cross River. Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè nínú ìmọ̀ ófin láti ilé ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì ti ìpínlẹ̀ èkó àti ìmọ̀ ìjìńẹ̀ nípa ìmọ̀ òfin láti Yunifásítì Calabar. A pè é sí ilé ìgbìmọ̀ àwọn agbejọ́rò Nàìjíríà ní ọdún 1978, a sì gbée ga sí ipò àwọn agbẹjọ́rò tí ó gajù ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ní ọdún 2004. Ó ti jẹ́ alákòóso ti ẹgbẹ àwọn Agbẹjọ́rò ti Nàìjíríà, Ẹka ti Calabar, àti Alakòóso ti Ilé-iṣẹ́ ìṣòwò Calabar. ò tún jẹ́ Olùdarí ti Cross River Basin ati ìdàgbàsókè agbègbè, àti alákòsòo fun ọ̀rọ̀ iṣẹ́ àti ìrìnà ní ìpínlẹ̀ Cross Rivers. [1]
Iṣẹ́ olóṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Ó díje lábẹ́ àsìà Ẹgbẹ́ People's Democratic Party (PDP), Ndoma-Egba jáwé olúborí láti lọ sí ilé aṣòfin àgbà ìṣí karùn-ún ni ọduń (2003-2007) níbití ó ti ṣe aṣoju ààrin gbùngbùn ti Cross River, ó tùn dìbò wọlé ẹlẹ́ẹ̀kejì ní ọdún 2007 fún ọdún mẹ́rin mìíràn. Sẹ́nátọ̀ Ndoma-Egba jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ ti àwọn ìgbìmọ̀ tí ò ǹ rìsí ọ̀rọ̀ epo rọ̀bì, ẹ̀tọ́ ènìyàn ati àwọn ọ̀rọ̀ òfin, ati pe o jẹ igbakeji alaga ti àwọn tí ó ń rísí ètò ìdájọ́ ti Ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà ti ilẹ̀ Nàìjíríà.[1]
Ni oṣù karùn-ún ọdún 2008, Ndoma-Egba sọ̀rọ̀ làti ṣe àtìlẹyìn fún àtúnṣe sì ìṣe àwọn ọlọ́pàá orìlẹ̀ èdè Nàìjíríà, èyítí ati ṣe láti ọjọ́ kìnní-ín oṣù kẹrin ọdún 1943 tí a kò sì yẹ̀wò láti ìgbà ná àn. Ní oṣù karùn-ún ọdún 2009, ó fẹ̀sùn kan ẹgbẹ́ Action Congress nípa dídènà láti ṣe àkọsìlẹ ìjọba ìbilẹ̀ mẹ́tadínlógójì ti ìlú èkó sínú ìwé òfin ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ẹ̀sùn tí ó wá làti ọ̀dọ̀ ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin kékeré Bola Gbabijo.
Ní Oṣù Kẹsǎn ọdun 2009, Ndoma-Egba ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn tí ó ṣe pàtàkì ní ìpínlẹ̀ Cross River ti lọ kúrò nínú ẹgbẹ́ òṣèlú ti Action Congress (AC) àti All Nigeria People's Party (ANPP) láti darapọ̀ mọ ẹgbẹ́ òsèlú ti People's Democratic Party (PDP), ń sọ́ pé èyí jẹ́ àmì pé àwọn ẹgbẹ́ alátakò ti ṣubú ní ìpínlẹ̀ náà. Ní Oṣù Kíní ọdún 2013 Ndoma-Egba sọ pé ojùtǔ sí àwọn ìjà tí ó ń bẹ́ sílẹ̀ ní àwọn agbègbè ti Cross River ni dídá tí àwọn ìgbìmọ́ tí ó ń rísí ọ̀rọ̀ ààlà ní Nàìjíríà ṣe ń dásí ọ̀rọ̀ àwọn ààlà ti ó yí Cross River ká. [2]
Ndoma-Egba ni a tún dìbò yàn gẹ́gẹ́bí aṣòfin àgbà fun ààrin gbùngbùn Cross River ọjọ́kọkàdínlọ́gbọ̀n Oṣù Kẹrin, ọdun 2011 lábẹ́ àṣìá ẹgbẹ́ PDP, ó jáwé olúborí pẹ̀lú ìbò tí ó jẹ́ 143,537, tí alátakó rẹ̀ Patric Iwara tí ó wà nínú ẹgbẹ́ òṣèlú Action Congress of Nigeria (ACN), ní ìbò tí ó jẹ́ 47,656. [3]
lẹ́yìn èdè àìyedè tí ó wáyé nínú ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, ó dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ All Peoples Congress (APC) ní oṣù kọkànlá ọdún 2015. Ò jẹ́ igbákejì Olùdarí ti ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà kẹfà láti ọdún (2007 sí 2011) àti adarí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin láti ọdún (2011 si 2015). Ó padà sí ilé iṣẹ́ òfin rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Òṣiṣẹ́ Alákòóso ní Ile-iṣẹ́ Òfin Ndoma-Egba, Ebri & Co ní Abuja. Ni Oṣu Keje ọdun 2016, a yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí Ìgbìmọ̀ Ìdàgbàsókè ẹkùn ti Niger Delta (NDDC) nípasẹ̀ Muhammadu Buhari tí ó jẹ́ olórí orílẹ̀ èdè.
Ìgbésí ayé ara ẹni
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ndoma-Egba ni a bí nípasẹ̀ olóògbé onídǎjọ́ Emmanuel Ndoma- Egba, ó jẹ́ onídǎjọ́ ní ẹka ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, àti arábìrin Regina Nentui, olùkọ́ni ilé-ìwé àti agbègbè, obìnrin àkọ́kọ́ tí ó jẹ alága agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ ní Nàìjíríà. Ó jẹ́ ọmọ-ìjọọ Kátólíìkì tó ní ìfọkànsìn, ó sì ti ṣe àwọn ọrẹ pataki sí ìjọ Kátólíìki tó wà ní ìlú abínibí rẹ̀, Ikom. Ndoma-Egba ní ìyàwó, Ọba òkè sì fi ọmọ mẹ́ta dé ìgbeyàwó wọn ládé.
Àwọn àlàyé
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- 1 2 3 Empty citation (help)
- ↑ "Nigeria: Demarcate Ebonyi, Cross River Boundaries, Ndoma-Egba Tells NBC". 28 January 2013. http://allafrica.com/stories/201301280424.html.
- ↑ Empty citation (help)