Simon Ajibola
Simon Ajibola | |
|---|---|
| Senator of the Federal Republic of Nigeria from Kwara South Senatorial District | |
| In office 29 June 2004 – May 2015 | |
| Asíwájú | Suleiman Ajadi |
| Arọ́pò | Rafiu Ibrahim |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | Kwara State, Nigeria |
Simon Ajibola di Sénétọ̀ fún Agbègbè Sénétọ̀rì Gúúsù Kwara ní Ìpínlẹ̀ Kwara ní Oṣù Karùn-ún ọdún 2004, wọn sì tún dìbò yàn án padà ní ọdún 2007. Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú People’s Democratic Party (PDP).[1]
Ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésíayé àti Ẹ̀kọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ajíbọ́lá gba ìwé-ẹ̀rí ìyẹ̀wù àkọ́kọ́ nínú Quantity Surveying láti Yúnifásítì Ahmadu Bello, Zaria ní ọdún 1979.
Iṣẹ́ òṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Wọn dìbò yàn Ajíbọ́lá gẹ́gẹ́ bí Aṣojú (Delegate) sí Àpéjọ Ìdásílẹ̀ Òfin Àpapọ̀ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láàárín ọdún 1994 sí 1995. Ní àkókò ìyípadà ìṣàkóso tí Gẹ́nérálì Sani Abacha gbèrò, Ajíbọ́lá dije fún ipò sénétọ̀ lábẹ́ United Nigeria Congress Party (UNPP). Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ka a sí ẹni tí kò ní ànfààní púpọ̀, ó jáwé olúborí nínú ìdìbò náà. Bótilèjẹ́ wípé, wọn fagilé ìlànà ìdìbò yìí lẹ́yìn ikú Abacha ní Oṣù Karùn-ún ọdún 1998.[2]
Lẹ́yìn tí ìjọba alágbádá padà wá sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọdún 1999, Ajíbọ́lá ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Kọ́mísọ́nà Àpapọ̀ ní Revenue Mobilization, Allocation & Fiscal Commission láàárín ọdún 2001 sí 2002.
Ní Oṣù Kẹrin ọdún 2003, Ajíbọ́lá tún dije fún ipò Sénétọ̀ Gúúsù Kwara, ṣùgbọ́n Suleiman Makanjuola Ajadi ti ẹgbẹ́ òṣèlú All Nigeria Peoples Party (ANPP) ṣẹ́gun rẹ̀. Síbẹ̀, ní Oṣù Karùn-ún ọdún 2004, Ilé-ẹjọ́ Ẹ̀sùn Ìdìbò fagilé àbájáde ìdìbò Ajadi, wọ́n sì kéde Ajíbọ́lá gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a dìbò yàn.[3] wọn tún dìbò yàn án padà ní ọdún 2007, wọn sì yan án sí àwọn komitì lórí ọ̀rọ̀ Omi (Water Resources), Epo Rọ́bà (Upstream Petroleum Resources), Ààbò àti Ìmúlòyẹ̀ (Security & Intelligence) àti Ọgbìn (Agriculture). Ní àyẹ̀wò àárín àkókò iṣẹ́ àwọn sénétọ̀ ní Oṣù Karùn-ún ọdún 2009, ìwé ìròyìn ThisDay sọ pé kò gbé òfin kankan kalẹ̀ ní ọdún tó ṣáájú, ìkópa rẹ̀ nínú àríyànjiyàn ilé-igbìmọ̀ sì kéré; síbẹ̀, ó kópa dára dára nínú iṣẹ́ komitì.[4]
Ajíbọ́lá tún dije fún ipò Sénétọ̀ Gúúsù Kwara ní ìdìbò ọjọ kẹsán Oṣù Kẹrin ọdún 2011, wọn sì dìbò yàn án padà fún ìgbà kẹta. Ní Oṣù Kejìlá ọdún 2014, Sénétọ̀ Ajíbọ́lá ṣẹ́gun àwọn olùdíje tí a ka sí olókìkí jù lọ bí Dele Belgore àti Gbemisola Saraki láti gba àmì ìdìbò àkọ́kọ́ fún ẹgbẹ́ òṣèlú PDP,[5] kí ó lè jẹ́ aṣáájú ẹgbẹ́ fún ìdìbò Gómìnà Ìpínlẹ̀ Kwara fún ọdún 2015,[6] níbi tí ó ti ṣe ìlérí láti fún àwọn ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́rìndínlógún (16) ní òmìnira bí wọn bá dìbò yàn án gẹ́gẹ́ bí gómìnà ìpínlẹ̀ Kwara.[7]
Ní Ìdìbò Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ọdún 2015, lẹ́yìn tí ìdìbò àkọ́kọ́ fi hàn pé Abdulfatah Ahmed ń ṣáájú jù lọ nínú ìdíje ipò gómìnà, Sénétọ̀ Ajíbọ́lá kó ẹjọ́ lọ sí ilé-ẹjọ́ láti tako àbájáde ìdìbò náà. Wọn gbé ẹjọ́ náà lọ sí Ilé-ẹjọ́ Gíga Àpapọ̀, níbi tí wọn ti kọ́ ọ́ sílẹ̀, adájọ́ sì pinnu pé Sénétọ̀ Ajíbọ́lá kò ní àṣẹ òfin (locus stand) láti gbe ẹjọ́ náà kalẹ̀.[8]
| Àyọkà yìí tàbí apá rẹ̀ únfẹ́ àtúnṣe sí. Ẹ le fẹ̀ jù báyìí lọ tàbí kí ẹ ṣàtúnṣe rẹ̀ lọ́nà tí yíò mu kúnrẹ́rẹ́. Ẹ ran Wikipedia lọ́wọ́ láti fẹ̀ẹ́ jù báyìí lọ. |
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ https://web.archive.org/web/20160303173958/http://www.nassnig.org/senate/member.php?senator=90&page=1&state=25
- ↑ "Ẹda pamosi". Archived from the original on 2012-03-06. Retrieved 2025-12-25.
- ↑ https://archive.today/20130209172251/http://groups.yahoo.com/group/Naija-news/message/3358
- ↑ http://allafrica.com/stories/200905250350.html?viewall=1
- ↑ "Ẹda pamosi". Archived from the original on 2014-12-31. Retrieved 2025-12-25.
- ↑ http://www.independentngonline.com/DailyIndependent/Article.aspx?id=31905
- ↑ "Ẹda pamosi". Archived from the original on 2025-04-27. Retrieved 2025-12-25.
- ↑ https://www.premiumtimesng.com/regional/north-central/201917-appeal-court-upholds-ahmeds-election-kwara-governor.html