Báyọ̀ Adébọ̀wálé

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Báyọ̀ Adébọ̀wálé
Ọjọ́ìbí(1944-06-06)6 Oṣù Kẹfà 1944
Adeyipo village, Ìbàdàn, Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Ọmọ orílẹ̀-èdèNigerian
Iṣẹ́
  • poet
  • novelist
  • critics
  • author
Ìgbà iṣẹ́1961 - present
Gbajúmọ̀ fúnThe Virgin

Báyọ̀ Adẹ́bọ̀wálé tí wọ́n bí ní ọjọ́ Kẹfà oṣù Kẹfà ọdún 1944 jẹ́ akọ ewì, òǹkọ̀wé, ọ̀jọ̀gbọ́n, lámèyítọ́, ònṣètò ìwé àti olùdásílẹ̀ ilé-ìwé African Heritage Library and Cultural Centre tí ó wà ní , Adéyipo, ni ìlú ÌbàdànÌpínlẹ̀ Òyọ́. [1][2][3] i[4]

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé rẹ[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Adébọ̀wálé sí ìdílé bàbá rẹ̀ Àkàngbé Adébọ̀wàlé tí ó jẹ́ àgbẹ̀ roko bọ́dún dé nígbà aye rẹ̀[5] Ó kẹ́kọ́ nílé ẹ̀kọ́ ti oníwé mẹ́wàá ti Mọdá tí ó wà ní ìlú Ìbàdàn, níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí ti WASSCE ní ọdún 1958, ṣáájú kí ó tó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ ti Olùkọ́ni ti St. Peter's níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí ti Grade III nínụ́ ìmọ̀ ìkọ́ni ní ọdún 1961. Ó sì tún wọlé sí ilé-ẹ̀kọ́ Olùkọ́ni Onítẹ̀bọmi ti ìlú Ẹdẹ láti kẹ́kọ́ gbàwé ẹ̀rị́ olùkọ́ni ti Grade II ní ọdún kan náa.[6] Ó lọ sí ilé-ẹkọ́ Yunifásiti Ìbàdàn ní inú oṣù Kẹwàá ọdún 1971 níbi tí ó ̣ti gba ìwé ẹ̀rí (B. A) nínú ìmọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì ní ọdún 1974, tí ó sì ṣe Agùnbánirọ̀ ni odun 1975. Ó ṣiṣẹ́ ní ilé-iṣẹ́ Western State Public Service Commission gẹ́gẹ́ bí olùkọ́ni ṣáájú kí ó tó di olùkọ́ni ní ilé ìtajà ti ìjọba (Government Trade Centre), ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ̣́.[7] Ó kàwé gboyè ìkejì nínú ìmọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì ní ọdún 1978, tí ó sì dara pọ̀ mọ́ ilé-ẹ̀kọ́ ìkọ́ni ti Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ gẹ́gẹ́ bí Olùkọ́ni, ṣáájú kí wọ́n tó gbe lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ gbogbonìṣe ti ìlụ́ Ìbàdàn níbi tí ó ti di igbákejì adarí ile-́ẹ̀kọ́ náà ní ọdún 1999 sí ọdún 2003, lẹ́yìn tí ó ti kàwé gboyè Ọ̀mọ̀wé nínú ìmọ̀ Lítíréṣ̀ọ̀ ní Yunifásitì Ìlọrin ní ọdún 1997.[8]

Iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Báyọ̀ ti tẹ ìwé tí ó ọgọ́rún , ó sì ri k9 àwọn ìwé ìtàn míràn tí a ti rí The Virgin ni wọ́n ti lò nínú àwọn eré ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.. Lára àwọn eré tí wọ́n ti lo ìwé 8tàn rẹ̀ ni The Narrow Path tí wọ́n gbé jáde ní ọdún 2006, lábẹ́ ilé-iṣẹ́ "Maiframe" lábẹ́ àṣẹ àti ìdarí gbajú-gbajà òṣèré àti olùgbéré-jáde àti adarí eré Túndé Kèlání. Eré yí náà ló gbé Ṣ9lá Asẹ́dẹkọ̀ jáde fáyé rí. Wọ́n tún lo ìwé ìtàn Báyọ̀ Adéwálé nínú eré The White Handkerchief.[9][10] He authored Lonely Days, a book that focus on African culture.[11] Báyọ̀ ti kòpa lààmì-laaka nínú iṣẹ́ lítíréṣọ̀ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà pàá pàá jùlọ Black African Literature in English.[12] He also authored a novel titled Out of his Mind.[13] Eré onítàn rẹ̀ The River Goddess ni ó fi gba amì-ẹ̀yẹ nínú ìdíje ECOWAS ní ọdún 1972, ewì rẹ̀ tí ó pè ní Perdition náà ni ó gba amì-ẹ̀yẹ níbi ayẹyẹ Censorship International Poetry Competition in London fún ilẹ̀ adúláwò. 9pòlọpọ̀ ìwé apilẹ̀kọ rẹ̀ ni wọ́n ti ṣamúlò nínú iṣẹ́ ìwádí ìmọ̀ oríṣiríṣi ní àwọn fásiti orísiríṣi.[14]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. ̣"Artistic bells in a science world". The Punch - Nigeria's Most Widely Read Newspaper. Archived from the original on 2015-04-10.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  2. "The man who grew larger than life". nigeria.gounna.com. Archived from the original on 10 April 2015. Retrieved 4 April 2015.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  3. Latestnigeriannews. "Research: Expert seeks improved govt funding". Latest Nigerian News. 
  4. "BAYO ADEBOWALE:BIOGRAPHICAL SKETCH". AFRICAN LITERATURE:IN HONOUR OF AFRICAN WRITERS: 1. BAYO ADEBOWALE (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2009-02-09. Retrieved 2020-05-27. 
  5. "Welcome to Adeyipo Village - Nigeria Content Online". nigeriang.com. 
  6. Holger G. Ehling, ed (2001). No Condition Is Permanent: Nigerian Writing and the Struggle for Democracy. Rodopi. p. 189. https://books.google.com/books?id=31mP-0eAhxYC&pg=PA189&lpg=PA189&dq=Bayo+Adebowale,+African+literature&source=bl&ots=86rov5E_P4&sig=pk9yXNIsH9TUc7SGYP51I0TSBng&hl=en&sa=X&ei=qQwgVdGaOsidPbHmgOgC&ved=0CBkQ6AEwBjgK. 
  7. Adewale Oshodi. "How SYNW is promoting unknown young writers in Nigeria". tribune.com.ng. Archived from the original on 2015-04-10.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  8. "Bearing Witness". google.co.uk. 
  9. "The Virgin". google.co.uk. 
  10. David Kerr, ed (2011). Media and Performance. Boydell & Brewer. p. 30. https://books.google.com/books?id=dFzMC-nHqi4C&pg=PA30&lpg=PA30&dq=Bayo+Adebowale-Punch&source=bl&ots=i0ev4xqs7_&sig=SrAan4yOvr3idGaNsGL9mALIsEI&hl=en&sa=X&ei=OQggVYn3KYGcsgGnoYCIDA&ved=0CBcQ6AEwBQ. 
  11. Lonely Days. Spectrum Books. 2006. https://books.google.com/books/about/Lonely_Days.html?id=y95lAAAAMAAJ. 
  12. "Black African Literature in English, 1997-1999". google.co.uk. 
  13. "Thought with Pen: Book Review: Out of His Mind – Bayo Adebowale". Thought with Pen. 2015-09-12. Retrieved 2020-01-17. 
  14. "Archived copy" (PDF). Archived from the original (PDF) on 2015-04-10. Retrieved 2015-04-04.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)

14.[1]Àdàkọ:Authority control

  1. "Summary Of Lonely Days". Archived from the original on 2019-04-22. Retrieved 2020-11-09.