Efunsetan Aniwura
| Ẹfúnṣetán Aníwúrà | |
|---|---|
| Ìyálóde of egba. | |
| Reign | 1867 – May 1, 1874 |
| Coronation | 1867 |
| Issue | |
| 1 (daughter, died 1860) | |
| Father | Ogunrin |
| Born | c. 1820s Abeokuta |
| Died | June 30, 1874 Ibadan |
Oloye Ẹfúnṣetán Aníwúrà (c.1820s–June 30, 1874) je Iyalode keji ti Ìbàdàn ati ọkan ninu awọn oniṣowo ẹrú ṣáaju ni ọrundun 19th Ibadan.[1][2] Ti a bọwọ fun bi onijaja ati onijaja aṣeyọri, ipa rẹ ni ayika iṣelu, ologun, eto-ọrọ aje ati awọn agbegbe ẹsin Ibadan. Ó jẹ́ olókìkí nítorí pé ó jẹ́ alágbára jù lọ, àti pé ó dájú pé ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn olówó jùlọ–àwọn obìnrin Yorùbá tí ó ti gbé ayé rí. A ti ṣapejuwe rẹ nipasẹ awọn onitan-akọọlẹ bi adari alaṣẹ, ti o lo ijiya nla nigbagbogbo lori awọn ẹrú ti o ṣina. Eyi ni á ti da si ibajẹ ọpọlọ ti o waye lati iku ọmọbirin rẹ kanṣoṣo, áti ailagbara rẹ lati bibi lẹhinna.
Ìgbésí ayé ara ẹni
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí Aniwura ní Ikija-Egba ní àárín ọdún 1820s[3][4]. Ẹbí rẹ̀ kó lọ sí Ìbàdàn lẹ́yìn ìṣubú Ikija ní ọdún 1820s. Bàbá rẹ̀, Oloye Ogunrin, jẹ́ ológun láti Ikija, nígbà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Ilé-Ifẹ̀. A lè sọ pé ìtara rẹ̀ sí ọjà àti òwò jẹ́ ogún tí ó jogún lọ́dọ̀ ìyá rẹ̀, ẹni tí í ṣe oníṣòwò kékeré. Ìbẹ̀wò Aniwura sí ọjà lọ́pọ̀lọpọ̀ pẹ̀lú ìyá rẹ̀ tún mú àṣeyọrí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí oníṣòwò túbọ̀ lágbára.[5] Ó ṣe ìgbéyàwó lọ́pọ̀ ìgbà, ó sì bí ọmọ kan tí ó kú nígbà ìbí. Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ti jẹ́ kókó ọ̀pọ̀ ìkọ̀wé ìtàn, wọ́n sì sọ pé ó ní ipa lórí apá ìkẹyìn ìgbé-ayé rẹ̀, ní ọ̀nà rere (nípa ìfọkànsìn sí iṣẹ́) àti ní ọ̀nà búburú (nípa ìkà àti ìkórìíra).[6]
Ìdàgbàsókè àti ìṣubú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Gẹ́gẹ́ bí Olawale Idowu ṣe sọ, ìpinnu Aniwura láti kó lọ sí Ìbàdàn wáyé fún ìdí méjì pàtàkì: àkọ́kọ́, ní àkókò yẹn, ọmọ ẹ̀gbọ́n bàbá rẹ̀ kan jẹ́ adarí olókìkí ní ìlú náà; èkejì, torí ìwà oníṣòwò àti ìlera ọrọ̀ ajé ìlú Ìbàdàn ní àkókò yẹn, ní ìfiwéra pẹ̀lú àwọn ibòmíràn, ó lè dá iṣẹ́ òwò aṣeyọrí sílẹ̀ níbẹ̀. Wọn sọ pé ó ní ẹrú tí o tó ẹgbẹ̀rún méjì (2,000) àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oko, ó ń ta àwọn ohun èlò ogbin lọ sí Porto-Novo, Badagry àti Ikorodu[5][7][5]. Òwò pàtàkì rẹ̀ ni taba àti títà ẹrú. Ó tún ń ṣe ohun ìtìjú ara (cosmetic) abinibi kan tí a ń pè ní Kijipa, tí wọn ń kó lọ sí Amẹ́ríkà fún lílo. Ìṣòro rẹ̀ nípa àìríọmọbí jẹ́ ìdí tí ó fi ṣiṣẹ́ takuntakun nínú òwò[8], bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ipa búburú rẹ̀ ni ìdàrúdàpọ̀ ẹ̀mí, torí pé ní àkókò yẹn, nini ajogún jẹ́ àmì pàtàkì ìlúmọ̀ọ́kàn àti ọrọ̀. Ó máa ń bínú púpọ̀, èyí sì hàn gbangba nínú ìlànà ìṣàkóso rẹ̀. Ó paṣẹ pé kò sí ẹrú kankan nínú ilé rẹ̀ tí yóò lóyún tàbí tó lè fún ẹlòmíràn lóyún, ó sì dá ẹjọ́ ìkú sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìjíyà fún ẹnikẹ́ni tí ó bá rú òfin yìí. Isola (2010) fi hàn pé ní àkókò ìgbé-ayé rẹ̀, ó paṣẹ kí wọ́n gé orí ẹrú mọ́kànlélógójì (41) nítorí rírú òfin rẹ̀.[6][9][7]
Ní ọdún 1860s, wọn yan án gẹ́gẹ́ bí Iyalode kejì ti ìlú Ìbàdàn.[6] Wọn tún yan gẹ́gẹ́ bí alábàápamọ́ Ìjọ Anglican ní Ìbàdàn nítorí ipa rẹ̀ nínú ìtẹ̀síwájú Kristiẹni ní àgbègbè náà. Ọmọ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ olókìkí kan, Rev. Daniel Olubi, jẹ́ alùfáà Anglican ní àkókò yẹn, ó sì ṣe àtìlẹ́yìn fún un nínú iṣẹ́ ìjọ.
Wọn yọ Aniwura kúrò nípò Iyalode ní ọjọ́ Kínní Oṣù Karùn-ún, 1874, lábẹ́ Ààrẹ Latoosa, lórí ẹ̀sùn tí ó jẹ́ ti ìṣèlú, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó san gbogbo ìtanràn tí wọ́n dá lé e.
Àṣẹ àti agbára rẹ̀ nínú àwùjọ, pẹ̀lú ìkòkòṣí rẹ̀ sí ìmọ̀ràn ìṣèlú Aare Ona Kakanfo, Ààrẹ Latoosa, mú kó pinnu láti pa á. Ṣùgbọ́n èyí ṣòro nítorí ipò rẹ̀ láàrín àwọn olórí ńlá. Ó fi owó rà Kumuyilo, ọmọ tí Aniwura gba tọ́, kí ó fi í tan an láti darí rẹ̀ lọ sí ibi tí wọ́n ti pa á.[3] Ọ̀pọ̀ èrò lo wà nípa ìdí tí Latoosa fi fẹ́ kí Aniwura kúrò ní Ìbàdàn. Diẹ̀ ló sọ pé ó jẹ́ torí ìkórìíra obìnrin àti ìlaríyànjiyàn, nígbà tí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ìtàn míì gbà pé torí pé ìlú náà ti gbẹ́kẹ̀ lé e púpọ̀, pàápàá nínú ohun ìjà ogun tí wọn ń gba lọ́wọ́ rẹ̀ láwìn. Àwọn onkọ̀wé kan tún sọ pé àìgbọ́ràn rẹ̀ sí àwọn òfin Ààrẹ ni ó mú un bínú sí i.[10][7]
Ikú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Àwọn ẹrú méjì ni o pa Aniwura nígbà tí ó ń sùn lọ́wọ́ ní ọdún 1874. Ọmọ tí ó gba tọ́, Kumuyilo, ni ó paṣẹ fún wọn láti ṣe bẹ́ẹ̀, ẹni tí Aare Latoosa, olórí Ìbàdàn ní àkókò yẹn, ti san owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fún. Wọn sọ pé ìdí ni pé Latoosa rí i pé ọrọ̀ àti àìgbọ́ràn Aniwura ń halẹ̀ mọ́ agbára òun.
Ìrántí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Oloye Aniwura di mímọ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀ lẹ́yìn tí Ọ̀jọ̀gbọ́n Akinwunmi Isola kọ eré-oníṣe kan nípa rẹ̀. Àwòrán òkúta (statue) Aniwura wà ní àárín Challenge Roundabout, ibi pàtàkì kan ní ìlú Ìbàdàn òde-òní.[6] Ó tún ti jẹ́ kókó nínú ọ̀pọ̀ fíìmù Nàìjíríà, nípa Efunsetan Aniwura.[11][9][12][13]
Àwọn Ìyálóde ìlú Ìbàdàn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Ìyálóde Subuola ọdún 1851-1869
- Iyalode Efunsetan Aniwura, c. ọdún 1870-1874
- Iyalode Iyaola, ọdún 1874-1893
- Iyalode Lanlatu Asabi Giwa, ọdún 1894-1913
- Iyalode Isale Osun, ọdún 1914-1917
- Iyalode Romlatu Ajisomo, ọdún 1917-1934
- Iyalode Rukayat Amosa Akande (alias Iyalode Ita Areegbeomo, ọdún 1935-1948
- Iyalode Abimbola, ọdún 1948-1961
- Iyalode Adebisi Abeo, ọdún 1961-1974
- Iyalode Wuraola Esan, ọdún 1975-1985
- Iyalode Hunmani Alade, ọdún 1985-1995
- Iyalode Wuraola Akintola, ọdún 1995-2007
- Iyalode Aminatu Abiodun, ọdún 2007-2018
- Iyalode Laduntan Oyekanmi, ọdún 2019 - títí di òní.
Awọn itọkasi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Slavery and Slave Trade in Nigeria. From Earliest Times to The Nineteenth Century.https://web.archive.org/web/20180812023005/https://krle6qjpz04.storage.googleapis.com/MTU5MjIxMjI4WA==04.pdf
- ↑ https://en.wikipedia.org/wiki/Efunsetan_Aniwura#cite_ref-2
- 1 2 Tayo, Ayomide (July 25, 2017). "The most powerful woman in the Yoruba kingdom". Pulse. Archived from the original on 2018-08-14. Retrieved 2018-08-06. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ Idowu, Olawale. "Gender and the Politics of Exclusion in Pre- Colonial Ibadan: The Case of Iyalode Efunsetan Aniwura". Journal of traditions and beliefs. Retrieved 2018-08-06.
- 1 2 3 Idowu, Olawale. "Gender and the Politics of Exclusion in Pre- Colonial Ibadan: The Case of Iyalode Efunsetan Aniwura". Journal of traditions and beliefs. Retrieved 2018-08-06.
- 1 2 3 4 Okunola, Akanji. "Research Note: Negative Life Events And Aggressive Behavior Of Efunsetan Aniwura" (PDF). African Journal of Criminology and Justice Studies. Retrieved 2018-08-06.
- 1 2 3 Okunola, Rashidi. "SOCIO-HISTORICAL CRIME REVIEW ON EFUNSETAN ANIWURA, BASHORUN GAA AND AARE-AGO OGUNRINDE AJE" (PDF). Retrieved 2018-08-06.
- ↑ "Efunsetan Aniwura: A Psycho-Historical Exploration of Women's Psychopathology" (PDF). International Journal of Information and Education Technology. Retrieved 2018-08-06.
- 1 2 "Efunsetan Aniwura and other Evans stories". Tribune. 2017-06-19. Archived from the original on 2018-09-04. Retrieved 2018-08-06. Unknown parameter
|url-status=ignored (help) - ↑ Ogunleye, Foluke (2004). "A Male-Centric Modification of History: "Efunsetan Aniwura" Revisited". History in Africa 31: 303–318. doi:10.1017/S0361541300003508. JSTOR 4128529.
- ↑ "Efunsetan Aniwura: Yoruba's most powerful woman that ever lived?". December 26, 2016. Retrieved 2018-08-06.
- ↑ "Epic movie, Efunsetan Aniwura, for release January". 12 January 2020.
- ↑ "The Return of 'Efunsetan Aniwura'". 25 January 2020.