Elfrida O. Adebo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Elfrida O. Adebo, tí orúkọ àbíso rẹ̀ jẹ́ Olaniyan (tí wọ́n sì bí ní ọdún 1928) jẹ́ ọ̀mọ̀wé àti Núrsì ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ní ọdún 1984, ó di ọ̀jọ̀gbọ́n àkọ́kọ́ nínú ìmọ̀ Núrsì ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1]

Ìgbésí ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Adebo ní ìlú Abeokuta, Ìpínlẹ̀ Ògùn,[2] ní ọjọ́ kẹta osù kẹta ọdun 1928.[3] Ó bèrè ipa rẹ̀ nínú iṣẹ́ Núrsì ní London,[1] ibè ló tí kó nípa ìṣẹ́ Núrsì àti gbígbẹ̀bí ní St Mary's Hospital, London láàrin ọdún 1957 sí 1958.[3] Ní ọdún 1959, ó padà sí Nàìjíríà láti di Núrsì ní Ibadan.[1] O gba àmì ẹyẹ D.P.H. nínú ìmò isẹ Núrsì ní ọdun 1961, àti àmì ẹyẹ Bachelor of Nursing ní ọdún 1962.[2] Lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣiṣẹ́ díè gẹ́gẹ́ bi olùbádá ìmọ̀ràn ní School of Hygiene ti ìlú Ibadan, ó di olùkọ́ ní Yunifásítì ìlú Ìbàdàn.[1] Ó dára pọ̀ mọ́ ẹ̀ka isẹ Núrsì ní oṣù Kẹ̀wá ọdún 1967, ó sì di adarí ẹ̀ka náà ní ọdún 1970.[4]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. 1.0 1.1 1.2 1.3 Michael Orodare, Dr Doyin Abiola, Prof. Elfrida Adebo, Major General Aderonke Kale – Extraordinary Nigerian women who made history in male-dominated fields, Neusroom, 14 May 2020. Accessed 17 January 2021.
  2. 2.0 2.1 Adetunji Akinyotu (1989). Who's who in Science and Technology in Nigeria. Federal University of Technology. p. 10. ISBN 978-978-2475-00-8. https://books.google.com/books?id=ojEJAQAAIAAJ. 
  3. 3.0 3.1 Joseph A. Balogun (2020). Healthcare Education in Nigeria: Evolutions and Emerging Paradigms. Taylor & Francis. p. 2. ISBN 978-1-00-031961-3. https://books.google.com/books?id=WjINEAAAQBAJ&pg=RA2-PA6. 
  4. Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid <ref> tag; no text was provided for refs named Tijani2003