Gbenga Omotoso

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Gbenga Omotoso
Ọjọ́ìbíNovember 11, 1961
Orílẹ̀-èdèNigerian
Iṣẹ́Journalist, writer, columnist and commissioner for information and strategy
OrganizationLagos State Ministry of Information and Strategy

Gbenga Omotoso (tí wọ́n bí ní ọjọ́ 11 oṣù November, ọdún 1961) jẹ́ akọ̀ròyìn àti òǹkọ̀wé. Òun ni olóòtú ìwé-ilròyìn The Nation títí tí wọ́n fi yàn án sípò Commissioner tó ní ṣe pèlú Lagos State Ministry of Information and Strategy. Gómínà Ìpínlẹ̀ Èkó, ìyẹn Babajide Sanwo-Olu mu ṣèbúra láti wọ iṣẹ́ ní ọdún 2019.[1][2][3][4]

Ìgbésí ayé àti ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọjọ́ kọkànlá oṣù kọkànlá ọdún 1961 ni wọ́n bí Omotoso. Ó wá láti Ipinle Osun, tó wà ní apá Gúúsù mọ́ Ìwọ-Oòrùn ilẹ̀ Nàìjíríà. Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè B.A nínú ìmọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì àti Lítíréṣọ̀ ní University of Benin (Nigeria) ní ọdún 1984. Ó tẹ̀síwájú láti gboyè Masters nínú ẹ̀kọ́ Public and International Affairs ní University of Lagos, Akoka, tí ó parí ní ọdún 2007.[5][6]

Iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Omotoso ti lo ọdún márùndínlógójì nínù iṣẹ́ ìròyìn. Ó bẹ̀rẹ̀ gẹ́gé bíi akẹ́kọ̀ọ́ tó ń kọ́ nípa iṣẹ́ olóòtú ní ilẹ́-iṣẹ́ ìwé-ìròyìn The Guardian. Ó padà di igbákejì olóòtú ti Guardian Express, níbi tí ó ti di olóòtú Saturday Guardian. Ní ọdún 1999, ní ìbẹ̀ẹ̀rè ìwé-ìròyìn Comet, wọ́n yàn án sípò aṣáájú-ọ̀nà olóòtú ìwé ìròyìn.

Ní ọdún 2006, ó tún di olóòtú aṣáájú-ọ̀nà ti ìwé-ìròyìn The Nation. Ó ti ṣètọ́jú ìwé kan "Àkọsílẹ̀ Olóòtú" ní The Nation, níbi ti ó ti kọ̀wé lórí àwọn ọ̀ràn inú ìlú, látàri lílo ọ̀nà àwàdà láti fi ṣàfihàn àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ náà.[7] Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Nigeria Guild of Editors (NGE) àti Nigeria Union of Journalist (NUJ).[8]

Ó jẹ́ olùfẹ́ eré-ìdárayá lọ́pọ̀lọpọ̀, pàápàá jù lọ bọ́ọ̀lù àfọwọ́gbá. Ó ti ní láti fi ẹ̀bùn rẹ̀ hàn níbi ìṣàfihàn kan tó ti bá bọ́ọ̀lù náà pẹ̀lú akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ agbábọ́ọ̀lù tó wà ní ipò ogún lágbàáyé, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Aruna Quadri, tí ó sì ṣe dáadáa.[9]

Àtòjọ àmì-ẹ̀yẹ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Omotoso ti gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àmì-ẹ̀yẹ fún iṣẹ́ títayọ rẹ̀ nínú iṣẹ́ ìròyìn. Díẹ̀ nínú àwọn àmì-ẹ̀yẹ náà ni; àmì-ẹ̀yẹ ti Dame ní ọdún 2010, àmì-ẹ̀yẹ ti Nigeria Media fún olóòtú tó dára jù lọ ní ọdún 2013, àmì-ẹ̀yẹ Nigeria Media Merit fún olóòtú tó dára jù lọ ní ọdún 2015, àti àmì-ẹ̀yẹ Nigeria Media Merit fún olóòtú tó dára jù lọ ní ọdún 2017.[10]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. "LIST: Lagos State Commissioners and Special Advisers – 2019 – 2023". Premium Times Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). August 21, 2019. Retrieved 2022-09-20. 
  2. "Former The Nation Editor Gbenga Omotosho sworn-in as Lagos Commissioner for Information" (in en-US). Marketing Edge Magazine. August 20, 2019. https://marketingedge.com.ng/former-the-nation-editor-gbenga-omotosho-sworn-in-as-lagos-commissioner-for-information/. 
  3. Aderinola, Tayo (July 2, 2020). "Gbenga Omotoso: A Veteran Journalist par excellence". Lagos Panorama (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-20. 
  4. Kehinde, Seye (January 27, 2020). "I Have Enjoyed Moving From Journalism To Public Service – LAGOS Info Comm., GBENGA OMOTOSO". City People Magazine (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-20. 
  5. Kehinde, Seye (January 27, 2020). "I Have Enjoyed Moving From Journalism To Public Service – LAGOS Info Comm., GBENGA OMOTOSO". City People Magazine (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-20. 
  6. "MR. GBENGA OMOTOSO – HONOURABLE COMMISSIONER". Ministry of Information & Strategy (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-20. 
  7. "Who edits The Nation?". Media Career Services (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). August 5, 2019. Retrieved 2022-09-20. 
  8. "Gbenga Omotoso Grows Tall". Independent Newspaper Nigeria. Retrieved 2022-09-20. 
  9. Anwankwo, Akan (August 17, 2021). "Lagos information commissioner Omotoso competes with Quadri in table tennis game". SportsBrief – Sport news. (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-20. 
  10. "MR. GBENGA OMOTOSO – HONOURABLE COMMISSIONER". Ministry of Information & Strategy (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2022-09-20.