Jump to content

Olufemi Adebanjo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Honourable
Olufemi Adebanjo
Ọjọ́ìbí12 Oṣù Kẹfà 1961 (1961-06-12) (ọmọ ọdún 64)
Ìlú Èkó
Ọmọ orílẹ̀-èdèỌmọ orílè-èdè Nàìjíríà
Iṣẹ́Olóṣèlú
Political partyAll Progressives Congress (APC)

Olufemi Adebanjo (ojoibi June 12, 1961) je oloselu omo orile-ede Naijiria ti o sise gẹ́gẹ́ bi ọmọ ile ìgbìmò asofin ijoba apapo ni ile ìgbìmọ̀ asofin agba orile-ede Naijiria 9th to n soju àgbègbè Alimosho labe egbe oselu All Progressives Congress ki Ayuba Ganiyu Adele lepo. O jẹ Igbakeji Alaga ti Ìgbìmò Ìdàgbàsókè igberiko ni Ile Awọn Aṣoju 9th titi di May 2023.[1][2]

Ìgbà èwé àti ìrínàjò iṣẹ́ rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n tọ́ Olufemi Adebanjo dàgbà ní ìlú Èkó, ní orílè-èdè Nàìjíría.[3] Ní ọdún 1980, ó gbà ìwé ẹ̀rí ilé-ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga Methodist, lẹ́yìn náà ó lọ sí ilé ìwé gíga Yunifásítì City University, ní ìlú New York (US) ó sì gba ìwé ẹ̀rí bachelor nínú ìmọ̀ nípa ètò ọrọ̀ ajé.

Iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Adebanjo bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òṣèlú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú ní ọdún 1999 nígbà tí wọ́n yàn án sí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó gẹ́gẹ́bíi aṣojú àgbègbè Alimowo 01 lábẹ́ ètò ìṣèlú Alliance for Democracy (AD). Lẹ́yìn náà, ó di onírúurú ipò mú ní Ìpínlẹ̀ Èkó, títí bí iṣẹ́ akọ̀wé Àgbà ti Ìjọba Ìbílẹ̀ Alimosho ní ọdún 2003, Alága Ìjọba Ìbílẹ̀ Alimosho ní ọdún 2004, àti Olùdámọ̀ràn Pàtàkì sí Gómìnà lórí Ìdásílẹ̀ àti Ìdánilẹ́kọ̀ọ́ nígbà ìjọba gómìnà Babatunde Fashola ní ọdún 2007 sí ọdun 2011.[4]

Nínú ìdìbò ọdún 2015, ó díje fún ipò Aṣòfin Àpapọ̀ lábẹ́ òṣèlú All Peoples Congress (APC) ó sì borí, ó sì gbà ipò láti ṣojú fún agbègbè Alimosho ní ilé igbimọ aṣòfin àgbà.[5]

Nínú ìdìbò Ilé Aṣòfin Nàìjíríà ní ọdún 2019 ní Èkó, ó ṣẹ́gun olùdíje ti ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party (PDP), Akinwale Akinsanya, àti àwọn olùdíje ẹgbẹ́ mẹ́rìnlá mìíràn láti dúró ní ipò rẹ̀ ní Ilé Aṣòfin Àpapọ̀ fún ìgbà kejì.[6]

Adebanjo dábàá ìgbésẹ̀ kàn nípa ìṣẹ̀lẹ̀ iná tó ṣẹlẹ̀ ní agbègbè tinsójú fún, èyí tó yọrí sí pípadánù ẹ̀mí márùn-ún. Ohun tó fa ìṣẹ̀lẹ̀ iná náà ni bí àwọn ọ̀daràn ṣe ba ọ̀nà epo jẹ́ tí wọ́n fi dé ọ̀dọ̀ àwọn ọlọ́pàá tí wọ́n sì tún dáàbò bò ó nígbà tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ àìtọ́ náà.[7][8]

  1. "Olufemi Adebanjo". ShineYourEye. Retrieved 2023-03-23.[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  2. "Chairmen and Deputies of Standing and Special Committees in the 9th House of Representatives" (PDF). PLAC. July 2019. Archived from the original (PDF) on 2023-06-14. Retrieved 2023-03-23.
  3. "National Assembly | Federal Republic of Nigeria". nass.gov.ng. Retrieved 2023-03-24.
  4. "Chairmen and Deputies of Standing and Special Committees in the 9th House of Representatives" (PDF). PLAC. July 2019. Archived from the original (PDF) on 2023-06-14. Retrieved 2023-03-23.
  5. "Biography Of Olufemi Adebanjo". Media Nigeria. 2018-06-07. Retrieved 2023-03-23.
  6. "Reps: APC wins in Alimosho, no winner declared in Somolu". The Eagle. 2019-02-25. https://theeagleonline.com.ng/reps-apc-wins-in-alimosho-no-winner-declared-in-somolu/.
  7. "National Assembly | Federal Republic of Nigeria". www.nass.gov.ng. Retrieved 2023-03-24.
  8. "Several feared killed as pipeline explodes in Alimosho". Channels TV. 2019-12-05. https://www.channelstv.com/2019/12/05/breaking-several-feared-killed-as-pipeline-explodes-in-alimosho/.