Jump to content

Oluwole

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Olúwọlẹ̀
Èkó
1837 - 1841
Adele
Akitoye
Father Adele
Born Lagos
Died Ọdún 1841
Lagos
Burial Lagos
Religion Ifá

Ọba Olúwọlé ( tí ó kú lọ́dún 1841) jẹ́ ọba ìlú Èkó láti ọdún 1837 sí 1841. Bàbá rẹ̀ ni Ọba Adele.[1]

Ìjà orogún pẹ̀lú Kọsọ́kọ́[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìbẹ̀rẹ̀ ìjà orogún Ọba Olúwọlé àti ọmọba Kòsọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ nípa dúdupò Ọba Èkó lẹ́yìn tí Ọba Àdèlé kú.[2] Nígbà tí Olúwọlé di Ọba, ó lé àbúrò Kọsọ́kọ́, Opo Olú kúrò ní ìlú Èkó, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé adífá dá a láre ẹsùn wíwà nínú ẹgbẹ́ àjẹ́ tí wọ́n fi kàn án.[3] Síwájú sí i, nígbà tí Kọsọ́kọ́ paná ogun Ewé Kókò,[4] Olúwọlé rán Balógun rẹ̀, Yesufu Badà níjà ogun láti lọ kó ìkógun tí Kòsọ́kọ́ kó lójú ogun.[5]

Ikú rẹ̀ láti ara àṣìta ìbọn-olóró[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Olúwọlé kú lọ́dún 1841 nígbà tí sísán àrá fàá tí àgbá àdó-olóró l'áàfin Ọba fi dún gbàmù. Gbogbo ẹran ara Olúwọlé ló fọ́n túká káàkiri, débi pé ilẹ̀kẹ̀ oyè rẹ̀ ní kan ni wọ́n fi dá a mọ̀.[3]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Mann, Kristin (2007). Slavery and the Birth of an African City: Lagos, 1760-1900. Indiana University Press, 2007. p. 45. ISBN 9780253348845. 
  2. Fasinro, Hassan Adisa Babatunde. Political and cultural perspectives of Lagos. University of Michigan. p. 61. 
  3. 3.0 3.1 Mann, Kristin (2007-09-26). Slavery and the Birth of an African City: Lagos, 1760--1900. Indiana University Press, 2007. pp. 47–48. ISBN 9780253117083. 
  4. Smith, Robert (January 1979). The Lagos Consulate, 1851-1861. University of California Press, 1979. pp. 14–17. ISBN 9780520037465. 
  5. Yemitan, Oladipo. Madame Tinubu: Merchant and King-maker. University Press, 1987. p. 8.