Sola Sobowale

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Ṣọlá Ṣóbọ̀wálé
Ọjọ́ìbí26 Oṣù Kejìlá 1963 (1963-12-26) (ọmọ ọdún 60)
Ìpínlẹ̀ Oǹdó, Nàìjíríà
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Ọmọ orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Iṣẹ́
  • òǹkọ̀wé
  • òṣèré
  • adarí eré
Parent(s)Joseph Olagookun, Esther Olagookun

Ṣọlá Ṣóbọ̀wálé tí wọ́n bí ní ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kejìlá, ọdún 1963, jẹ́ òṣèré sinimá àti adarí eré ti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. [1] Ó di olókìkí ní ọdún 2001, nínú ìṣàfihàn ti Ìtàn-àkọọ́lẹ̀ Super Story  : Oh Father, Oh Daughter.

Iṣẹ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ó dara pọ̀ mọ́ eré orí ìtàgé nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn fíìmù tí Ẹgbẹ́ Awada Kẹrikẹri ṣe lábẹ́ adarí Adébáyọ̀ Sàlámì . [2] Láàárín ọdún díẹ̀, ó ti ṣe iṣẹ́ akọ̀wé, ìtọ́sọ́nà àti ìgbéjáde ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn fíìmù Nàìjíríà. [3] Ó ṣe akọ̀wé, àgbékalẹ̀ ati ìtọ́sọ́nà, Ohun Oko Somida, fíìmù Nàìjíríà kan tí ó jáde ní ọdún 2010 èyí tí ó ṣe ìràwọ̀ Adébáyọ̀ Sàlámì . [4] Ó ṣe ìfihàn nínú Dangerous Twins, fíìmù ti Nàìjírà tí ó jáde ní ọdún 2004 tí Tádé Ògìdán ṣe, ẹni tó kọ fíìmù yìí ni Níji Àkànní . [5] Ó tún ṣe ìfihàn nínú Family on Fire ìṣelọ́pọ̀ ati ìtọ́sọ́nà nípasẹ̀ Tádé Ògìdán . [6]

Ìgbésí Ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Sola Sobowale jẹ́ ìyàwó Dotun Sobowale. Ó bí ọmọ mérin fún ọkọ rẹ̀.[7]

Àwọn àmì ẹ̀yẹ[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ọdún 2019, ó gba àmì ẹ̀yẹ African Academy Academy (AMAA) fún Òṣèré tó dára jù lọ fún ipá rẹ̀ ní fíìmù King of Boys tó jáde ní ọdún 2018.

Àwọn àṣàyàn eré rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Òṣèré[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Olóòtú[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Àwọn Ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]