Jump to content

Solomon Lar

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Solomon Daushep Lar
Fáìlì:Photo of Chief (Dr.) Solomon Daushep Lar.jpeg
Member of the Federal Parliament
In office
January 1960  January 1966
ConstituencyLowland East
Governor of Plateau State
In office
1 October 1979  31 December 1983
AsíwájúJoshua Anaja
Arọ́pòSamuel Atukum
Minister of Police Affairs
In office
November 1993  1994
National Chairman of People's Democratic Party
In office
1998–2002
AsíwájúPosition established
Arọ́pòBarnabas Gemade
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí(1933-04-04)4 Oṣù Kẹrin 1933
Langtang, Northern Region, British Nigeria (now in Plateau State, Nigeria)
Aláìsí9 October 2013(2013-10-09) (ọmọ ọdún 80)
United States
(Àwọn) olólùfẹ́Prof. Mary Lar; eldest daughter, Dr. Chalya Lar

Olóyè (Dr.) Solomon Daushep Lar (a bi ni ọjọ́ kẹrin, oṣù kẹrin ọdún1933 o jáde laye ní ọjọ́ kẹsàn-án oṣù kẹwàá ọdún 2013) (Walin Langtang) jẹ́ olóṣèlú ní Nàìjíríà tí ó ti ṣàkóso àwọn ọfiisi oriṣiriṣi nì orílẹ̀-èdè fún bíi àádọ́ta ọdún ó lé. Ó wà lára àwọn ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin orílẹ̀-èdè àkọ́kọ́ nígbà tí Nàìjíríà gba òmìnira ní ọdún 1960. A yàn-án sí ipò gómìnà ìpínlẹ̀ Plateau lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú Nigeria People's Party NPP lábẹ́ ìjọba alájùmọ̀ṣe kejì ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, láti Oṣù Kẹwàá ọdún 1979 títí di ìdìtẹ̀gbàjọba àwọn ọmọ ológun tí ó wáyé ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbàn Oṣù kejìlá ọdún 1983 tí ó mú kí Ọ̀gágun Muhammadu Buhari di olórí orílẹ̀ èdè. Nígbà tó yá, ó di ààrẹ ìgbìmọ̀ tí ó dá ẹgbẹ́ òṣèlútó People's Democratic Party (PDP) sílẹ̀.

Bíbí àti Ìgbà Èwe rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí Lar ní Pangna, Langtang, Ìpínlẹ̀ Plateau ní Oṣù Kẹrin ọdun 1933. Àgbẹ̀ ni bàbá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ amọ̀kòkò. Ó kẹ́kọ̀ọ́ ní Ilé Ẹ̀kọ́ alákǎbẹ̀rẹ̀ ti Sudan United Mission ní Langtang, lẹ́yìn náà ó lọ sí Gindiri Teachers College níbi tó ti gba ìwé ẹ̀rí láti kọ́ni ní Ilé Ẹ́kọ́ Alákọ̌bẹ̀rẹ̀, Langtang. Lẹ́hìn ọdún méjì ó padà sí Gindiri fún ìkẹ́kọ̌ làti di olùkọ́ àgbà, gba ìwé-ẹ̀rí olùkọ́ ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̌bẹ̀rẹ̀ ìpele gíga rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ni ní ìpele giga ti ilé ìwé alákọ̌bẹ̀rẹ̀. [1] Ó pinnu láti di àlùfáà.

Lar di agbẹnusọ fún agbègbè Abínibí rẹ̀ tíí ṣe Langtang ní Oṣù Kínní ọdún 1959. Ní ọjọ́ kejìlá Oṣù kejila ọdún 1959 a dìbò yàń sí Ilé-ìgbìmọ̀ ti ìjọba àpapọ̀ lórí pẹpẹ ti United Middle Belt Congress (UMBC). A tún dìbò yàń ní ìgbà kejì ní ọdún 1964, láti ìgbà náà títí di ọjọ́ karùndínlógún Oṣù Kínní ọdún 1966, nígbàtí Ọ̀gágun Yakubu Gowon dìtẹ̀ gbàjọba, Lar jẹ́ akọ̀wé ilé aṣòfin fún olórí ìjọba Abubakar Tafawa Balewa. Ó tún jẹ́ alákǒso kékeré fún ilé iṣẹ́ ìjọba àpapọ̀ tó ń rísí ọ̀rọ̀ ìṣẹ̀dálẹ̀.

Lẹ́yìn tí ìjọba ìjọba olómìnira ṣubú, Lar lọ sí Yunifásítì Ahmadu Bello, Zaria, ó sì gba ẹ̀rí agbẹjọ́rò (LLB) lọ́dún 1970 ó sì di agbẹjọ́ro gbòógì lọ́dún 1971. Ó dá ilé iṣẹ̀ òfin aládǎni ti ẹ̀ sílẹ̀, ó sì jẹ́ olùjùmọ̀dásílẹ̀ àti akọ̀wé àkọ́kọ́ fún ẹgbẹ́ àwọn agbẹjọ́ro ní orìlẹ̀-èdè Nàìjíríà. [2]

Lọ́dún 1972, Lar dara pọ̀ mọ́ ìgbìmọ̀ tó ń bójú tó àgbájọ àwọn tó ń wa kùsà ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ó di alága ìgbìmọ̀ alákǒso ti African Continental Bank, ọmọ ẹgbẹ́ ti Nigeria Council of Legal Education àti ọmọ ẹgbẹ́ ti Ile-igbimọ ti o ṣe idiwọ (1977-1978). Ó jẹ́ igbákejì alága ìgbìmọ̀ tí Adájọ́ Ayọ̀ Irikefe darí èyí tí ó ń ṣàlàyé ṣíṣe àfikún àwọn ìpínlẹ̀ láti méjìlá sí ókàndínlógún lábẹ́ ìjọba ológun Murtala Muhammed ati Olusegun Obasanjo. Lar tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ tí ó ń rìsí ọ̀rọ̀ Agbègbè fún ilẹ̀ Áfíríkà èyí tí ó wà ní ìlú AMẸ́RÍKA.

Ìjọba Olómìnira Kejì àti Ìkẹta

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ìbẹ̀rẹ̀ ti ìjọba olómìnira Kejì, Lar jẹ́ olùjùmọ̀dásílẹ̀ Ẹgbẹ́ àwọn ènìyàn Nàìjíríà NPN. A yàn-án gẹ́gẹ́ bíi olùdíje fún ipò ààrẹ Nàìjíríà lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ náà ní ọdún 1978, lẹ́yìn náà ó yege láti di gomìnà ìpínlẹ̀ Plateau ní ọjọ̀ kìnní oṣù kẹwàá ọdún 1979, èyí sì mu kó di gómianà àkọ́kọ́ tí wọ́n dìbò yàn ní ìpínlẹ̀ náà. Àlhájì Aliyu Akwe Doma ni igbákejì rẹ̀. Ó kó ipa ribiribi nínú kíkọ́ àwọn oun amáyédẹrùn ní ìpínlẹ̀ náà fún bí àpẹẹrẹ; ilé ìwòsàn, ilé ẹ̀kọ́, lílo iná mànàmáná ní ìgbèríko, ìpèsè omi àti àwọn ọ̀nà. Ó ṣe àtúnṣe ìwé òfin ìgbanisíṣẹ́ ti ípínlẹ̀ náà, tí ó fagilé owó ọ̀yà ojoojúmọ́ àti iṣẹ́ àgbàṣe ati fífún àwọn ìyálọ́mọ tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ bímọ ní ìsinmi àti owó fún gbogbo ìgbà tí wọ́n bá fi wà ní ilé.

Lẹ́yìn ìdìtẹ̀ gbàjọba àwọn ọmọ ológun ní oṣù kejìla ọdún 1983, Ọ̀gágun Muhammadu Buhari dá ilé ẹjọ́ ológun sílẹ̀ tí wọ́n ń gbé gbogbo àwọn gómìnà tí wọ́ n jẹ́ tẹ́lẹ̀ wò. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ò rí Lar fun ìkówójẹ tàbí lílo owó ìlú lọ́nà àìtọ́, wọ́n dá a lẹ́jọ́ wọ́n sì ran lọ sí ẹ̀wọ̀n láti lo ọdún méjìdínláàádọ́rin, àkọ́kọ́ ní ìlu Jos kí wọ́n tó wá gbe lọ sí Kiríkirì ní ìlú Èkó. A ṣe àtúnyẹ̀wò ọ̀ran rẹ̀ àti pé ìjọba ti Ọ̀gágun Ibrahim Babangida tú u sílẹ̀, ẹnití ó bẹ̀rẹ̀ ìyípadà miiràn sí ìjọba alágbádá ní ọdún 1992. [1]

Nígbà ìjọba olómínira kẹta ní Nàìjíríà, Lar jẹ alátìlẹyìn ẹgbẹ́ òṣèlú Social Democratic Party (SDP). A yàn án gẹ́gẹ́ bí alákòóso fún ọ̀rọ̀ àwọn Ọlọ́pàá lábẹ́ ìjọba Ọgágun Sani Abacha, ó sì fi iṣẹ́ sílẹ̀ nígbà tó rí i pé Abacha kò fẹ́ dá ìjọba alágbádá padà.

Ìjọba Olómìnira Kẹrin

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ní ìyípadà sí ìjọba olómìnira kẹrin ti Nàìjíríà, Lar di Alákòóso àkọ́kọ́ fún Ẹgbẹ́ Òṣèlú ti People's Democratic People (PDP) ní ọdún 1998, ó wà ní ipò yìí títí di ọdún 2002 nígbàtí ó gbé ìṣàkóso fún Barnabas Gemade. Ní Oṣú Kejì ọdún 2004 ó kọ̀wé fi ipò rẹ̀ sílẹ̀ bíi alága Igbimọ ẹgbẹ́ òṣèlú PDP, ó gbé ìṣàkóso lé Olóyè Tony Anenih lọ̀wọ̀ ní ìgbìmọ̀pọ̀ kan ní ìlú Abuja. Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ògúnnángbòǹgbò ẹgbẹ́ òṣèlú PDP títí di ọdún 2005, nígbàtí ó ṣe àtìlẹyìn fún Igbákejì ààrẹ Atiku Abubakar nínú ìtàpórógan tí ó wáyé laàrín òhun àti ọ̀gá a rẹ̀ èyíinì ààrẹ Olusegun Obasanjo, lẹ́yìn èyí, ó ṣe àtìlẹyìn fún Atiku láti du ipò ààrẹ ní ọdún 2007. [3] Ní Oṣù Kẹrin ọdun 2006, Lar tún ṣe ìtẹ́wọ́gbà ìpinnu ààrẹ ológun tẹ́lẹ̀, Ọ̀gágun Ibrahim Babangida láti díje fún ipò ààrẹ nínú ètò ìdìbò tí ó wáyé ní ọdún 2007, ó sọ pé nínú ìjọba àwarawa ẹnikẹ́ni ní ẹ̀tọ́ láti díje fún ipò tí ó bá wùú.

Lar ni a mọ̀ gẹ́gẹ́ bíi onígbọ̀wọ́ gbóògì fún abala ààrin gbùngbùn Nàìjíríà, ó kó ipa takuntakun ní abala àwọn ẹ̀yà yìí. Ní ìpínlẹ̀ Plateau, ó ṣe àtìlẹyìn tó lóòrìn fún ètò lórí bí ìjọba ìpínlẹ̀ náà yó ṣe ran àwọn ojúlówó ọmọ bíbí ìpínlẹ̀ náà lọ́wọ́ láti ṣe ìmúlò àwọn àǹfàní tí ó wà níbi òmìnira tí wọ́n gbà lọ́wọ́ ìjẹgàba àwọn Hausa, àti pé àwọn agbègbè Hausa Jarawa àti Yelwa tí ó ti pẹ́ ní Jos ni wọn kò gbọdọ̀ kà gẹ́gẹ́ bí àwọn ojúlówó ọmọ ìpínlẹ náà. Nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ kan ní oṣù kejì ọdún 2009, ó sọ pé àwọn ẹ̀yà Àárín Gbùngbùn ni wọ̀n ti tanù láì náání ipa ribiribi tí wọ́n kó nínú ìṣọ̀kan àti pàápàá jùlọ ogun abẹ́lé ní Nàìjíríà. Ó tún ń ṣàlàyé nípa ìyàsọ́tọ̀ sí àwọn ẹlẹ́sin Krìstìáni ní apá àríwá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ó le débi wípé wọn kìí fúnwọn nílẹ̀ láti kọ́ ilé ìjọsìn sí.

Ní oṣù kejì ọdún 2010 igbákejì ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà Goodluck Jonathan yàn án gẹ́gẹ́ bí Alága Ìgbìmọ̀ Ààrẹ tí a gbé kalẹ̀ láti ṣọ àwọn ọ̀nà tí a lè gbà láti dẹ́kun wàhálà tí ó ń fi ìgbà gbogbo ṣẹlẹ̀ ni Jos, olú-ìlú ìpínlẹ̀ Plateau.[4]

Ní ọjọ́ kẹsàn-án oṣù kẹwàá ọdún 2013, gómìnà ìpínlẹ̀ Plateau, Jonah David Jang kéde ikú Ọ̀gbẹ́ni Lar. Ó kú ní ilé ìwòsàn kan ní Amẹ́ríkà lẹ́yìn àìsàn tó pẹ́, ó jẹ́ ẹni ọgọ́rin ọdún nígbà tó jáde láyé.

Àwọn Ìtọ́kasi

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. 1 2 . London. Missing or empty |title= (help); [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  2. Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid <ref> tag; no text was provided for refs named vang693
  3. Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid <ref> tag; no text was provided for refs named nation42285
  4. Empty citation (help)