Yorùbá Academy

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Àjọ Yorùbá Academy ni àjọ tí ó kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpele ékọ́ àti àkójọpọ̀ àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n nínú ìmọ̀ òṣèlú, okòwò àti àwọn onímọ̀ akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ nípa èdè Yorùbá, àṣà ètò ọrọ̀-ajé, ofin, sáyẹ́nsì àti ìmọ̀ tẹkinọ́lọ́jì, àti ìmọ̀ ètò ìṣèjọba. Wọ́n dá àjọ yí sílẹ̀ ní ìlú Ìbàdàn, ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ , orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní oṣù Kẹ́wàá ọdún 2007, lẹ́yìn tí àwọn ọ̀dọ́ akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ nínú àwọn ìmọ̀ tí a ti mẹ́nu bà pinu láti padà sórílẹ̀-èdè baba wọn, tí ẹgbẹ́ Afẹ́nifẹ́re Renewer Group ń ṣàkóso rẹ̀. Ohun tí ó jẹ́ ìlépa wọ́n ni láti dá àbò àti láti tọ́jú èdè Yorùbá pàá pàá jùlọ àṣà àwùjọ àti ìdàgbàsókè àwọn ọmọ Yorùbá nílé àti loke okun.

Nínú ìlépa wọn ni kí wón ma ṣe àkóso iwe Atúmọ̀ èdè Yorùbá láti lè fi ẹsẹ̀ èdè Yorùbá múlẹ̀ láàrín èdè tó kú lágbàáyé.

Ibi tí àwọn ọmọ Yorùbá wà ilẹ̀ Adúláwọ̀: in Togo, Benin, Sierra Leone àti apá kan nílẹ̀ Ghana

Ibi tí àwọn ọmọ Yorùbá wà yàtọ̀ sí ilẹ̀ Adúláwọ̀:Haiti, Cuba, Puerto Rico, Brazil, United States, UK, [(Ireland)]

Àwọn ìtàkùn ìjásóde[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]