AbdulRahman AbdulRasaq
| It has been suggested that this article be merged with Àdàkọ:Pagelist. (Discuss) |
Abdulrahman Abdulrazaq | |
|---|---|
| Gómìnà ìpínlẹ̀ Kwara | |
Lọ́wọ́lọ́wọ́ | |
| Ó gun orí àga 29 May 2019 | |
| Deputy | Kayode Alabi |
| Asíwájú | Abdulfatah Ahmed |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 5 Oṣù Kejì 1960 Zaria, Northern Nigeria|Northern Region, British Nigeria (now in Kaduna State, Nigeria) |
| Ẹgbẹ́ olóṣèlú | All Progressives Congress (APC) |
| (Àwọn) olólùfẹ́ | Olufolake Davies |
| Occupation | Politician |
| Website | Campaign website |
AbdulRahman AbdulRazaq (tí a bí ní ọjọ́ karún oṣù Kejì ọdún 1960) jẹ́ olósèlú ará Nàìjíríà, ẹni ti o ti nṣe gómìnà ipinlẹ̀ Kwara láti odun 2019 titi di ìsín. [1][2]
Ó jẹ́ ẹni tí ó ti jẹ́ Alákóso (CEO) First Fuels Limited nígbà kan rí.[3] Ó ti gbìyànjú lálái wọlé gẹ́gẹ́ bí olùdíje fún Gómìnà Ìpínlẹ̀ Kwara ní ọdún 2003, 2007 àti 2011 lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú Congress for Progressive Change (CPC), ṣùgbọ́n kò wọlé ní àwọn àkókò wọ̀nyí. Bukola Saraki ló borí rẹ̀ ní ọdún 2003 àti 2007, nígbà tí Abdulfatah Ahmed sì jáwé olúborí ní ọdún 2011.[4] Síbẹ̀, ní ọdún 2019, ó tún jáde lẹ́ẹ̀kan síi lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC), ẹgbẹ́ olóṣèlú alákòóso ní Nàìjíríà, ó sì jáwé olúborí nínú ìdìbò gómìnà ọdún 2019 nípínlẹ̀ Kwara, ó sì di Gómìnà Ìpínlẹ̀ Kwara.[5] Ní ọdún 2021, ó ṣe àfihàn KwaraLEARN ní ẹ̀kọ́ ìbílẹ̀ láti kún àwọn olùkọ lọ́wọ́.[6] Ní oṣù kàrún ọdún 2023, nígbà tí KwaraLEARN pé ọdún kan, ó sọ pé ètò yìí jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìlànà tó dára jù lọ tí ó ti ṣe rí.[7] Ní ọjọ́ kínní Ọ̀ṣù Kọkànlá, ọdún 2023, òun pẹ̀lú àwọn gómìnà mẹ́fà míì wà pẹ̀lú Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu ní ìrìnàjò lọ sí Orílẹ̀-Èdè Benin fún ayẹyẹ ọjọ́ òmìnira wọn ọdún kẹtàlélọ́gọ́ta (63rd).
Igbesi aye ibẹrẹ
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Won bi ni ìpínlẹ̀ Kanu. AbdulRahman jẹ́ ọmọ Alh. Abdulganiyu AbdulRazaq SAN. , agbẹjọro ariwa akọkọ ni Nigeria.[8]
Ó lọ sí ile-ẹ̀kọ́ Capital School, Kaduna láàárín ọdún 1966 sí 1968; lẹ́yìn náà, ó lọ sí Bishop Smith Memorial School ní Ilorin láàárín ọdún 1970 sí 1971; ó tún lọ sí Government College, Kaduna, níbi tí ó ti gba ìwé-ẹ̀rí ìdánwò ìyàtọ̀ ilé-ẹ̀kọ́ gíga (WASSCE) ní ọdún 1976.[9]
Iṣẹ-ṣiṣe
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Oselu
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ọdún 1999 ló darapọ̀ mọ́ òṣèlú nígbà ti Nàìjíríà padà si inú ìjọba tiwantiwa. Ni ọdún 2011, kò yege fun un láti díje du ipò Gómìnà ni Ìpínlẹ̀ Kwara lábẹ́ ẹgbẹ òṣèlú Congress for Progressive Change (CPC) [10] o si tun dije laibobo fun Kwara Central Senatorial District ni egbe Peoples Democratic Party (PDP) ni odun 2011 ati Ọdun 2015.[11] O bori ninu idibo alakọbẹrẹ gomina ti Gbogbo Progressive Congress fun Ipinle Kwara ni Oṣu Kẹwa ọdún 2018. [12]
Wọ́n di bo yàn án gẹ́gẹ́ bí gómìnà ìpínlẹ̀ Kwara níbi ìdìbò gómìnà ọdún 2019 tí ó wáyé ní ọjọ́ kẹsàn-án oṣù kẹta ọdún 2019[13] tí wọ́n sì búra ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù karùn-ún ọdún 2019. Ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù Kẹta, ọdún 2023, Abdulrahman Abdulrazaq ni wọ́n kede gẹ́gẹ́ bí ẹni tó tún jáwé olúborí níbi ètò ìdìbò Gómìnà ìpínlẹ̀ Kwara lẹ́lẹ́kejì, níbi tí ó ti ṣẹ́gun alatako rẹ̀ to súnmọ́ jùlọ, Yaman Abdullahi, ti Ẹgbẹ́ People's Democratic Party (PDP), lẹ́yìn tí ó kó púpọ̀ jùlọ nínú àwọn ibò[14].
Ni ọjọ kẹrinlélógún, Oṣù Kaàrún ọdún 2023, o di alága tuntun ti Àpéjọ Àwọn Gómìnà Nàìjíríà ní ìpàdé àti lẹ̀kùn mọn tí àwọn Gómìnà ti o wáyé ní Abuja ti o tẹle Gómìnà ti tẹ́lẹ̀ ti Ìpínlẹ̀ Sokoto, Aminu Tambuwal, ti o di alága ní ọdún 2022[15], pẹ̀lú Gómìnà ipinle Oyo, Seyi Makinde gẹ́gẹ́bí igbákejì alága[16].
Ìgbé-ayé ti ara ẹni
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ó fẹ́ Ọ̀jọ̀gbọ́n Olúfọlákẹ́ Molawa Davies Abdulrazaq (tí a bí ní ọjọ́ keji, oṣù kẹjọ, ọdún 1967), wọ́n sì ní ọmọkùnrin mẹ́ta[17].
Awọn itọkasi
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ https://thenationonlineng.net/abdulrazaq-bags-governor-of-the-year-award/amp/
- ↑ https://www.vanguardngr.com/2023/04/kwara-what-aided-abdulrazaqs-re-election-how-late-alliances-failed/
- ↑ https://www.thisdaylive.com/index.php/2018/10/14/hope-rising-for-oil-magnate-abdulrahman-abdulrazaq/
- ↑ https://web.archive.org/web/20190310230201/http://voteabdulrahman.com/biography
- ↑ https://www.vanguardngr.com/2019/03/abdulrahman-wins-kwara-governorship-election/
- ↑ https://www.thisdaylive.com/index.php/2021/11/04/abdulrazaq-introduces-kwaralearn-to-revolutionise-basic-education/
- ↑ https://kwaralearn.ng/kwaralearn-remains-my-best-policy-ever-gov-abdulrazaq/
- ↑ https://justeventsonline.blogspot.com/2018/10/brief-history-about-kwara-state-apc.html
- ↑ https://businessday.ng/politics/article/certificate-scandal-school-mates-clarify-abdulrahman-abdulrazaq/
- ↑ https://thenationalpilot.ng/real-reasons-abdulrahman-abdulrazaq-emerged-kwara-apc-guber-candidate/%5B%5D
- ↑ https://www.vanguardngr.com/2018/10/abdulrazaq-abdulrahaman-the-new-man-on-the-block-in-kwara/
- ↑ Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid
<ref>tag; no text was provided for refs named:1 - ↑ https://theinformant247.com/inec-announces-apcs-abdulrahaman-abdulrazaq-the-winner-of-kwara-guber-poll/
- ↑ https://punchng.com/abdulrazaq-wins-re-election-as-kwara-gov/
- ↑ https://punchng.com/abdulrazaq-emerges-new-ngf-chairman/
- ↑ https://punchng.com/abdulrazaq-emerges-ngf-chair-makinde-vice-chair/
- ↑ https://web.archive.org/web/20210303140212/https://www.newsdiary.com.ng/2020/02/05/icpc-summons-kwara-govs-wife-olufolake-8-others-over-corruption-allegations/