Bíńtà Bello

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Fatima Bíńtà Bello
Deputy Minority Whip tẹ́lẹ̀ nílé ìgbìmọ̀ aṣojú-ṣòfin Nàìjíríà
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
May 29, 2015
ÀàrẹMuhammadu Buhari
OlóríYakubu Dogara
AsíwájúAdamu Gora Kalba
ConstituencyẸkùn ìdìbò Kaltungo/Shongom
Ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣojú-ṣòfin tẹ́lẹ̀ fún ẹkùn ìdìbò Kaltungo/Shongom
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
2011
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí1970
gbuzo|Igbuzo, Ìpínlẹ̀ Delta [1]
Ọmọorílẹ̀-èdèỌmọ Nàìjíríà
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeople's Democratic Party
(Àwọn) olólùfẹ́usman Mustapha Bello
Àwọn ọmọ2
ResidenceAbuja, Nàìjíríà
Alma materUniversity of Maiduguri [2]
OccupationÒṣèlú-bìnrin
ProfessionOlùkọ́, òṣèlú

Fatima Bíńtà Bello tí ó jẹ́ olùkọ́, kọmíṣánnà nígbà kan, tí ó sìn jẹ́ igbákejì ọlọ́pàá, Deputy Minority Whip, ilé igbimọ̀ aṣojú-ṣòfin, Nigerian House of Representatives tẹ́lẹ̀.[2] tí ó ń ṣojú ẹkùn ìdìbò Kaltungo/Shongom ti Ìpínlẹ̀ Gombe tẹ́lẹ̀, [3]jẹ́ gbajúmọ̀ òṣèlú-bìnrin ọmọ Nàìjíríà. Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party, PDP, Òun nìkan ni obìnrin tí ó wà nínú àwọn ìgbimọ̀ àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú tí ó wà ní ilé igbimọ̀ aṣojú-ṣòfin Nàìjíríà lásìkò rẹ̀.[3]

Ìgbésí ayé àti ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ láti ìbẹ̀rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Bíǹtà ní ìlú was born in IgbuzoÌpínlẹ̀ Delta lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ajagun-fẹ̀yìntì ni bàbá rẹ̀.[4] She moved all around the country before finally returning to her native Gombe State.[4][1]

Ó kàwé gboyè ìwé ẹ̀rí ònípele méjì (teachers grade II certificate) láti W.T.C Bajoga, ní Ìpínlẹ̀ Gombe lọ́dún 1988, àti ìwé ẹ̀rí Dípólómà nínú ìmọ̀ Ètò Àwùjọ (Public Administration) ní University of Jos lọ́dún 1995, [1] àti ìwé ẹ̀rí B.Sc. nínú ìmọ̀ Ètò láti University of Maiduguri lọ́dún 2010.[2]

Iṣẹ́[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọn yan Bíńtà gẹ́gẹ́ bí kọmíṣánnà fún ètò obìnrin ní Ìpínlẹ̀ Gombe lọ́dún 2007 sí 2010 .[4] Ó díje dùpò fún ilé ìgbìmọ̀ aṣojú-ṣòfin ti ẹkùn ìdìbò ìjọba àpapọ̀ ti Kaltungo/Shongom lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú People's Democratic Party, tí ó sìn wọlé.[4] Àwọn akẹgbẹ́ rẹ̀ obìnrin tí wọ́n tún wọlé ìdìbò nígbà náà lábẹ́ PDP ni Nnenna Elendu-Ukeje, Sodaguno Festus Omoni, Nkiruka Chidubem Onyejeocha, Rita Orji, Evelyn Omavovoan Oboro, Beni Butmaklar Langtang, Omosede Igbinedion Gabriella, Stella Obiageli Ngwu àti Eucharia Okwunna.[5]

Lọ́dún 2019, ó tún díje, ṣùgbọ́n ó pàdánù sọ́wọ́ akẹgbẹ́ tí ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress, Amos Bulus.[6]

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]