Jump to content

Bolaji Abdullahi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Bolaji Abdullahi
Mallam Bolaji Abdullahi, Former Minister of Youth Development, Federal Republic of Nigeria
Ọjọ́ìbíBolaji Abdullahi
Ẹ̀kọ́University of Lagos
University of Sussex
Iṣẹ́Politician
Writer

Bolaji Abdullahi (A bí ní ọdún 1969) jẹ́ olóṣèlú àti oǹkọ̀wé ọmọ ilẹ̀ Nàìjíríà láti Ìpínlẹ̀ Kwara. Ó wà nínú Ìgbìmọ̀ ti Alákóso orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tẹ́lẹ̀, lábẹ́ àkóso Goodluck Jonathan gẹ́gẹ́ bi Mínísítà fún Ìdàgbàsókè Ọ̀dọ́ ní oṣù keje, ọdún 2011 àti lẹ́hìn náà bíi Mínísítà ètò Ìdárayá.

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé àti ẹ̀kọ́

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Abdullahi kọ́ ẹ̀kọ́ gboyè lórí ìbáraẹnisọ̀rọ̀ láti ilé ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì èkó. Ní ọdún 2001, pẹ̀lú ètò ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ Chevening, Abdullahi fi orúkọ sílẹ̀ fún ikẹkọ ní ilé ẹ̀kọ́ fún iwadi ìdàgbàsókè (Institute of Development Studies) ní Yunifásítì ti Sussex níbi tí o ti kọ́ ẹ̀kọ́ gboyè gíga tí ó peregedé lori Ìṣèjọ́ba àti Ìdàgbàsókè (Governance and Development)

Ní ọdún 1997, Abdullahi darapọ̀ mọ́ ilé iṣẹ́ ìwé ìròhìn tí This Day gẹ́gẹ́ bí oníròhìn sùgbọ́n lẹ́hìn ọdún kan, Ó kúrò láti lọ darapọ̀ mọ́ Àpèjọ Alákòso Áfríkà (African Leadership Forum). Ó padà ní ọdún 2002 tí ó sì ní ìgbega sí ipò igbákejì olóòtú ti ìwé ìròhìn ní ọdún 2003. Lẹ́hìn náà, wọ́n kọ́kọ́ yan Abdullahi gẹ́gẹ́ bí olùránlọ́wọ́ pàtàkì fún Ìbáraenisọ̀rọ̀ àti Ìpín ýiká (Special Assistant Communication and Strategy) sí gómìnà Ìpínlẹ̀ Kwara tẹ́lẹ̀, Bukola Saraki ní ọdún 2003 lẹ́hìn náà ni ó wá di olùdámọ̀ràn pàtàkì lórí Ìmúlò àti ìpín yíká (Special Adviser on Policy and Strategy) ní ọdún 2005. Wọ́n yan Bolaji Abdullahi gẹ́gẹ́ bi kọmísọ́nnà fún ètò ẹ̀kọ́ àti ìmọ̀ ẹ̀rọ́ ti Ìpínlẹ̀ Kwara láti ọdún 2007 sí ọdún 2011. Ó tẹ̀ síwájú láti lọ sìn nínú ìgbìmọ̀ Minisita ti aàrẹ ilẹ̀ Nàìjíríà tẹ́lẹ̀, Goodluck jonathan nígbàtí wọ́n yàn án gẹ́gẹ́ bi Mínísítà fún ìdàgbàsókè ọ̀rọ̀ àwọn ọ̀dọ́ ní oṣù keje ọdún 2011. Lẹ́hìn naa34 ni wọ́n yàán gẹ́gẹ́ bi Minisita fún eré ìdárayá.

Ní oṣù kejìlá ọdún 2016, wọ́n kéde Abdullahi gẹ́gẹ́ bí akọ̀wé gbogboogbò ti orílẹ̀ (National Poblicity Secretary) fún ẹgbẹ́ onígbàálẹ̀ (All Progressive Congress). Ní ọjọ́ kìn-ní-ín, oṣù kẹjọ, ọdún 2018, Abdullahi finú fẹ́dọ̀ fí ìwé sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí akọ̀wé gbogboogbo tí ẹgbẹ́ onigbale (All Progressive Congress) tí ó sì kúrò nínú ẹgbẹ́ náà.

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

1. https://www.thisdaylive.com/index.php/2018/10/02/bolaji-abdullahi-seven-others-withdraw-from-kwara-pdp-guber-race/

2. https://punchng.com/ex-minister-laments-hardship/

3.https://www.thisdaylive.com/index.php/2018/03/02/bolaji-abdullahi-newly-inaugurated-boards-will-help-mdgs-navigate-political-difficulties/

4.https://punchng.com/i-like-doing-house-chores-to-encourage-my-sons-bolaji-abdullahi/

5,https://www.vanguardngr.com/2017/11/bolaji-abdullahi-a-liar-exposed-his-book-as-tissue-of-lies-jonathan/

6. http://saharareporters.com/2018/08/01/breaking-its-official-bolaji-abdullahi-resigns-apc

7.https://www.tammysenglishblog.com/2019/02/jambs-201920-english-novel-bolaji.html

8.https://www.basedonnews.com/download-pdf-bolaji-abdullahi-sweet-sixteen-16-jamb-novel-summary-likely-exam-questions-150-plus-answers-jamb-examination/

9.https://dailypost.ng/2018/08/01/breaking-apc-spokesman-bolaji-abdullahi-confirms-exit-party/

10.https://www.thecable.ng/payback-time-bolaji-abdullahi

11. https://dailypost.ng/2018/08/24/apc-ex-spokesman-bolaji-abdullahi-run-kwara-governor/

12.https://www.dailytrust.com.ng/why-i-wrote-a-book-on-former-president-jonathan-bolaji-abdullahi.html