Jump to content

Boss of all bosses

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Boss Of All Bosses
AdaríIke Nnaebue
Olùgbékalẹ̀Emeka Kachikwu
Àwọn òṣèréPatience Ozokwor, Akpororo, Bishop Imeh, Adunni Ade, Eniola Badmus, Nedu Wazobia[1]
OlóòtúMark Grandy
Déètì àgbéjáde
  • Oṣù Kẹfà 15, 2018 (2018-06-15)

Ọ̀gá gbogbo àwọn ọ̀gá (Boss of All Bosses) jẹ́ eré àgbéléwò apanilẹ́rìn-ín tí a gbé jáde ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, eré náà dá lórí ìjà láàrin àwọn aláṣẹ méjì; Tony àti Samuel, àwọn tó já sí pé kò sí ohun tí wọn kò lè ṣe láti du ipò ọ̀gá àgbà pátápátá. Wọ́n gbé e jáde ní June 15,[1] àwọn àgbà òṣèré tí wọ́n kópa nínú eré náà ni Akpororo, Nedu Wazobia fm, Mama G (Patience Ozokwo), Okon Lagos (Bishop Ime),[2][3] Senator (Bethel Njoku), Emeka Kachikwu, Adunni Ade, Sani Danja, Eniola Badmus àti Babatunde Charles.

Ọ̀gá àwọn ọ̀gá (Boss of all Bosses) wọ́n gbé e jáde ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ní June 15, 2018.[3][4]

Tireni Adebayo, ẹni tí ó jẹ́ akọ̀rọ̀yìn fún ilé iṣẹ́ ìròyìn Kemi Filani News, ṣe àpèjúwe eré náà gẹ́gẹ́ bí "èyí tí ó ń kó ìrira àti ìbínú bá ni", ó sì tẹ̀síwájú pé eré náà le è jẹ́ "eré tí ó burú jù nínú gbogbo eré Nollywood tí ènìyàn le rí ní sinimá (cinema)" bẹ́ẹ̀ ni ó rọ gbogbo àwọn òǹwòran "láti yàgò fún irúfẹ́ eré bẹ́ẹ̀ láti máa wò ní orí ẹ̀rọ agbóhùngbójìjí".[5] Omidire Idowu, akọ̀rọ̀yìn fún Pulse.NG, nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ gbé oríyìn fún eré náà nípa ṣíṣe àpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi "eré tó gbé ìṣòro orílẹ̀ èdè Nàìjíríà jáde láti ibi èrò tí ó gúnmọ́".[6]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]