Délé Giwa

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Sumonu Oladele Giwa
Fáìlì:Dele Giwa Portrait.jpg
Ọjọ́ìbí16 March 1947
Ile-Ife, British Nigeria
Aláìsí19 October 1986 (Age 39)
Ikeja, Lagos State, Nigeria
Cause of deathMail bomb explosion
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Ẹ̀kọ́Brooklyn College, New York City
Fordham University
Iṣẹ́Journalist,Editor And a Publisher.
Gbajúmọ̀ fúnNewswatch
Notable workFounder of Newswatch magazine
Olólùfẹ́Florence Ita Giwa
(1980s; divorced)
Olufunmilayo Olaniyan
(1984-1986; his death)
Àwọn ọmọ5

Dele Giwa tí abísọ rẹ̀ ń jẹ́ Sùmọ́nù Ọládélé Baines Giwa jẹ́ ọmọ prílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí won bí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kẹta ọdún 1947, tí ó sì papò dà ní ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù kẹwá ọdún 1986. (16 March 1947 – 19 October 1986) jẹ́ oníṣẹ́ ìwé ìròyìn àti olóòtú ìwé ìròyìn ọlọ́sọ̀ọ̀sẹ̀ Newswatch.

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Sùmọ́nù Ọládélé Baines Giwa won bí ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kẹta ọdún 1947, tí ó sì papò dà ní ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù kẹwá ọdún 1986. (16 March 1947 ) ni wọ́n bí sínú ẹbí ìkan nínú àwọn òṣìṣẹ́ l'áàfin Ọba Adesoji Aderemi nígbà ayé rẹ̀.

Ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Délé l9 sí ilé-ẹ̀kọ́ L.A tí ó wà ní Làgèrè ní ìlú Ilé-Ifẹ̀. Ó sì wọ ilé-ẹ̀kọ́ ti Odùduwà College ní Ilé-Ifẹ̀ nígbà tí bàbá rẹ̀ ríṣẹ́ sí ibẹ̀ gẹ́gẹ́ bí alágbàfọ̀.[1] Délé tún lọ sílé ẹ̀kọ́ àgbà ní ìlú Amẹ́ríkà tí ó sì kẹ́kọ́ gboyè BA nínú ìmọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì ní ulé-ẹ̀kọ́ Brooklyn College ní ọdún 1977. Ó tún sì tún lọ sílé ẹ̀kọ́ Fordham University láti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè siwájú si. Ó ṣiṣẹ́ ní ilé-iṣẹ́ ìwé ìròyìn ilẹ̀ Amerika tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ The New York Times gẹ́gẹ́ bí amúgbá-lẹ́gbẹ̀ẹ́ olóòtú ìwé ìròyìn náà fún odidi ọdún mẹ́rin gbáko ṣáájú kí ó tó padà sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti sìṣẹ́ nílé iṣẹ́ ìwé ìròyìn Daily Times tí ó wà ní ìlú Èkó.[2]

Délé Gíwá, Ray Ekpu, Dan Agbese ati Yakubu Mohammed ni wọ́n jọ pawọ́pọ̀ dá ilé-iṣẹ́ ìwé ìròyìn Newswatch [3] ní ọdún 1984, wọ́n sì gbé àpilẹ̀kọ akọ́kọ́ jáde ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kíní ọdún 1985, tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ń pin ká ní oṣù kíní. [4] Délé gbé iṣẹ́ ìmọ̀ ìròyìn àti ìkóroyìn jọ jáde ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà pẹ̀lú ṣíṣàfikún ìgboyà àti ìtọpinpin nínú iṣẹ́ ìròyìn nígbà ayé rẹ̀.[5] Ní àsìkò ìjọba Ààrẹ apàṣẹ wàá lábẹ́ ìjọba ológun Ibrahim Babangida tí ó gba ìjọba ní inú oṣù kẹjọ ọdún 1985. Délé gbé àwòrán ojú Ààrẹ náà sí ojú ewé akọ́kọ́ ìwé ìròyìn náà ní ẹ̀mẹ́rin tí ó sì tún ń fẹnu àbùkù sọ tẹni bá ro wípé òun yóò ma da ìjọba Ààrẹ Babangida rà.[6] Nígbẹ̀yìn, ìwé ìròyìn Newswatch gbójú agan sí Ààrẹ náà lásìkò ìjọba rẹ̀.[7]

Ìgbé ayé rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Délé Gíwá fẹ́ ìyàwó rẹ̀ àkọ́kọ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà tí ó jẹ́ oníṣẹ́ ìlera ní ọdún 1974.[2] Ó fẹ́ ìyàwó kejì tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Florence Ita Giwa, amọ́ ìgbéyàwó wọn kò ju lò ju oṣù mẹ́wá lọ kí ó tó túká. Lẹ́yìn náà ó tún ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú arabìnrin Olufunmilayo Olaniyan ní ọjọ́ kẹwá oṣù keje ọdún 1984, tí wọ́n sì jọ wà papọ̀ títí di àsìkò ikú rẹ̀ ní ọdún 1986.[8] Ìyá rẹ̀ tó bi àti ọmọ rẹ̀ ni wọ́n gbẹ̀yìn rẹ̀.[9][10]



Itokasi[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

  1. Charles Soeze (20 October 2009). "Dele Giwa: 23 years after". The Punch. Retrieved 24 June 2011. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  2. 2.0 2.1 "Zaccheus Onumba Dibiaezue Memorial Libraries (ZODML)". Archived from the original on 21 September 2013. Retrieved 20 September 2013. 
  3. "Remembering Dele Giwa". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2021-10-20. Retrieved 2022-03-13. 
  4. Ndaeyo Uko (2004). Romancing the gun: the press as promoter of military rule. Africa World Press. p. 100. ISBN 1-59221-189-5. https://books.google.com/books?id=Abm-v6wGWOQC&pg=PA100. 
  5. James Phillip Jeter (1996). International Afro mass media: a reference guide. Greenwood Publishing Group. p. 30. ISBN 0-313-28400-8. https://books.google.com/books?id=uLenDhrLQ8oC&pg=PA30. 
  6. Lyn S. Graybill; Kenneth W. Thompson; White Burkett Miller Center (1998). Africa's second wave of freedom: development, democracy, and rights. University Press of America. p. 150. ISBN 0-7618-1071-4. https://books.google.com/books?id=V0FYXwY2sc8C&pg=PA150. 
  7. Admin (19 October 2015). "Dele Giwa, 29 years after". Vanguard. Retrieved 8 February 2019. 
  8. Ugochukwu Ejinkeonye (31 May 2007). "Florence Ita-Giwa: What Next?". Nigerians in America. Archived from the original on 14 July 2011. Retrieved 24 June 2011.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  9. Tony Osauzo (17 February 2013). "Dele Giwa's mother laid to rest beside son's grave". Sun News. http://sunnewsonline.com/new/?p=18431. 
  10. "Dele Giwa: Fond memories for first Nigerian letter bomb victim". The Vanguard. http://www.vanguardngr.com/2011/10/dele-giwa-fond-memories-for-first-nigerian-letter-bomb-victim/.