Ijebu Ode Grammar School
Ìrísí
| Ijebu Ode Grammar School | |
| Location | |
|---|---|
| Information | |
| Established | 1913 |
| Gender | Akọ (Ọmọkùnrin) |
| Houses |
|
Ijebu Ode Grammar School (JOGS) jẹ́ ilé-ìwé girama fún àwọn ọmọkùnrin nìkan tí ó wà ní agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ Ìjẹ̀bú-Òde, ní Ìpínlẹ̀ Ògùn, ní apá Gúúsù mọ́ Ìwọ̀-Oòrùn ilẹ̀ Nàìjíríà.[1] Wọ́n ṣe ìdásílẹ̀ ilé-ìwé yìí ní ọjọ́ ogún oṣù kìíní ọdún 1913 (20 January 1913), ilé-ìwé náà sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ilé-ìwé tí ó pẹ́ jù lọ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[2][3]
Àwọn Ilé (Houses)
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Gansallo (Blue) - Aláwọ̀ Búlúù
- Johnson (Red) - Aláwọ̀ Pupa
- Kuti (Grey) - Aláwọ̀ Eérú
- Odumosu (Green) - Aláwọ̀ Ewé
- Phillips (Yellow) - Aláwọ̀ Ìyeyè
- School (Purple) - Aláwọ̀ Pọ́pù
Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Àtijọ́ tó lami-laaka
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- Abraham Adesanya, Agbẹjọ́rò àti ajìjàgbaara ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà
- Inumidun Akande, Adájọ́ Àgbà tẹ́lẹ̀ rí ti Ìpínlẹ̀ Èkó
- Mobolaji Bank Anthony, Ààrẹ ìgbìmọ̀ tẹ́lẹ̀ rí ti Lagos Stock Exchange
- Deji Ashiru, Onímọ̀-ẹ̀rọ àti Olùdarí Àgbà (MD/CEO) fún Ogun-Osun River Basin Development Authority
- George Ashiru, Ọ̀gá àgbà nínú eré Taekwondo
- Harold Demuren, Onímọ̀-ẹ̀rọ ọkọ̀ òfuurufú ọmọ Nàìjíríà
- Bode George, Olóṣèlú àti Gómìnà Ológun tẹ́lẹ̀ ní Nàìjíríà
- Seth Kale, Bíṣọ́ọ̀bù tẹ́lẹ̀ rí ti Èkó (Bishop of Lagos)
- Adeleke Mamora, Mínísítà fún ètò Ìlera
- Omololu Meroyi, Sẹ́netọ̀ tẹ́lẹ̀ rí fún agbègbè Gúúsù Ondo
- Adeola Odutola, Gbajúmọ̀ oníṣòwò
- Olu Oyesanya, Akọ̀ròyìn
- Vector, Olórin räp
- Wizkid, Olórin
Àwọn Olùkọ́ tó gbajúmọ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ẹgbẹ́ Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Àtijọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ijebu-Ode Grammar School ní ẹgbẹ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó ti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ní ilé-ìwé náà (Old Students Association), tí wọ́n ń pè ní JOGSOBA (Ijebu-Ode Grammar School Old Boys Association).
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Emmanuel Ayankanmi Ayandele (1992). The Ijebu of Yorubaland, 1850-1950: politics, economy, and society. Heinemann Educational Books (Nigeria). ISBN 978-978-129-433-4. https://books.google.com/books?id=MnUuAQAAIAAJ.
- ↑ Ukwu, Jerrywright (2015-05-22). "Nigeria's Ancient Secondary Schools". http://www.naij.com/444344-nigerias-ancient-secondary-schools.html. Retrieved 2016-02-25.
- ↑ Barbara Goff (9 May 2013). 'Your Secret Language': Classics in the British Colonies of West Africa. A&C Black. pp. 48–. ISBN 978-1-78093-205-7. https://books.google.com/books?id=QUBMAQAAQBAJ&pg=PA48.