Jump to content

Bode George

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Olabode Ibiyinka George
9th Governor of Ondo State
In office
July 1988  September 1990
AsíwájúRaji Alagbe Rasaki
Arọ́pòSunday Abiodun Olukoya
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbíNovember 21, 1945
Lagos, Lagos State, Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúMilitary

Olabode Ibiyinka George jẹ́ àgbà olóṣèlú ọmọ bíbí ìpínlẹ̀ Eko ní apá ìwọ̀-oòrùn orilẹ-ède Naijiria. A bíi ní ọjọ kọkànlelógún, oṣù kọkànlá ọdún 1945[1]. O ti fìgbà kan jẹ Gómìnà ìjọba ológun Ipinle Ondo ní ọdún 1988 si 1990[2]. Títí di àsìkò yìí, Bode George jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́-òsèlú alátakò People Democratic Party[3]

George ti a bí ní ọjọ́ kọkànlá-lé-lógún, oṣù kọkànlá, ọdún 1945 ní Èkó. Ó gba ìwé-ẹ̀rí B.Sc. àti MBA.[4] Bode George di Commodore nínú ọmọ olóògùn orí omi Nàìjíríà, wọ́n sì yàn án gẹ́gẹ́ bí Gómìnà ìjọba ológun ti Ìpínlẹ̀ Ondo láàrin ọdún (1988–1990).[5]

Ní àjọṣe ìfọrọ̀wánilẹ́nuwò ti owaye ní Oṣù Keje ọdún 2002, Gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó, Bola Tinubu sọ pé Bode George nilò láti kọjú ilé ẹjọ́ ìhùwà ọdaràn lórí ìṣe rẹ̀ lorí ipò gómìnà nípínlẹ̀ Ondo. Ó ní: “Bode George àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ tí wọ́n gbàgbọ́ nínú ìjọba ọmọ-ologun gbọ́dọ̀ mọ̀ gbangba pé àkókò wọn ti parí, a wà ní abẹ́ ìjọba olóminira báyìí.[6]” Ní ìdáhùn, Ààrẹ ẹgbẹ́ PDP, Alhaji Muhammed Muritala Ashorobi, sọ pé Bode George ní àkọsílẹ̀ rere gẹ́gẹ́ bí gómìnà ìpínlẹ̀ Ondo tẹlẹ ri, àti pé àwọn ilé tó kọ jẹ́ àmì ìrántí dáadáa.[7]Ní ọdún 1990, ó dá Rufus Giwa Polytechnic, Owo sílẹ̀ nípasẹ̀ àṣẹ òfin , ilé-ẹ̀kọ́ tí ó ní ju ọmọ-ẹ̀kọ́ ẹgbẹ̀run lọ́nà mẹrin 4,000 lọ báyìí.[8]

Ó tún di Olùdarí Ìṣẹ́ (Principal Staff Officer) sí General Oladipo Diya nígbà tí Diya jẹ́ Olórí Ìṣẹ́ Gbogbogbò (Chief of General Staff) láàárín ọdún 1993 sí 1997. George tún jẹ́ Olùdarí ní Ilé-ẹ̀kọ́ Ogún Orílẹ̀-Èdè Nàìjíríà (Nigerian National War College, NWC).[9]