Jump to content

Majid Michel

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́


Majid Michel
Ọjọ́ìbíMajid Michel
22 Oṣù Kẹ̀sán 1980 (1980-09-22) (ọmọ ọdún 44)
Cantonments, Accra, Ghana
Ọmọ orílẹ̀-èdèGhana
Iṣẹ́Actor and pastor
Ìgbà iṣẹ́2000–present
Notable workThings We Do For Love
Olólùfẹ́Virna Michel
Àwọn ọmọ3[1]
Websitemajidmichel.com[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]


Majid Michel tí a bí ní ọjọ́ kejìlélógójì, oṣù kẹsàn-án, ọdún 1980 jẹ́ òṣèré ti orílẹ̀-èdè Ghana, olóòtú ètò lórí ẹ̀rọ̀ amóhùn-máwòrán, ajíhìnrere àti oníwà-ìranmọlàkejì-lọ́wọ́. Wọ́n yàn án fún ìdíje gbígba àmì-ẹ̀yẹ fún òṣèré-kùnrin tó dára jù lọ ní ayẹyẹ Africa Movie Academy Awards ní ọdún 2009, 2010, 2011, 2012, 2014 àti 2017.[2][3] Ó pàpà gba àmì-ẹ̀yẹ ọ̀hún ní ọdún 2012 lẹ́yìn tí wọ́n ti yàn án ní ọdún mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀.[4][5]

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé rẹ̀.

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ìlú Accra ní orílẹ̀-èdè Ghana ni wọ́n bí Michel sí. Lebanese ni bàbá rẹ̀ tí ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ọmọ ìlú Ghana,[2] ìlú Accra sì ni ó gbé dàgbà pẹ̀lú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀ mẹ́sẹ̀sán. Ilé-ìwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ St. Theresa ni ó lọ, lẹ́yìn tí ó wá lọ ilé-ìwé Mfantsipim, tí Van Vicker àti akọ̀wé àgbà ti United Nations (Kofi Annan) ti kàwé. Nígbà ti ó wà ní ilé-ìwé girama, ó sábà máa ń kópa nínú eré orí ìtàgé, ó sì dara pọ̀ mọ́ àwọn eléré-oníṣe, èyí sì mu kí ó gba àmì-ẹ̀yẹ gẹ́gẹ́ bí òṣèré tó dára jù lọ ní Cape Coast, ní Ghanalọ́hùn-ún.[2]

Ní kété tí Michel dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ àwọn òṣèré, ó kópa nínú eré kan tí woṇ́ máa ń ṣàfihàn rẹ̀ lórí ẹ̀rọ amóhùn-máwòrán tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ Things We Do for Love, lẹ́yìn èyí ni ó gbé fíìmù rẹ̀ jáde tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ Divine Love. Jackie Aygemang àti Van Vicker sì kópa nínú eré náà.

Ní ọdún 2018, ó tún kópa nínú fíìmù kan tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ Agony of the Christ, èyí sì mú u kí àwọn èèyàn yàn án fún ìdíje gbígba àmì-ẹ̀yẹ ti Africa Movie Academy Awards ní ọdún 2009. Ní ọdún 2009, ó fi ìdí ẹ̀ múlẹ̀ níbi ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pé òun máa ń gbà tó dọ́là mẹ́ẹ̀dógún lọ́nà ẹgbẹ̀rún kan($15,000) sí dọ́là márùndínlógójì lọ́nà ẹgbẹ̀rún kan ($35,000) lórí fíìmù kan.[4] Àti pé bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn eré-ajẹmọ́fẹ̀ẹ́ ni òun máa ń sábà ṣe, òun ò fìgbà kan rí ní ìbálòpò pẹ̀lú àwọn òṣèré-bìnrin tí wọ́n jọ ń ṣiṣẹ́[5]. Ní ọdún 2017, ó sọ ọ́ di mímọ̀ lórí ètò rédíò kan tí wọ́n ti gbà á lálejò pé òun ò ní máa gbà láti ṣe fíìmù kọkan tí òun máa nílò láti fẹnu ko èèyàn lẹ́nu.[5]

{{columns-list|colwidth=30em|

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. "PHOTOS: Majid Michel Steps Out With Pregnant Wife". 2016. Archived from the original on 30 October 2019. Retrieved 23 February 2022. 
  2. 2.0 2.1 2.2 "AMAA 2009: List of Winners and Nominees". Retrieved 17 January 2010.  [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  3. "Interview with Majid at ModernGhana.com, 2008". Retrieved 22 October 2009. 
  4. 4.0 4.1 Opurum, Nkechi (23 April 2012). "Rita Dominic wins best actress". Daily Times (Lagos, Nigeria). Archived from the original on 26 April 2012. https://web.archive.org/web/20120426231657/http://dailytimes.com.ng/article/rita-dominic-wins-best-actress. 
  5. 5.0 5.1 Alonge, Osagie (23 April 2012). "Rita Dominic, Majid Michel win big at AMAA 2012". Nigerian Entertainment (Lagos, Nigeria). Archived from the original on 10 January 2015. https://web.archive.org/web/20150110121508/http://www.thenetng.com/2012/04/23/rita-dominic-majid-michel-win-big-at-amaa-2012/.