Mudashiru Obasa
Right Honourable Mudashiru Obasa | |
|---|---|
| Speaker of the 8th Lagos State House of Assembly | |
Lọ́wọ́lọ́wọ́ | |
| Ó gun orí àga 2015 | |
| Asíwájú | Adeyemi Ikuforiji |
| Constituency | Lagos, Agege Constituency I |
| Member of the Lagos State House of Assembly | |
| In office 2011–2015 | |
| Member of the Lagos State House of Assembly | |
| In office 2007–2011 | |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 11 Oṣù Kọkànlá 1972 |
| Ọmọorílẹ̀-èdè | Nigerian |
| Ẹgbẹ́ olóṣèlú | All Progressive Congress (APC) |
| Ẹbí | Married |
| Residence | Lagos |
| Alma mater | LASU |
| Occupation | Legislature |
| Profession | Legal Practitioner |
Mudashiru Àjàyí Ọbasá (tí a bí ní ọjọ́ kọkànlá oṣù kọkànlá ọdún 1972) jẹ́ agbẹjọ́rò orílẹ-èdè Nàìjíríà àti olóṣèlú ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress ilẹ̀ Nàìjíríà kan. O ṣiṣẹ gẹ́gẹ́bí agbẹnusọ fún ilé ìgbìmọ̀ Aṣòfin ìpínlẹ̀ Èkó láti oṣù kẹfà ọdún 2015 sí oṣù kínní ọdún 2025[1][2][3][4].
Ibẹ̀rẹ̀ aye rẹ̀
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]A bí i ní ilù Agege, ní Ìpínlẹ̀ Èkó ní apa gúsù ìwọ̀ Olorun ilẹ̀ Nàìjíríà ní ọjọ kọkànlá oṣù kọkànlá ọdún 1972. [5]
Ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ní Ilé-ẹ̀kọ́ St Thomas Acquinas ní Sùúrù-lérè, ṣáájú kí ó tó lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ girama Archbishop Aggey Memorial, ní ìlú Mushin, ní agbègbè Ìlasa-màjà, ní ìpínlẹ̀ Èkó níbi tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ gba ìwé ẹ̀rí ìdánwò àpapọ̀ Ìwọ̀ Oòrùn ilẹ̀ Adúláwọ̀ (WAEC). [6] Ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ìmọ̀òfin ní Ilé-Ẹ̀kọ́ Ìpínlẹ̀ Èkó ní ọdún 2006. [7]
Iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Ní ọdún 1999, Mudashiru díje dupò sí ipò kánsílọ̀ ní ijọba ìbílẹ̀ Agege lábẹ́ egbẹ́ òṣèlú Alliance for Democracy ó sì borí, léyìí tí ó ṣiṣẹ́ nibẹ̀ láàrín ọdún 1999 sí 2002. [8]
Ẹ̀wẹ̀, wọn dìbò yan sí Ilé ìgbìmọ̀ aṣojúṣòfin ìpínlẹ̀ Èkó ní ẹkùn ìjọba ìbílẹ̀ Agége ní ọdún 2007, wọn tún tún yàn ní ọdún 2011, 2015, 2019 àti ọdún 2023. [9][10]
Nígbà ìṣòro #EndSARS ní ìpínlẹ̀ rẹ̀, a rí lórí amóunmáwòrán tí óún sàlààyè pé “Ile-Asọfin Ìpínlẹ̀ Èkó kò ní fọwọ́sí ikú àwọn olùjìjàgbara tí àwọn ọlọ́pàá pa,” tí o sì pè fún ìdakẹ́jẹ iṣẹ́ju kan fún àwọn tí o faragbáá #LekkiMassacre àti àwọn míìràn káàkiri Nàìjíríà[11].
Ẹ̀sùn ìkówójẹ
Ní ọdún 2020, Olùjábọ̀ ìròyìn Sahara (Sahara Reporters) fi ẹ̀sùn kán fún ìkówójẹ àwùjọ lórí Obasa. Ṣùgbọ́n ó tako gbogbo ẹ̀sùn náà[12][13][14][15].
Lẹ́yìn náà, Sahara Reporters tún jábọ̀ pé a mú Obasa lọ sí ọ̀dọ̀ àjọ t'in mójútó ọrọ̀ ajé ìlú àti ẹ̀sùn nípa owó (Economic and Financial Crimes Commission EFCC) fún ìbéèrè ní ọjọ́ kẹjọ àti ọjọ kẹ̀sán Oṣù Kẹwàá ọdún 2020. Ní gẹ́gẹ́ bí orísun abẹ́lé tí Sahara Reporters tọ́ka sí wípé, Obasa puró àìsàn mọn ara rẹ̀ nígbà tí ìbéèrè ńlọ ní ọ́fíìsì EFCC, èyí tó fa kí wọ́n dá ìbéèrè náà dúró. Wọn gbé e lọ sí yàrá ìwòsàn ní ọ́fíìsì EFCC kí wọ́n tó túu sílẹ̀[16]. Lẹ́yìn náà, Obasa bèèrè fún ìdápadà ìwé irinna ìlú òkèèrè rẹ̀ (passport) láti lè lọ sí ìlú òkèèrè fún ìtọju ìlera kí ó tó lọ Umrah láti pàdé Bola Tinubu ní orílẹ̀-ẹ̀dẹ̀ Saudi Arabia. Obasa ṣi wà ní abẹ́ ìwádìí EFCC fún ẹ̀sùn ìkówójẹ àti ìlu ìjìbìtì[17].
Ní ọjọ́ kẹtàlá Oṣù Kínní ọdún 2025, wọn rọ Obasa lóyè nípasẹ̀ ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Ile-Asọfin Ìpínlẹ̀ Èkó lórí ẹ̀sùn ìwà àìtọ́ àti lílo ọ́fíìsì rẹ̀ ní ọ̀nà tí kò bófin mu. Igbákejì rẹ̀, Mojisola Meranda, ni wọ́n dìbò yàn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ wọ́n sì gbé e sípò gẹ́gẹ́ bí olórí tuntun[18][19][20][21].
Àwọn ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ Ebhomele, Eromosele. "Meet Obasa, The New Lagos Speaker". The News. The News. http://thenewsnigeria.com.ng/2015/06/meet-obasa-the-new-lagos-speaker/. Retrieved 13 January 2017.
- ↑ https://www.bbc.com/pidgin/articles/cewkdq1rpeyo
- ↑ https://punchng.com/breaking-obasa-returns-as-lagos-assembly-speaker/
- ↑ https://www.arise.tv/obasa-reinstated-as-lagos-assembly-speaker-meranda-returns-to-deputy-role/
- ↑ Ademola, Jamiu. "The Rise And Rise Of The New Lagos Speaker". Naij. Naij. https://politics.naij.com/456274-the-rise-and-rise-of-the-new-lagos-speaker.html. Retrieved 13 January 2017.
- ↑ Obasa, Mudashiru. "Why I want to come back to House for the fourth time". Econium. http://encomium.ng/why-i-want-to-come-back-to-house-for-the-fourth-time-hon-mudashiru-obasa/. Retrieved 13 January 2017.
- ↑ Ademola, Jamiu. "The Rise And Rise Of The New Lagos Speaker". Naij. https://politics.naij.com/456274-the-rise-and-rise-of-the-new-lagos-speaker.html. Retrieved 13 January 2017.
- ↑ Admin. "Profiles of the new principal officers of Lagos House of Assembly". Emcomium. http://encomium.ng/profiles-of-the-new-principal-officers-of-lagos-house-of-assembly/. Retrieved 13 January 2017.
- ↑ https://punchng.com/breaking-lagos-speaker-obasa-other-win-lagos-house-of-assembly-seats-in-agege/amp/
- ↑ https://www.lagoshouseofassembly.gov.ng/team_member/rt-hon-mudashiru-ajayi-obasa-speaker/
- ↑ https://allnews.ng/news/endsars-we-won-t-honour-miscreants-killed-by-the-police-lagos-speaker-video
- ↑ https://www.lagoshouseofassembly.gov.ng/lagos-assembly-clears-the-air-on-misappropriation-of-funds/
- ↑ http://saharareporters.com/2020/05/15/exclusive-lagos-assembly-speaker-obasa-approves-n258m-printing-invitation-cards-house
- ↑ http://saharareporters.com/2020/05/04/exclusive-how-obasa%E2%80%99s-wife-receives-n10m-illegal-monthly-allocation-lagos-assembly
- ↑ https://guardian.ng/tag/mudashiru-obasa/
- ↑ http://saharareporters.com/2020/10/10/exclusive-lagos-assembly-speaker-obasa-returns-efcc-interrogation-feigns-sickness
- ↑ http://saharareporters.com/2021/05/11/lagos-speaker-obasa-under-efcc-probe-sighted-mecca-after-lying-he-was-sick-needed-his
- ↑ https://www.thecable.ng/breaking-lagos-assembly-impeaches-obasa-elects-mojisola-meranda-as-new-speaker/
- ↑ https://gazettengr.com/lagos-lawmakers-impeach-speaker-obasa-amid-multibillion-naira-fraud-allegations/
- ↑ https://tribuneonlineng.com/breaking-lagos-assembly-speaker-obasa-impeached/
- ↑ https://thenigerialawyer.com/after-obasas-impeachment-mojisola-meranda-becomes-first-female-speaker-of-lagos-assembly-pledges-transparency/