Raymond Dokpesi

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́

Raymond Dokpesi
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí
Raymond Anthony Aleogho Dokpesi

(1951-10-25)25 Oṣù Kẹ̀wá 1951
Ibadan, Nigeria
Aláìsí29 May 2023(2023-05-29) (ọmọ ọdún 71)
Abuja, Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlú
Alma mater
Websiteraymonddokpesi.com

Olóyè Raymond Anthony Aleogho Dokpesi (tí wọ́n bí ní 25 October 1951 tó sì ṣaláìsí ní 29 May 2023) jẹ́ oníṣòwò ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Àwọn òbí rẹ̀ wá láti Agenebode, ní Ìpínlẹ̀ Ẹdó, sínú ìdílé tó ní àbúròbìnrin mẹ́fà. Ó wọ inú ilé-iṣẹ́ agbéròyìnjáde pẹ̀lú ilé-iṣẹ́ rẹ̀ DAAR Communications, ó sì ṣèdásílẹ̀ ìkànni orí ẹ̀rọ̀-amóhùnmáwòrán ti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, èyí tí ń ṣe Africa Independent Television (AIT).[1] Òun ni alága ìgbìmọ̀ tó ń ṣètò ìpérò àgbáyé ti People's Democratic Party ní ọdún 2015.[2] Ní oṣù kẹta ọdún 2020, ó ń kojú àwọn ẹ̀sùn jìbìtì tí wọn fi sùn ún.[3] Ní oṣù karùn-ún ọdún 2020, Dokpesi làlùyọ nínú àrùn COVID-19.[4] Ó ṣàìsàn ìrọlápá-ìrọlẹ́sẹ̀ ní ọdún 2023, lẹ́yìn àwẹ̀ Ràmàdáànì wọn. Ó ṣaláìsí ní ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n, oṣù karùn-ún ọdún 2023.[5]

Ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Dokpesi bẹ̀rẹ̀ ètò ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Loyola college, Ibadan. Lẹ́yìn èyí, ó darapọ̀ mọ́ Immaculate Conception College (ICC) ní Ìlú Benin, níbi tí ó ti jẹ́ ọmọ-ẹgbé Ozolua Play house, èyí tó jẹ́ ẹgbẹ́ onítíátà àti ijó. Ó kẹ́kọ̀ó gboyè ní University of Benin Edo State, ó sì parí ẹ̀kọ́ rè ní University of Gdansk, ní Poland, níbi tí ó ti gba oyè Doctorate degree, nínú ẹ̀kọ́ Marine Engineering. Alhaji Bamanga Tukur ló san owó ilé-ìwé rẹ̀, láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin.

Àwọn ìtọ́kasí[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]