Segun Osoba
Olúṣẹ́gun Ọ̀ṣọbà Akirogun of Egbaland | |
|---|---|
Àrẹ̀mọ Olúṣẹ́gu Ọ̀ṣọbà | |
| Executive Governor of Ogun State | |
| In office January 1992 – November 1993 | |
| Asíwájú | Oladeinde Joseph |
| Arọ́pò | Daniel Akintonde |
| Executive Governor of Ogun State | |
| In office 29 May 1999 – 29 May 2003 | |
| Asíwájú | Kayode Olofin-Moyin |
| Arọ́pò | Gbenga Daniel |
| Àwọn àlàyé onítòhún | |
| Ọjọ́ìbí | 1939 |
Olúṣẹ́gun Ọ̀ṣọbà (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù keje ọdún 1939) jẹ́ gbajúmọ̀ òṣèlú ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti Gómìnà Ìpínlẹ̀ Ògùn tẹ́lẹ̀.[1] [2]
Ìgbésí ayé ìbéèrè àti ẹ̀kọ́
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Olúṣẹ́gun Osoba ni wọ́n bí fún Ògbẹ́ni àti Arábìnrin Jonathan Babatunde Osoba. Osoba lọ sí oríṣiríṣi àwọn ẹ̀kọ́ ọ̀jọ̀gbọ́n lẹ́yìn tí ó parí ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga Methodist Boys’ High School, Lagos . Ó gba ìwé ẹ̀rí iṣẹ́ ìròyìn ní Yunifásítì ti Èkó ó sì lọ sí ẹ̀kọ́ ọdún kan ní United Kingdom lórí ẹ̀bùn ẹ̀kọ́ láti ọwọ́ Commonwealth Press Union ní ọdún 1967. Ní ọdún 1969, ó ń kẹ́kọ̀ọ́ ní Bloomington, USA ní ẹ̀ka iṣẹ́ ìròyìn ti Indiana University. Ní ọdún 1974, ó gba ẹ̀bùn Nieman Fellowship fún iṣẹ́ ìròyìn fún ọ̀pọ̀ ọdún tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ ní Harvard University, Cambridge, Massachusetts, USA. Òun ni ọmọ Nàìjíríà àkọ́kọ́ tí ó ti gba ẹ̀bùn Nieman Fellowship fún iṣẹ́ ìròyìn.
Iṣẹ́ ìròyìn
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]Osoba bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ nínú iṣẹ́ ìròyìn ní ọdún 1964, ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú Daily Times of Nigeria gẹ́gẹ́ bí oníròyìn tí ó ń kọ́ṣẹ́ nípa ìtàn ìwà ọ̀daràn, nígbà tí ó sì di ọdún 1966, ó jẹ́ aṣojú ìjọba fún Times. Ó di olóòtú ìròyìn ní ọdún 1968, igbákejì olóòtú ìwé ìròyìn Sunday Times ní ọdún 1971 àti igbákejì olóòtú ìwé ìròyìn Times ní ọdún 1972. Ní oṣù kẹjọ ọdún 1975, ó di olóòtú ìwé ìròyìn Daily Times of Nigeria, lẹ́yìn náà ó fi ilé-iṣẹ́ náà sílẹ̀ ní oṣù kọkànlá ọdún 1975 láti gba iṣẹ́ Olùdarí Gbogbogbò ti Nigerian Herald tí ó wà ní Ilorin . Ó padà sí Times ní ọdún 1984 gẹ́gẹ́ bí olùdarí àgbà. Ní àgbáyé, ó ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí oníròyìn tàbí aṣojú ìbílẹ̀ fún British Broadcasting Corporation, The Times of London, Newsweek Magazine, àti United Press International News Agency. Ó jẹ́ alága Ìgbìmọ̀ Olùdarí ti Nigerian Institute of Journalism àti ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ àgbà ti International Press Institute tí ó ń ṣojú fún Black-Africa láti ọdún 1984 sí 1992. Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Àpérò Àwọn Oníròyìn Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ọdún 1988. Ó tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Commonwealth Press Union, London àti Nigerian Union of Journalist.
Àwọn Ìtọ́kasí
[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]- ↑ "CHIEF OLUSEGUN OSOBA". Ogun State Government Official Website. 2017-05-12. Archived from the original on 2019-12-25. Retrieved 2019-12-13.
- ↑ "The adventures of Olusegun Osoba - The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. 2019-07-15. Archived from the original on 2019-12-13. Retrieved 2019-12-13.