Jump to content

Aliyu Mohammed Gusau

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Aliyu Mohammed Gusau
Minister of Defence
In office
5 March 2014  May 2015
AsíwájúOlusola Obada
Arọ́pòMansur Dan Ali
Chief of Army Staff
In office
August 1993  September 1993
AsíwájúSalihu Ibrahim
Arọ́pòChris Alli
National Security Advisor
In office
29 May 1999  1 June 2006
Arọ́pòAbdullahi Sarki Mukhtar
National Security Advisor
In office
8 March 2010  September 2010
AsíwájúAbdullahi Sarki Mukhtar
Arọ́pòKayode Are
Director General of the National Security Organization
In office
September 1985  July 1986
AsíwájúMohammed Lawal Rafindadi
Arọ́pòNSO Dissolved
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí18 Oṣù Kàrún 1943 (1943-05-18) (ọmọ ọdún 82)
Gusau, Zamfara State, Nigeria
Alma materNigerian Defence Academy
Military service
Branch/service Nigerian Army
Years of service1964 - 1993
RankLieutenant General

Aliyu Mohammed Gusau (ojoibi May 18 1943) oga agbogun ara Naijiria to ti feyinti. O ti je Alakoso Oro Abo, Onimoran Oro Abo Orile-ede fun aare Naijiria otooto meji, Oga awon Omose Agbogun, o se olori fun orisirisi ile-ise otelemuye, besini o tun se Oga Alase Nigerian Defence Academy.[1]

Ìgbésí Ayé Ìbéèrè

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

A bí ní Odún 1943, Oṣù Karùn-ún Ojó Kejìdínlógún ni Gusau, Ìpínlè Zamfara. Láti le damò yàtò sì Ògá Ológun Mìíràn tí orúkọ rẹ ń jẹ Aliyu Mohammed, Àjọ Omo ológun fi 'Gusau' Tí ńṣe agbègbè Ìbí re sì inú orúko rè.

Bótilèjèpè Aliyu Fún rarè kíì lo Gusau nínú kíko orúko ara re, ṣùgbón ọtí di gbajúmò látàrí àwon Oníròyìn tí won Sábà má n'lo.

Ní Odún 1964, ó forúkó sílè gégé bí omo akẹ́kọ̀ọ́ labẹ àsíá Omo ologun orile-ede Naijiria. Wọn fi jẹ olóyè ní Odún méta léyìn náà nínú Egbé Omo Ogun Nàìjíríà gẹ́gẹ́ bí igbá kejì Leuiftenanti. Ní ọdún 1967, ó kó pa nínú Ogun Abélé Nàìjíríà.

Ó jé Adarí Ikò omo ogun elésè tí Ipele Kẹsán, Abeokuta( Oṣu Kẹrin Ọdún 1976 - Oṣu Keje Odún 1977), Olùdarí Ààjo Ẹka fun tí ìmò ìjìnlè lórí ìjà tó ní ṣe pelu èro ( Oṣu Keje Odún 1978- Oṣu Kẹsan Odún 1979).

Láti Oṣù Kẹ̀sán Ọdún 1979 sí Oṣù Kejìlá Odún 1983, Aliyu jé Olùdarí Ẹka Yàrá ìmò àwọn omo ológun. Ó kó pa takun-takun nínú ìdìtè gbà ìjọba tí ó lè Shehu Shagari ati ìjọba Olómìnira kejì kúrò, tí ó sì gbé Ògagun Muhammad Buhari bó sí orí ipò.

Àwọn Ìjọba Ológun ti 1983–1993

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]


Lẹ́yìn ìfipá gba ìjọba náà, wọ́n dábàá láti jẹ kí ó di olórí gbogbo ètò ìsọ̀rọ̀ àti Ẹka Ìmò ìjọba, pẹ̀lú àtìlẹ́yìn láti òdò Olórí Ògun Ibrahim Babangida, ṣùgbọ́n Buhari tako ìyàn sí pò na. Lẹ́yìn náà ni Buhari fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé Muhammadu Lawal Rafindadi, ẹni tí Shagari yàn, ni yóò jẹ́ Olùdarí Ètò Ààbò Orílẹ̀-Èdè, ti ó sì lé Aliyu kúrò ní DMI, ó sì fi Colonel Halilu Akilu rọ́pò rẹ̀. Wọ́n rán Aliyu lọ sí Royal College of Defence StudiesUnited Kingdom fún ìdánilẹ́kọ̀ọ́.

Aliyu tún kópa nínú ìfipá-gba ìjọba ní ọjọ́ Ketadinlogbon, Oṣù Kẹjọ ọdún 1985, níbi tí Babangida tí gba ipò lọ́wọ́ Buhari.

Láàárín ìgbà tí wọ́n ń ṣe ìtòlẹ́sẹẹsẹ ìfipá-gba ìjọba yìí, nítorí ipa tí Aliyu ti ní ní gẹ́gẹ́bi olùdarí Ìkó DMI, wọ́n fi i sí abẹ́ ìtopinpin tó le jù, èyí tí ó kó ìpáká leke báwọn láti ṣe Kia Kia.

Lẹ́yìn ìfipá-gba ìjọba náà, wọ́n yàn Aliyu gẹ́gẹ́ bí Olùdarí Ààbò Ògun (Defence Intelligence Agency - DIA) àti Olùdarí Àgbà Ìṣe fún Ètò Ààbò Orílẹ̀-Èdè (Acting Director-General of the National Security Organisation - NSO) láti Oṣù Kẹ̀sán Ọdún 1985 sí Oṣù Kèjo Odún 1986, lẹ́yìn náà ó di Alábàáṣiṣẹ́pọ̀ lórí Ààbò Orílẹ̀-Èdè (Coordinator on National Security) láti Oṣù Kẹjọ ọdún 1986 sí Oṣù Kejìlá Odún 1989.

Ó tún ṣe àtúntò gbogbo ètò ààbò àti ìsọ̀rọ̀ ìjọba tí ó ti bàjẹ́ gan-an lábẹ́ Rafindadi nígbà ìjọba Buhari, ó sì pín NSO náà sí ẹ̀ka mẹ́ta: "State Security Service (SSS)", National Intelligence Agency(NIA), àti Defense intelligence Agency (DIA)

Wọ́n yàn Aliyu gẹ́gẹ́ bí Olórí Ọ̀gágun tó ń Mójú tó Ẹ̀ka Ìkejì tí ológun Adinpapa mora ní Ìlú Ìbàdàn láti Oṣù Kejìlá Odún 1989 sí Oṣù Kẹjọ ọdún 1990;

Ìpadàbọ̀ Sínú Òṣèlú

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Lẹ́yìn tí Aliyu fẹ́yìntì kúrò nínú ẹgbẹ́ ọmọ ogun, ó di Alága àti Olórí Àgbà ni Alpha Public Affairs Consultancy bẹ̀rẹ̀ láti Oṣù Kejìlá Odún 1993 sí Oṣù Kàrún ọdún 1999. Pẹ̀lú ipa àti agbára tó ní nínú àwùjọ àwọn aráàlú àti ti àwọn ológun, Aliyu kó ipa pàtàkì gan-an nínú ìdápadàbòsípò Ijọba Ọlógun sí ti alágbádá.

Ní àkókò pàtàkì tí àwọn tí wọ́n tí di ipo pàtàkì kú nínú iṣẹ́ ológun fèyìntì, Aliyu jẹ́ Olùdámọ̀ràn Ààbò Orílẹ̀-Èdè, ó sì ran Obasanjo lọ́wọ́ láti gba ìṣàkóso ẹgbẹ́ ológun gẹ́gẹ́ bí Ààrẹ aráàlú. Ó wà ní ipo Olùdámọ̀ràn Ààbò Orílẹ̀-Èdè ní àkókò ìjọba Obasanjo. Ó fi ipo rẹ̀ sílẹ̀ láti dije nínú ìdìbò àkọ́kọ́ ti Ẹgbẹ́ People's Democratic Party (PDP) fún olùdìbò ààrẹ ní Odún 2006, ó sì wá ní ipò kẹta. Ẹni tí ó ṣẹ́gun, Umaru Yar'Adua, ló tẹ̀ síwájú láti di Ààrẹ tí a yàn.

Ni ọjọ́ Kèjo Oṣu Kẹta ọdún 2010, Ààrẹ Adúróṣinṣin Goodluck Jonathan kéde pé òun ti yọ Major-General Sarki Mukhtar kúrò ní ipò Olùdámọ̀ràn Ààbò Orílẹ̀-Èdè, ó sì fi Aliyu rọ́pò rẹ̀.

Ní ọjọ́ díẹ̀ lẹ́yìn náà, Aliyu pàdé àwọn olórí ẹ̀ka ológun ní Abuja láti jíròrò lórí ìṣòro Jos àti ipò ààbò nínú orílẹ̀-èdè náà. Àwọn òrò abélè kan jeyo tí wọ́n ń tọka si ìsípòpadà àwọn ògá àgbà nínú ẹgbẹ́ ọmọ ogun àti ọlọ́pàá lè wáyé.

Ní oṣù kèrin ọdún 2010, Lákòókò tí Aliyu ń sọ̀rọ̀ ní ìpàdé àwọn onímọ̀, ó sọ pé ètò ìdájọ́ òfin dà bí ẹni pé ó ń gbè lẹ́yìn ìwà ọ̀daràn, àwọn ilé-iṣẹ́ tó ń bójú tó ìmúṣẹ òfin sì dà bí ẹni tí wọ́n rẹ̀wẹ̀sì.

Ó tún sọ pé àwọn ìgbìyànjú láti dojú ìjà kọ ìbàjẹ́ ni a rí bí èyí tí ó jẹ́ yíyan-ààyàn àti tí kò lé gbani, àwọn ilé-iṣẹ́ kan sì ní ìṣòro ìgbẹ́kẹ̀lẹ́ nítorí pé wọ́n ti fi àwọn olórí wọn sùn mọ́ ìbàjẹ́.

Ní oṣù kèrin ọdún 2010, Aliyu kéde ìfẹ́ rẹ̀ láti di olùdìbò fún ipo ààrẹ níbi ìdìbò ààrẹ Odún 2011.

Ìgbésí ayé ara eni

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Ọmọ rẹ̀ ọkùnrin Mahdi Mohammed Gusau (tí a bí ní Odún 1981) ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí Igbákejì Gómìnà Ìpínlẹ̀ Zamfara láti ọdún 2019 títí di ìgbà tí wọ́n yọ̀ ọ́ kúrò ní ipo rẹ̀ ní ọdún 2022.

Àwọn Àmì Èyẹ Aponle

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Orileede Àmì Èyẹ Òrò
Nàìjíríà Olùdarí tí àpapọ̀ orileede Nàìjíríà (CFR); Ipò kèta eléyìí to làmì-laka Jù lọ.

Àwọn Àmì Èyẹ Ìlú Òkèèrè

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
Orileede Àmì Èyẹ Oro
Germani Grand Cross of the Order of Merit (OM);[2] National honour in Germany. Awarded for merit
South Korea Order of National Security Merit;[3] "Outstanding meritorious services in the interest of national security"
South Africa National Intelligence Service Medal, Gold South African intelligence service medal
Ethiopia Grand Collar of the Order of Emperor Haile Selassie Ethiopian award named after Emperor Haile Selassie

Ilé Èkó Gíga Tí Gusau

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Aliyu dá ilé ẹ̀kọ́ gíga ìwádìí Gusau sílẹ̀ ní Kaduna, ó sì fi ilé ìwé àdáni rẹ̀ àti àwọn ìtẹ̀wé rẹ̀ ṣe ẹ̀bùn fún ilé-iṣẹ́ ìwádìí náà láti gbélẹ́rẹ́ ìdàgbàsókè orílẹ̀-èdè.

  1. Ibrahim Auduson (9 March 2010). "The Return of General Aliyu Gusau". Daily trust. Retrieved 21 April 2010.
  2. "The role of Aliyu Mohammed Gusau as NSA| IMG". www.ijawmonitor.org. Archived from the original on 24 July 2020. Retrieved 17 August 2020.
  3. "The role of Aliyu Mohammed Gusau as NSA| IMG". www.ijawmonitor.org. Archived from the original on 24 July 2020. Retrieved 17 August 2020.